TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé Atiku ni olórí àwọn alamojuto ọrọ̀ ajé tí Obasanjo ṣe agbekalẹ rẹ̀?
Share
Latest News
FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?
FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?
FACT CHECK: Ndume erred. 22 governors didn’t endorse Jonathan in 2015
Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé
Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá
No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu
A’a, Paparoma Leo bai nemi Tinubu ya saki Nnamdi Kanu ba
FACT CHECK: No, Pope Leo didn’t ask Tinubu to release Nnamdi Kanu
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé Atiku ni olórí àwọn alamojuto ọrọ̀ ajé tí Obasanjo ṣe agbekalẹ rẹ̀?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published February 17, 2023 7 Min Read
Share

Atiku Abubakar, igbá-kejì Olusegun Ọbásanjọ́, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nígbàkanrí sọ wí pé òun ni ó jẹ́ olórí tàbí olùṣàkóso àwọn alamojuto ọrọ̀ ajé nígbà ìjọba Ọbásanjọ́. 

Atiku, ẹni tí ó jẹ Ólùdíje fún Ipò Ààrẹ nínú ẹgbẹ́ òsèlú Peoples Democratic Party (PDP) sọ ọ̀rọ̀ yìí ní ọjọ́ ajé ní ibi ifiọ̀rọ̀jomitoroọ̀rọ̀ nípa ọrọ̀ ajé/karakata (National Economic Summit Group-NESG) ṣe ní ìlú Èkó.

“Gẹ́gẹ́bí olórí alákòóso/alamojuto ètò ọrọ̀ ajé/karakata nígbà tí mo jẹ igbá-kejì, mo wà lára àwọn tí ó se agbekalẹ bí ọrọ̀ ajé yóò ṣe lọ déédéé tí mo sì ṣe àgbàtẹru pé kí àwọn aladani dá sí ọrọ̀ ajé. A sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ àṣeyọrí,” Atiku ni ó wí báyìí.

“Ó dá mi lójú pé wàá rántí ìgbà tí ọrọ̀ ajé ń lọ déédéé, tí nkan kò gbé owó lórí, tí  iṣẹ́ wà, tí ìṣẹ́ kò pọ̀.

“A san ọ̀pọ̀lọpọ̀ gbèsè tí a jẹ àwọn orílẹ̀-èdè kan.”

As head of the economic management team while I was Vice President, I was instrumental in designing a private sector revival strategy and advocated for the opening of the economy for private sector investments in several sectors. And we made tremendous progress. #AtikuAtNESG

— Atiku Abubakar (@atiku) January 16, 2023

Ọbásanjọ́ ṣe Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti ọdún 1999 sí ọdún 2007.

Ṣé òótọ́/òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ tí Atiku wí?

ÌWÁDÌÍ

Ayẹwo tí ìwé ìròyìn TheCable ṣe fihàn pé Ngozi Okonjo-Iweala, minisita tẹ́lẹ̀rí fún ètò isuna tí ó sì jẹ́ ọga pátápátá fún àjọ àgbáyé fún ọrọ̀ ajé (World Trade Organization-WTO) gangan ni ó jẹ́ Alákòóso àwọn alamojuto ọrọ̀ ajé ní ìgbà tí Ọbásanjọ́ ṣe ìjọba.

Ọbásanjọ́ dá àwọn alamojuto fún ọrọ̀ ajé yìí sílẹ̀ ní ọdún 2003 nígbà tí ó se Ààrẹ lẹẹkeji.

Atẹjade nípa gbèsè Nàìjíríà, tí àjọ ibaraẹnise láàárín àwọn orílẹ̀-èdè adulawọ àti ilẹ̀ òyìnbó (Centre for Africa-Europe Relations) sọ wí pé: “Nígbà tí a dibo yan Ààrẹ Ọbásanjọ́ láti ṣe ìjọba lẹẹkeji ní ọdún 2003, ó yan àwọn alamojuto ọrọ̀ ajé, ó sì fi arábìnrin Ngozi Okonjo-Iweala, ẹni tí ó jẹ́ ọga ní Bánkì fún àgbáyé (World Bank) nígbàkanrí ṣe olórí wọn. Àwọn Alamojuto yìí ṣe akitiyan lọpọlọpọ kí àyípadà rere lè dé bá ètò ìdàgbàsókè.”

