TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Njẹ Fúlàní darandaran fi màlúù àti ilẹ̀ tọrẹ fún Peter Obi, olùdíje fún ipò ààrẹ?
Share
Latest News
No, Emefiele no return N4trn to FG
Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà
Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn
A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba
FACT CHECK: No, Emefiele didn’t return N4trn to FG
FAKE NEWS ALERT: Akume hasn’t been replaced as SGF, says presidency
Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró
Slurs, smears, slander… how gendered disinformation targets high-profile Nigerian women
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Njẹ Fúlàní darandaran fi màlúù àti ilẹ̀ tọrẹ fún Peter Obi, olùdíje fún ipò ààrẹ?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published July 20, 2022 5 Min Read
Share

Àtẹ̀jáde kan lórí Facebook gbé àhesọ pé darandaran Fulani kan fi àádọta màlúù ati ẹka ilẹ̀ mẹ́ta tọrẹ fún Peter Obi, olùdíje fún ipò Ààrẹ ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

“Ọkùnrin Hausa kan, “Danladi” ọmọ Ìpínlẹ̀ Kaduna fi àádọta màlúù àti ẹka ilẹ̀ mẹ́ta ta Peter Obi lọrẹ,” ọ̀rọ̀ ìfòrí yìí ni olùmúlò ojú òpó kan kọ s’ábẹ́ àtẹ̀jáde naa.

Àwòrán méjì ló wà pẹ̀lú àtẹ̀jáde náà. Èyí tí ó wà ni apá òsì ṣ’àfihàn màlúù funfun nínú aginjù. Ní apá kejì, àwòrán míràn ṣ’àfihàn màlúù aláwọ̀ funfun àti búráùn nínú ewéko.

Ọkùnrin pupa kan wà nínú àwòrán kejì.

“Ó dámilójú pé tí arákùnrin yìí tí ó wá láti ìlà-oòrùn bá di ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, yóò ṣe ètò àbò tí ó kún ojú òṣùwọ̀n,” báyìí ni ìparí ọ̀rọ̀ ìfòrí náà wí, èyí tí ‘Danladi’, ọkùnrin pupa inu àwòrán náà sọ.

Olùmúlò ìkànnì ibaraẹnisọrẹ kan ti orúkọ rẹ̀ń jẹ́ ‘Obidient’, ọ̀rọ̀ tí àwọn ọmọlẹ́yìn tàbí olùfẹ́ràn Peter Obi fi ń pe ara wọn fi àtẹ̀jáde yìí sí ojú òpó rẹ̀ ní ọjọ́ kejìlá oṣù keje, ó ní ọ̀rọ̀ ìwòye èjì dín ní okòó-lé-ní-ẹgbẹ́ta, àwọn olumulo míràn ti bu ọwọ́ ìfẹ́ lùú ni ọ̀nà ẹgbẹ̀ẹ́dógún, wọ́n sì ti se atunpin rẹ̀ ní ìgbà ẹẹdẹgbẹrin ó lé ní ọgọrin àti mẹ́ta.

Àwọn ojú òpó míràn lórí ìkànnì ibaraẹnisọrẹ náà ṣ’atunpin àtẹ̀jáde yìí ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà.

Olùmúlò ojú òpó tí kò ní ìfura sọ pe, “Inú mi dùn gidigan. Ọlọ́run ti bá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣé.”

Isaridaju

A lo Yandex, oun àmúlò ìgbàlódé fún àyẹ̀wò àwòrán láti fi ṣe ìwádìí orísun àwòrán yìí, ati àwọn míràn tó jọọ́, ṣíṣe itọpinpin àwòrán at’ẹyin wa (reverse image search) fihàn pé, àwòrán ọkùnrin pupa tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Danladi ti wà lórí ayélujára láti oṣù kẹta ọdún 2021.

Àbájáde àyẹ̀wò fihàn pé ilé ìwé ìròyìn Daily Trust lo àwòrán yìí ní ojú ìwé ayélujára wọn ni ogúnjọ́, oṣù kẹta ọdún 2021 pẹ̀lú àkòrí ìròyìn tó sọ wí pé “Dauda, Láti Isẹ Darandaran Sí Olùkọ́ Ilé Ìwé Gíga Yunifásítì.”

Tani Adamu Dauda?

Ìwé Ìròyìn Daily Trust ṣ’àfihàn arákùnrin yìí gẹ́gẹ́ bíi Adamu Dauda Garba, lòdì sí Danladi, orúkọ tí wọ́n pèé nínú àtẹ̀jáde akálékáko náà.

Ìròyìn náà gbé ìtàn bí Adamu, ẹni tí wọ́n bí ní ojọ́ kẹ̀wá, oṣù kẹ̀wá ọdún 1985, ṣe bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ darandaran ní Ìpínlẹ̀ Taraba láti ọmọ ọdún mẹ́fà àti bí ó ṣe ń kẹ́ẹ̀kọ́ pẹ̀lú iṣẹ́ náà.

