TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé òtítọ́ ni wí pé àwọn gómìnà gúúsù ilà-oòrùn ló dá ESN sílẹ̀?
Share
Latest News
Seven ways to detect an AI-generated video
BLIND SPOT: Nigeria’s shortcomings in the age of AI scams
The rise of deepfakes and the fight for digital truth
DISINFO ALERT: Health ministry debunks AI video claiming free nationwide diabetes treatment
Video wey show as ‘security operatives’ dey break into apartment no be from south-east
Íhé ńgósị́ ébé ńdị́ ǹché nà-ákpáká ụ́lọ̀ ésiteghị nà south-east
Ìṣẹ̀lẹ tí àwọn ‘òṣìṣẹ́ elétò ààbò’ fẹ́ fipá wọ ibùgbé kan kò ṣẹlẹ̀ ní gúúsù ilà oòrùn Nàìjíríà
Bidiyon da ake dangantawa da ‘jami’an tsaro’ da suka kutsa cikin gida ba daga kudu maso gabas ba ne
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé òtítọ́ ni wí pé àwọn gómìnà gúúsù ilà-oòrùn ló dá ESN sílẹ̀?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published November 1, 2022 5 Min Read
Share

Peter Obi, olùdíje fún ipò ààrẹ nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ (Labour Party), sọ láìpẹ́ yìí pé àpapọ̀ àwọn gómìnà ìhà gúsù ilà-oòrùn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ló da ikọ̀ aláàbò Eastern Security Network (ESN) silẹ.

Olùdíje náà sọ ọ̀rọ̀ yìí ní ọjọ́ ajé, ọjọ́ kẹẹdogun, oṣù kẹwa, ọdún 2022, ní ibi ìpéjọ ifọrọwerọ ti Arewa Joint Committee ní Ìpínlẹ̀ Kaduna.

Nínú fọ́nrán àpéjọ náà, ènìyàn kan bèrè pé, “kíni ìdí tí àwa ènìyàn àríwá Nàìjíríà ṣe máa gbà ẹ́ gbọ́, nígbà tí ó kò fi ìgbà kankan ṣe ìdálẹbi kónílé-ó-gbélé ọjọ ajé ní gúúsù ìlà-oòrùn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà?

“Kíni ìdí tí àwọn ènìyàn àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣe gbọ́dọ̀ fi ọkàn tán ẹ nígbà tí àwọn alága ìpolongo ìbò fún ẹgbẹ́ òsèlú àwọn osisẹ tí o gbé kalẹ fún ìpínlẹ̀ Sokoto àti àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpínlẹ̀ míràn ní àríwá orílẹ̀-èdè wa fún ìdíje ipò Ààrẹ rẹ jẹ́ ọmọ ẹ̀yà igbo?

“Kilode tí àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣe máa gbà ẹ́ gbọ́, nígbà tí èmi kò fi ìgbà kankan gbọ kí o da IPOB (Indigenous People of Biafra) ati ESN lẹbi fún gbogbo àwọn àṣemáṣe tí wọ́n ṣe?” arákùnrin kan ló bere ìbéèrè yìí.

Ni idahun sí ìbéèrè náà, Obi sọ wí pé kò sí ọ̀nà bí òun yóò ṣe dá ESN lẹbi fún àwọn nǹkan tí wọn ṣe nítorí wí pé àwọn ìjọba Ìpínlẹ̀ gúúsù ila-oorun ni wọn dáa silẹ.

“Awon ìjọba ìpínlẹ̀ gúúsù ilà-oòrùn ló dá ESN sílẹ̀. Àwọn gómìnà Ìpínlẹ̀ gúúsù ila-oorun ló dá ikọ̀ ààbò náà sílẹ̀, kíló le fàá tí mo ma ṣe dá wọn lẹbi? Mo ti sọ̀rọ̀ nípa kónílé-ó-gbélé ọlọsọọsẹ ní gúúsù ìlà-oòrùn, àwọn ènìyàn sì ti mẹ́nuba orúkọ mi nípa ọ̀rọ̀ náà. Ẹ lọ ṣe ìwádìí òun gbogbo tí mo bá sọ.”

Àmọ́sá, ṣé òtítọ ni ọ̀rọ̀ yìí?

Iṣaridaju

Àyẹ̀wò ìwé ìròyìn TheCable fihàn pé ọgbẹni Nnamdi Kanu, adarí ẹgbẹ́ ajijagbara tí a mọ sí Indigenous People of Biafra (IPOB) ló dá ESN silẹ ní oṣù Kejìlá, ọdún 2020.

Ẹgbẹ́ IPOB ti Kanu dá sílẹ̀ ní ọdún 2012, ti pè fún idasilẹ orílẹ̀-èdè Biafra, ìjọba alàdáni fún àwọn ènìyàn gúúsù ila-oorun orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, lori àhesọ pé wọn kò ri ànfààní t’óyẹ jẹ láti ọ̀dọ̀ ìjọba àpapọ̀.