Nínú ọ̀rọ̀ tí a fi tonileti tí Okonjo-Iweala sọ nípa ipa tí wọn ṣà kí ọrọ̀ ajé lè lọ déédéé, ó gbà wí pé ní ọdún 2003 lẹ́hìn ìgbà tí Ọbásanjọ́ gbáà láyè láti kó àwọn alamojuto ọrọ̀ ajé jọ, Ààrẹ Ọbásanjọ́ pinnu láti jẹ́ olórí àwọn alamojuto náà, ó sì fi Okonjo-Iweala ṣe adarí.

Àwọn Alamojuto náà jẹ́ ènìyàn méjìlá tí wọn ní ìmọ̀ tí ó yekooro nípa ọrọ̀ ajé, bí a ṣe ń mojuto gbèsè, fífún àwọn aladani láyè láti darí ọrọ̀ ajé, ìlọsíwájú àwọn aladani, ètò ìjọba, ètò igbogunti ìwà ṣíṣe nkan mọkumọku, àyípadà rere fún iṣẹ́ ìjọba àti ètò isuna ni wọn ṣe agbekalẹ rẹ̀ fún ọrọ̀ ajé nígbà tí Ọbásanjọ́ ṣe ìjọba.

Lára àwọn ènìyàn méjìlá tí ó wà nínú àjọ alamojuto náà ni Chukwuma Soludo, ẹni tí ó jẹ ọga pátápátá/Gómìnà Bánkì Àpapọ̀ Nàìjíríà tẹ́lẹ̀rí, Nuhu Ribadu, adarí àjọ tí ó ń gbógun ti ṣíṣe nkan ọrọ̀ ajé lọ́nà tí kò yẹ àti ikowojẹ/isowo mọkumọku (Economic and Financial Crimes Commission-EFCC), Nasir el-Rufai, minisita nígbàkanrí fún olú ìlú ilẹ̀ Nàìjíríà tí Ìjọba Àpapọ̀ ń ṣe àkóso rẹ̀ (Federal Capital Territory-FCT), Oby Ezekwesili, minisita nígbàkanrí fún ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́, Bode Augusto, ọga pátápátá nígbàkanrí ní ọ́fíìsì fún ètò isuna, Ifueko Omoigui, alaga tẹ́lẹ̀rí fún àjọ ìjọba Àpapọ̀ tí ó ń rí sí bí owó ṣe ń wọlé àti àwọn mìíràn.

Gẹ́gẹ́bí olórí àwọn alamojuto ọrọ̀ ajé àti minisita fún ètò isuna, Okonjo-Iweala ni ó darí ifiọrọweọrọ tí Nàìjíríà ṣe pẹ̀lú àwọn tí ó jẹ lowo ní òkè òkun.

Lẹ́hìn ifiọrọweọrọ yìí, Nàìjíríà àti àwọn tí ó jẹ lowo ṣe ìkéde àdéhùn ìparí láti lè dín gbèsè Nàìjíríà kù. Gbèsè náà tó biliọnu méjìdínlógún dọla lẹ́hìn ìgbà tí Nàìjíríà san biliọnu méjìlá dọla nínú gbèsè náà.

ṢÉ IKAN NÁÀ NI ÀWỌN ALAMOJUTO ỌRỌ̀ AJÉ (ECONOMIC MANAGEMENT TEAM) ÀTI IGBIMỌ ỌRỌ AJÉ (NATIONAL ECONOMIC COUNCIL)?

Rárá. Àwọn àjọ méjèèjì kìí se iṣẹ́ kan/ìkan náà.

Nígbà tí Atiku ṣe igbá-kejì Ààrẹ, òun ni ó jẹ́ adarí igbimọ bí ọrọ̀ ajé yóò ṣe lọ déédéé.