Ní ọdún 2009, arákùnrin yìí gba ìwé-ẹ̀rí ilé ẹ̀kọ́ gíga fún àwọn olùkọ́, National Certificate of Education (NCE) ní Ìpínlẹ̀ Taraba níbi tí a ti ń kọ́ni ní iṣẹ́ olùkọ́ (Taraba state college of education) ní ìlú Jalingo, èyí tí ó jẹ olú ìlú Ìpínlẹ̀ Taraba.

”Ní ìgbà tí mo parí ẹ̀kọ́ mi, àwọn ènìyàn fi tó mi létí pé, Yunifásítì ìjọba àpapọ̀  tó wà ní Wukari ń wá àwọn olùṣọ́gbà, mo sì pinnu láti kọ lẹ́tà ìgbanisíṣẹ́, wọ́n sí gbà mí sí iṣẹ́,” arákùnrin yìí ló sọ báyìí.

L’ẹ́yìn ọdún mẹ́rin tó ṣiṣẹ́ aṣọ́gbà ni Yunifásítì náà, arákùnrin yìí di akẹ́kọ̀ọ́  ni ilé ẹ̀kọ́ gíga náà níbi ti ó ti kọ́ nípa isẹ ọ̀rọ̀ àwùjọ (sociology) – wọ́n sì gbáà sí iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí olùrànlọ́wọ́ olùkọ́ni (graduate assistant) l’ẹ́yìn tó kẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ tán.

Èsì Adamu sí ìròyìn òfégè

Ìwádìí lórí ìkànnì abẹ́yẹfò (Twitter) fihàn pé ìdènà ránpẹ́ kan wà lórí ojú òpó Adamu.

Àyẹ̀wò ojú òpó rẹ̀ fihàn pé ó ti fèsì sí àhesọ náà.

Ó ní: “Orúkọ mi ni Adamu Dauda Garba láti Ìpínlẹ̀ Taraba. Èmi kò fọwọ́sí ìmúlò àwòrán mí lórí ojú ìwé ayélujára wọn fún ìròyìn èké yìí. Mo rọ gbogbo ènìyàn kí wọ́n má ṣ’àfiyèsí ìròyìn yìí, kí wọ́n sì dúró de àbájáde ilé ẹjọ́ lórí ọ̀rọ̀ yìí.”

https://twitter.com/ADAMUDaudaGarb2/status/1546909972239368192?ref_src=twsrc%5Etfw%7Ctwcamp%5Etweetembed%7Ctwterm%5E1546909972239368192%7Ctwgr%5E%7Ctwcon%5Es1_&ref_url=https%3A%2F%2Fwww.thecable.ng%2Fwp-admin%2Fpost.php%3Fpost%3D724194action%3Deditclassic-editor

Àbọ̀ Ìwádìí

Àbájáde ìwádìí wà fihàn pe Adamu Garba ni orúkọ ọkùnrin tí wọ́n pè ní ‘Danladi’ nínú àtẹ̀jáde yìí. Kò fi àádọta màlúù tàbí ẹ̀ka ilẹ̀ mẹta tọrẹ ní ìpínlè Kaduna fún Peter Obi, olùdíje fún ipò ààrẹ. Irọ́ gbáà ni àhesọ náà.

TAGGED: 2023 elections, Adamu Dauda, Fact Check, peter obi, presidential campaign

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo July 20, 2022 July 20, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

No, Emefiele no return N4trn to FG

One video wey dey waka for social media show as Facebook user claim sey Godwin…

July 4, 2025

Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà

Fídíò kan tí àwọn ènìyàn ti ń pín lórí àwọn ohun ìgbàlódé íbaraẹnise orí ayélujára,…

July 4, 2025

Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn

Ótù ihe ngosị nà soshal midia egosila ebe ótù onye ji Facebook ekesa ozi kwuru…

July 4, 2025

A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba

Wani faifan bidiyo da ke yawo a kafafen sada zumunta ya nuna wani ma’abocin Facebook…

July 4, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

No, Emefiele no return N4trn to FG

One video wey dey waka for social media show as Facebook user claim sey Godwin Emefiele, di forma govnor of…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà

Fídíò kan tí àwọn ènìyàn ti ń pín lórí àwọn ohun ìgbàlódé íbaraẹnise orí ayélujára, tí ó ṣe àfihàn ẹni…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn

Ótù ihe ngosị nà soshal midia egosila ebe ótù onye ji Facebook ekesa ozi kwuru na Godwin Emefiele, onye bụbu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba

Wani faifan bidiyo da ke yawo a kafafen sada zumunta ya nuna wani ma’abocin Facebook yana ikirarin Godwin Emefiele, tsohon…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?