Ní ọjọ́ kẹtàlá, oṣù Kejìlá, ọdún 2020, Kanu kede idasilẹ ikọ̀ akọgun ESN. Ó sọ wí pé a dá ikọ̀ akọgun náà silẹ láti máa dàbobo àwọn ènìyàn gúúsù ilà-oòrùn orílẹ̀-èdè wa láti ọwọ́ àwọn agbesunmọmi àti àwọn ọ̀daràn míràn.

Ṣáájú àsìkò yìí, ìròhìn ti tànká orí ayélujára lóri bí àwọn darandaran Fulani ṣe ń kọlù oko ní gúúsù ilà-oòrùn.

Nínú ìkéde rẹ̀, Kanu fi ikọ̀ akọgun ESN wé ikọ̀ ẹ̀ṣọ́ aláàbò Amọtẹkun ni iwọ oòrùn gúúsù Nàìjíríà àti Miyetti-Allah ni àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Ó ní, aiṣedede àwọn gómìnà Ìpínlẹ̀ gúúsù ilà-oòrùn Nàìjíríà nípa ètò ààbò tó dájú fún àwọn ará ìlú ló fàá tí wọ́n fi dá ESN silẹ.

Ní ọdún 2021, àwọn gómìnà ìpínlẹ̀ gúúsù ilà-oòrùn ṣ’agbekalẹ ikọ̀ ẹ̀ṣọ́ aláàbò Ebube Agu, “lati gbógun ti ìwà ọ̀daràn ní agbègbè náà.”

Dave Umahi, gómìnà Ìpínlẹ̀ Ebonyi, tó tún jẹ́ alága ẹgbẹ́ àwọn gómìnà gúúsù ìlà-oòrùn sọ pé wọ́n da ìkọ aláàbò náà silẹ torí àìsí-ààbò tí ó ń burú sí ní agbègbè náà.

“Gbogbo wá ti fẹnukò láti fi ìmọ̀ ṣọ̀kan lórí ètò ààbò nì ilẹ̀ wa. Ikọ̀ ẹ̀ṣọ́ aláàbò tí a gbekalẹ fún gúúsù ilà-oòrùn ni a ń pé ní Ebube Agu. Olú ilé-isẹ ikọ̀ náà yóó wà ní ipinlẹ Enugu, láti ibi tí yóò ti máa darí ètò àbò káàkiri gúúsù ilà-oòrùn orílẹ̀-èdè wa,” Umahi ló sọ báyìí.

Àbájáde ìwádìí

Irọ àti isinilọna ni ọrọ ti Obi sọ nípa idasilẹ ESN. Ẹgbẹ́ ajijagbara IPOB ló dá ikọ̀ ẹ̀ṣọ́ aláàbò náà silẹ kìíse àwọn gómìnà Ìpínlẹ̀ gúúsù ila-oorun/ilẹ Igbo. Adijedupo fún Ipò Ààrẹ nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn osisẹ náà gbé idasilẹ IPOB àti ESN fún ara wọn.

TAGGED: ESN, Fact Check, Labour Party, peter obi

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo November 1, 2022 November 1, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Seven ways to detect an AI-generated video

A video announcing the launch of a free nationwide diabetes treatment recently went viral across Nigerian…

August 13, 2025

BLIND SPOT: Nigeria’s shortcomings in the age of AI scams

It sounded exactly like her, but it was not. Adeola Fayehun was thousands of miles…

August 12, 2025

The rise of deepfakes and the fight for digital truth

BY PRUDENCE OKEOGHENE EMUDIANUGHE On May 30, 2025, a 49-minute video surfaced on a YouTube…

August 12, 2025

DISINFO ALERT: Health ministry debunks AI video claiming free nationwide diabetes treatment

The ministry of health and social welfare has dismissed a viral claim alleging the launch…

August 12, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Video wey show as ‘security operatives’ dey break into apartment no be from south-east

One Facebook user don claim sey video wey show as hooded armed security operatives dey break into residential apartment hapun…

CHECK AM FOR WAZOBIA
August 7, 2025

Íhé ńgósị́ ébé ńdị́ ǹché nà-ákpáká ụ́lọ̀ ésiteghị nà south-east

Ótù onye na Facebook ekwuola na ihe ngosị ebe mmadụ na-agbaka ụlọ obibi mmadụ mere na south-east. N'ụbọchị iri abụọ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
August 7, 2025

Ìṣẹ̀lẹ tí àwọn ‘òṣìṣẹ́ elétò ààbò’ fẹ́ fipá wọ ibùgbé kan kò ṣẹlẹ̀ ní gúúsù ilà oòrùn Nàìjíríà

Ẹni kan tí ó ń lo Facebook, ohun ìgbàlódé íbaraẹnisọrẹ lórí ayélujára sọ pé fídíò tí ó se afihan àwọn…

CHECK AM FOR WAZOBIA
August 7, 2025

Bidiyon da ake dangantawa da ‘jami’an tsaro’ da suka kutsa cikin gida ba daga kudu maso gabas ba ne

Wani ma’abocin amfani da shafin Facebook ya yi ikirarin cewa wani faifan bidiyo da ke nuna jami’an tsaro dauke da…

CHECK AM FOR WAZOBIA
August 7, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?