TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Kọ́lá Abiola ní igbimọ fún ààbò ni Nàìjíríà kò jókòó láti 1999. Ṣé òtítọ́ ni?
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Kọ́lá Abiola ní igbimọ fún ààbò ni Nàìjíríà kò jókòó láti 1999. Ṣé òtítọ́ ni?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published November 18, 2022 5 Min Read
Share

Kọ́lá Abíọ́lá, olùdíje fún ipò ààrẹ ní ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Redemption Party (PRP), sọ láìpẹ́ yìí pé igbimọ tó ń ṣojú ètò àbò ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (National Security Council) kò tíì ní ìpàdé kankan láti ọdún 1999.

Abiola sọ ọ̀rọ̀ yìí ní ibi ifiọ̀rọ̀wálẹ́nuwò ìta gbangba àwọn Ólùdíje fún ipò ààrẹ tí àjọ kan tó ń polongo ìjọba àwa-ara-wa àti ìdàgbàsókè, Centre for Democracy and Development (CDD), ṣètò pẹ̀lú ajọṣepọ ilé-isẹ iroyin Arise News ní Abuja, olú ìlú orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Abiola jẹ́ ìkan nínú àwọn olùdíje fún ipò ààrẹ mẹ́rin tí wọn pésẹ̀ sí ibi àpéjọ náà ní ọjọ́ àìkú.

Àwọn olùdíje mẹ́ta míràn tó wà ní ibi ifiọ̀rọ̀wálẹ́nuwo ọ̀ún ni Peter Obi, olùdíje fún ipò ààrẹ ní ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ (Labour Party), Rabiu Kwankwaso, tí ó jẹ ti ẹgbẹ́ ́òṣèlú New Nigeria Peoples Party (NNPP) àti Ifeanyi Okowa, igbá-kejì Atiku Abubakar, tí ó jẹ olùdíje fún ipò ààrẹ ní ẹgbẹ́ òsèlú Peoples Democratic Party (PDP).

Gbogbo àwọn olùdíje náà ló sọ̀rọ̀ nípa ètò ààbò ati ọrọ ajé tí wọn yóò gbekalẹ ti won bá dé ipò ààrẹ.

Nínú ifọrọwaniẹnuwo náà, Reuben Abati, olóòtú ètò náà bèrè lọ́wọ́ àwọn olùdíje ìgbésẹ tí wọ́n yóò gbé, bí wọ́n bá jẹ ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ìgbà tí irú ìṣẹ̀lẹ̀ akọlu tireni  tí ó rin ní ojú irin Kaduna sí Abuja ní oṣù kẹta, ọdún 2022 bá ṣẹlẹ̀.

Abiola f’èsì pé igbimọ tó ṣojú ètò àbò l’órílẹ̀ èdè Nàìjíríà ò tíì jókòó láti ọdún 1999.

“Ìṣẹ̀lẹ̀ aburú yìí jẹ́ ọ̀kan nínú ìdojúkọ orílẹ̀-èdè yìí ní ti ètò ààbò láti ọdún tó ti pẹ. A ní láti s’agbeyẹwo ètò ààbò wa lórílẹ̀ èdè yìí.

“Bí ọdún ti ń gorí ọdún,  ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀ lati sọ nípa ètò ààbò ṣùgbọ́n ṣé oun tó kàn ní èyí? Lati ọdún 1999, igbimọ tó ń ṣojú ètò àbò l’órílẹ̀ èdè Nàìjíríà kò tíì jókòó láti ọdún 1999,” Abiola ló sọ báyìí.

Isewadi

TheCable ṣe agbeyẹwo abala ẹtalelaadọjọ, apá kẹdọgbọn ti ìwé òfin ọdún 1999 (section 153, subsection 25 of the 1999 constitution) tí ó se agbekalẹ àwọn tí yóò wà ní ìgbìmọ̀ ọ̀ún.

“Igbimọ tó ṣojú ètò àbò l’órílẹ̀ èdè Nàìjíríà gbọ́dọ̀ ní: (a) ààrẹ orílẹ̀-èdè tí ó jẹ alága ìjókòó náà; (b) igbá-kejì ààrẹ tí yóò jẹ igbá-kejì alága;  (c) ọgagun òṣìṣẹ́ lórí ètò ààbò orílẹ̀-èdè (d) mínísítà nípa ọ̀rọ̀ ìlú (e) mínísítà nípa ètò ààbò (f) Mínísítà fún ọrọ ilẹ òkèèrè (g) oludamọran ààrẹ lórí ètò ààbò (h) ọga pátápátá fún àwọn Ọlọpa àti (i) ẹnikẹ́ni tí ààrẹ bá yàn.”

Apá  kẹrindinlọgbọn f’ikun-un wí pé ètò igbimọ náà ní láti gba ààrẹ ní ìmọ̀ràn lórí ètò ààbò “àti àwọn ọ̀rọ̀ míràn tó nííse pẹ̀lú àwọn Ilé isẹ tí òfin gbé kalẹ̀ fún ètò ààbò orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.”

Ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹwa ọdún yìí, TheCable gbé ìròyìn pé ààrẹ Muhammadu Buhari ṣe Ìpàdé pẹ̀lú igbimọ tó ń ṣojú ètò ààbò nì ìlú Abuja.

Àwọn míràn tó pesẹ si ibi Ìpàdé náà ni ìgbákeji ààrẹ, Yemi Osinbajo, Boss Mustapha, akọ̀wé àgbà fún ìjọba àpapọ̀, Babagana Monguno, olùdámọ̀ràn ààrẹ Buhari lórí ètò ààbò àti Ibrahim Gambari, olórí àwọn òṣìṣẹ́ ti ìjọba àpapọ̀ ilẹ̀ Nàìjíríà.

Àwọn mínísítà míràn tí ó wà nibẹ ni Bashir Magashi, mínísítà nípa ètò ààbò, Rauf Aregbesola, mínísítà tó ń rí sí ọrọ abẹle àti Maigari Dingyadi, mínísítà fún ọrọ àwọn ọlọpa. Gbogbo àwọn olórí òṣìṣẹ́ ìjọba àti olórí àwọn ẹṣọ alaabo ló péjú sí ibi àpéjọ náà.

Ní ọjọ́ kọkanlelọgbọn, oṣù kẹwa ọdún 2022, ìròyìn tàn pé ààrẹ Buhari pe fún ìjokòó àwọn ọmọ ẹgbẹ́ igbimọ aṣoju ètò ààbò.

Ìpàdé náà wáyé ni ilu Abuja láti ṣe agbeyẹwo lẹkunrẹrẹ àti láti fí okun kún agbára fún àwọn ẹṣọ aláàbò ni Orílẹ̀-èdè yìí.

Àbájáde ìwádìí

Ìrọ́ gbàá ni ọrọ tí Abiola sọ pé igbimọ aṣojú ètò ààbò ní orílẹ̀-èdè yìí ko jókòó/ṣe ìpàdé láti ọdún 1999. Ààrẹ Buhari pe ìpàdé igbimọ náà laipẹ yìí.

TAGGED: Arise Town Hall Meeting, Kola Abiola, PRP

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo November 18, 2022 November 18, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?