TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjẹ́ bánkí àpapọ̀  orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kéde ìfòpinsí Form A fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ òkè òkun?
Share
Latest News
Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró
Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal
No, Nigeria no send peace support mission go Israel
A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba
Ǹjẹ́ Tinubu àti Alexander Zingman lọ sí ilé-ìwé kan náà? Èyí ni ohun tí a mọ̀
Tinubu nà Alexander Zingman ọ̀ gàrà ótù ụ́lọ̀ákwụ́kwọ́? Lèé íhé ányị́ mà
Tinubu go di same school wit Alexander Zingman? Na wetin we sabi be dis
Shin Tinubu ya halarci makaranta daya da Alexander Zingman? Ga abin da muka sani
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjẹ́ bánkí àpapọ̀  orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kéde ìfòpinsí Form A fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ òkè òkun?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published July 1, 2022 3 Min Read
Share

Ìròyìn tán ràn-ìn lórí ayélujára wí pé, ní ìparí ọdún yìí, bánkì àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (CBN) yóò fòpinsí lílo Form A, èyí tí máa ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tó ń kàwé ní òkè òkun láti san owó ẹ̀kọ́ wọn.

Ní ipasẹ̀ form A yìí, àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tó ń kàwé l’ókè òkun máa ń r’áyè san owó ẹ̀kọ́ wọn pẹ̀lú òṣùwọ̀n pasípárọ ti ìjọba, dípò àwọn tó ń ṣe pàṣípàrọ̀ dọ́là sí náírà nínú ọjà, eléyìí tí ó wọ́n ju ti ìjọba lọ.

Àwọn ọmọ Nàìjíríà ní orí ayélujára ti fíbínúhàn lórí ìròyìn pé, láti oṣù kínní ọdún 2023, owó ẹ̀kọ́ tí wọn yóò máa san yóò lé si.

“Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ ka ìròyìn kan pé, ní oṣù kejìlá ọdún yìí, bánkì àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yóò fagilé Form A. Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó ń f’ojú sọ́nà láti kàwé l’ókè òkun máa ní láti gba òṣùwọ̀n pásípáro ọ̀dọ àwọn tí wọ́n ń ṣe káràkátà owó. Ní ṣe ni ó tún burú si,” Adéwálé Adétọ̀nà, olùmúlò ìkànnì abẹ́yẹfò (Twitter), kọ èyí sí ojú òpó rẹ̀. Àwọn ènìyàn tí s’àtúnpín àtẹ̀jáde yìí ní ọ̀nà ọ̀kan dín ní ọ̀rìn-lé-ní-igba, àwọn olùmúlò míràn sì ti bu ọwọ́ ìfẹ́ lu àtẹ̀jáde yìí ní ọnà eéjìlá dín ní ọrìn lélọ́ọ̀dúnrún.

I just read that from December 2022, the CBN is canceling Form A. Prospective International Students from Nigeria will have to get FX for their school fees from black market. It keeps getting worse.

— Slimfit (@iSlimfit) June 21, 2022

Àhesọ yìí tí ó wà l’órí ìkànnì Abẹ́yẹfò (Twitter) àti Facebook gbé àwòrán àtẹ̀jáde kan tó wá láti ilé ẹ̀kọ́ gíga Manchester Metropolitan/Manchester Metropolitan Yunifásiti (Manchester Metropolitan University).

Àkòrí àtẹ̀jáde náà sọ wí pé, “ìdínkù nínú àwọn ìdíyelé Form A ti bánkì àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí yóò bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kejìlá, ọdún 2022”.

Apparently Manchester Metropolitan University sent this circular alleging that CBN is withdrawing form A by end of 2022 for fee payments. Japa via studies about to be more expensive if true. pic.twitter.com/FOPPz0PpkY

— Wissam Ben Yedder (@DipoAW) June 21, 2022

Èsì ilé ẹ̀kọ́ giga Manchester Metropolitan Yunifásití

TheCable kàn sí àwọn olúṣàkóso ilé ẹ̀kọ́ gíga Manchester Metropolitan Yunifásiti  láti ṣe ìwádìí àhesọ ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní ó wá láti ilé ẹ̀kọ́ náà.

“A mòye pé bánkì àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yóò mú Form A kúrò nílẹ̀ ní ìparí ọdún yìí. Nítorínáà a fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ wa ní ìtọ́sọ́nà tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́ fún wọn lórí ọ̀rọ̀ yìí,” agbẹnusọ ilé ẹ̀kọ́ náà ni ó wí báyìí.

Iṣamudaju

Osita Nwanisobi, olùdarí ẹ̀ka ìbáraẹnisọ̀rọ̀ ti bánkì àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà sọ wí pé irọ́ gbá ni àtẹ̀jáde tí ó wá láti ilé ẹ̀kọ́ gíga Manchester Metropolitan Yunifásiti.

Nwanisobi ní,“Ìlànà yìí ò wá láti bánkì àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.”

Ó rọ àwọn òbí àti akẹ́kọ̀ọ́ kí wọ́n má ṣe ṣ’àfiyèsí àtẹ̀jáde náà pé kí wọ́n san ọ̀pọ̀ lára owó ẹ̀kọ́ wọn pẹ̀lú Flywire síwájú  ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kejìlá, ọdún 2022.

Àbọ̀ Ìwádìí

Àbájáde ìwádìí fihàn pé bánkì àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kò tíì ṣe ìkéde ìlànà pé wọn yóò fòpinsí lílo Form A ní ìparí ọdún yìí. Àhesọ ni ọ̀rọ̀ yìí.

 

TAGGED: cbn, Form A, Manchester Metropolitan University, Osita Nwanisobi

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo July 1, 2022 July 1, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró

Ìròyìn lati inú fídíò Facebook kan sọ pé Nàìjíríà fi àwọn ọmọ ogun ránṣẹ́ sí…

June 28, 2025

Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal

Ótù ihe ngosị si na Facebook kwuru na Naijiria zipụrụ ndị agha ka ha gaa…

June 28, 2025

No, Nigeria no send peace support mission go Israel

One Facebook video claim sey Nigeria send soldiers go Israel for joint peace support mission.…

June 28, 2025

A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba

Wani faifan bidiyo na Facebook ya nuna cewa Najeriya ta tura dakaru domin aikin hadin…

June 28, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró

Ìròyìn lati inú fídíò Facebook kan sọ pé Nàìjíríà fi àwọn ọmọ ogun ránṣẹ́ sí orílẹ̀ èdè Ísírẹ́lì kí rògbòdìyàn…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal

Ótù ihe ngosị si na Facebook kwuru na Naijiria zipụrụ ndị agha ka ha gaa kwàdó udo na mba Isreal.…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

No, Nigeria no send peace support mission go Israel

One Facebook video claim sey Nigeria send soldiers go Israel for joint peace support mission. One male broadcaster wey dey…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba

Wani faifan bidiyo na Facebook ya nuna cewa Najeriya ta tura dakaru domin aikin hadin gwiwa na tallafawa zaman lafiya…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?