Ìtàn ìgbésí ayé rẹ̀ tí ẹnikan kọ tí ó wà ní orí wẹbusaiti Yar’Adua Foundation sọ wí pé: “Gẹ́gẹ́bí igbá-kejì Ààrẹ, Atiku jẹ alága igbimọ tí ó ń rí sí ọrọ̀ ajé tí ó kó àwọn onímọ̀/olóye tí wọn mú àyípadà rere bá ètò ọrọ̀ ajé Nàìjíríà jọ láàárín ọdún 2000 àti ọdún 2007.”

A dá igbimọ ọrọ̀ ajé yìí sílẹ̀ nípasẹ̀ ìwé òfin tí Ìjọba Àpapọ̀ Nàìjíríà, tí a ti ṣe àtúnṣe rẹ̀ tí ó wà ní apá kẹtalelaaadọjọ, abala Kínní àti ipinrọ kejidinlogun àti ikọkàndínlógún tí apá Kínní, ibi kẹta tí a yà sọtọ.

Bí ìwé òfin ṣe wí, iṣẹ́ igbimọ ọrọ̀ ajé ni láti máa “gba Ààrẹ ní amọran nípa ọrọ̀ ajé àti ní pàápàá jùlọ láti máa ṣe agbekalẹ bí ọrọ̀ ajé yóò ṣe máa lọ déédéé fún gbogbo àwọn ìjọba Nàìjíríà.”

Àwọn tí ó wà nínú igbimọ náà ni igbá-kejì Ààrẹ, ẹni tí ó jẹ alága, àwọn gómìnà mẹrindinlọgbọn ilẹ̀ Nàìjíríà, Gómìnà Bánkì Àpapọ̀ Nàìjíríà àti àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba mìíràn.

Ẹni tí ó jẹ́ adarí igbimọ ọrọ̀ ajé nísinsìnyí ni Yemi Osinbajo, igbá-kejì Ààrẹ Muhammadu Buhari.

Igbimọ náà máa ń ṣe ìpàdé lẹẹkan nínú oṣù.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ NÁÀ SÍ

Ọ̀rọ̀ tí Atiku sọ pé òun ni Olórí àwọn alamojuto ọrọ̀ ajé kìí se òtítọ́. Ọdún 2003 ni wọn dá àwọn alamojuto yìí sílẹ̀ nígbà tí Ọbásanjọ́ ń ṣe ìjọba.

Ààrẹ Ọbásanjọ́ ni alákòóso tí Okonjo-Iweala sì jẹ́ adarí àwọn alamojuto náà.

TAGGED: atiku abubakar, economic management team, National Economic Summit Group (NESG), ngozi okonjo-iweala, Obasanjo

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael February 17, 2023 February 17, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?

A viral X post claims that Nigeria’s new national anthem was not recited during the…

June 13, 2025

FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?

Reports of a military coup in Cameroon ousting President Paul Biya have gone viral on…

June 13, 2025

FACT CHECK: Ndume erred. 22 governors didn’t endorse Jonathan in 2015

On June 8, Ali Ndume, senator representing Borno south, claimed that 22 governors elected on…

June 10, 2025

Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé

Ẹni kan tí ó ń lo Facebook, ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ orí ayélujára sọ pé Robert…

June 10, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé

Ẹni kan tí ó ń lo Facebook, ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ orí ayélujára sọ pé Robert Francis Prevost, Pope Leo XIV…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá

Ótù onye na Facebook ekwuola na Pope Leo na ụfọdụ ndị Bishop yọrọ onye isiala Bola Tinubu ka ọ tọpụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu

One Facebook user claim sey Pope Leo XVI and oda bishops join mouth beg President Bola Tinubu to release Nnamdi…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

A’a, Paparoma Leo bai nemi Tinubu ya saki Nnamdi Kanu ba

Wani mai amfani da Facebook ya yi ikirarin cewa Paparoma Leo na 16 da wasu limaman coci sun roki shugaban…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?