TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé òtítọ́ ni wí pé àwọn gómìnà gúúsù ilà-oòrùn ló dá ESN sílẹ̀?
Share
Latest News
FACT CHECK: Amupitan, INEC chair nominee, wasn’t part of Tinubu’s legal team at election tribunal
Anambra guber: Offences that can get you arrested during elections in Nigeria
Charly Boy yayi da’awar karya kan cewa Dan Nnamdi Kanu yaci gasar ‘kwakwalwa ta Duniya’
Charly Boy no tok true sey Nnamdi Kanu son win ‘international brain competition’
Irọ́ ni Charly Boy pa pé ọmọ Nnamdi Kanu ọkùnrin ṣàṣeyọrí nínú ìdíje àwọn ọlọ́pọlọ pípé ní àgbáyé
FACT CHECK: Report claiming police rescued 300 people in Kaduna building is from 2019
No be true. Ikpeazu no collect death sentence by hanging sake of ‘N1trn fraud’
Irọ́ ni. Wọn kò dá ẹjọ́ ikú fún Ikpeazu nítorí pé ‘ó kó triliọnu kan náírà owó ìjọba sí àpò ara rẹ̀’
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé òtítọ́ ni wí pé àwọn gómìnà gúúsù ilà-oòrùn ló dá ESN sílẹ̀?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published November 1, 2022 5 Min Read
Share

Peter Obi, olùdíje fún ipò ààrẹ nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ (Labour Party), sọ láìpẹ́ yìí pé àpapọ̀ àwọn gómìnà ìhà gúsù ilà-oòrùn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ló da ikọ̀ aláàbò Eastern Security Network (ESN) silẹ.

Olùdíje náà sọ ọ̀rọ̀ yìí ní ọjọ́ ajé, ọjọ́ kẹẹdogun, oṣù kẹwa, ọdún 2022, ní ibi ìpéjọ ifọrọwerọ ti Arewa Joint Committee ní Ìpínlẹ̀ Kaduna.

Nínú fọ́nrán àpéjọ náà, ènìyàn kan bèrè pé, “kíni ìdí tí àwa ènìyàn àríwá Nàìjíríà ṣe máa gbà ẹ́ gbọ́, nígbà tí ó kò fi ìgbà kankan ṣe ìdálẹbi kónílé-ó-gbélé ọjọ ajé ní gúúsù ìlà-oòrùn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà?

“Kíni ìdí tí àwọn ènìyàn àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣe gbọ́dọ̀ fi ọkàn tán ẹ nígbà tí àwọn alága ìpolongo ìbò fún ẹgbẹ́ òsèlú àwọn osisẹ tí o gbé kalẹ fún ìpínlẹ̀ Sokoto àti àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpínlẹ̀ míràn ní àríwá orílẹ̀-èdè wa fún ìdíje ipò Ààrẹ rẹ jẹ́ ọmọ ẹ̀yà igbo?

“Kilode tí àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣe máa gbà ẹ́ gbọ́, nígbà tí èmi kò fi ìgbà kankan gbọ kí o da IPOB (Indigenous People of Biafra) ati ESN lẹbi fún gbogbo àwọn àṣemáṣe tí wọ́n ṣe?” arákùnrin kan ló bere ìbéèrè yìí.

Ni idahun sí ìbéèrè náà, Obi sọ wí pé kò sí ọ̀nà bí òun yóò ṣe dá ESN lẹbi fún àwọn nǹkan tí wọn ṣe nítorí wí pé àwọn ìjọba Ìpínlẹ̀ gúúsù ila-oorun ni wọn dáa silẹ.

“Awon ìjọba ìpínlẹ̀ gúúsù ilà-oòrùn ló dá ESN sílẹ̀. Àwọn gómìnà Ìpínlẹ̀ gúúsù ila-oorun ló dá ikọ̀ ààbò náà sílẹ̀, kíló le fàá tí mo ma ṣe dá wọn lẹbi? Mo ti sọ̀rọ̀ nípa kónílé-ó-gbélé ọlọsọọsẹ ní gúúsù ìlà-oòrùn, àwọn ènìyàn sì ti mẹ́nuba orúkọ mi nípa ọ̀rọ̀ náà. Ẹ lọ ṣe ìwádìí òun gbogbo tí mo bá sọ.”

Àmọ́sá, ṣé òtítọ ni ọ̀rọ̀ yìí?

Iṣaridaju

Àyẹ̀wò ìwé ìròyìn TheCable fihàn pé ọgbẹni Nnamdi Kanu, adarí ẹgbẹ́ ajijagbara tí a mọ sí Indigenous People of Biafra (IPOB) ló dá ESN silẹ ní oṣù Kejìlá, ọdún 2020.

Ẹgbẹ́ IPOB ti Kanu dá sílẹ̀ ní ọdún 2012, ti pè fún idasilẹ orílẹ̀-èdè Biafra, ìjọba alàdáni fún àwọn ènìyàn gúúsù ila-oorun orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, lori àhesọ pé wọn kò ri ànfààní t’óyẹ jẹ láti ọ̀dọ̀ ìjọba àpapọ̀.

Ní ọjọ́ kẹtàlá, oṣù Kejìlá, ọdún 2020, Kanu kede idasilẹ ikọ̀ akọgun ESN. Ó sọ wí pé a dá ikọ̀ akọgun náà silẹ láti máa dàbobo àwọn ènìyàn gúúsù ilà-oòrùn orílẹ̀-èdè wa láti ọwọ́ àwọn agbesunmọmi àti àwọn ọ̀daràn míràn.

Ṣáájú àsìkò yìí, ìròhìn ti tànká orí ayélujára lóri bí àwọn darandaran Fulani ṣe ń kọlù oko ní gúúsù ilà-oòrùn.

Nínú ìkéde rẹ̀, Kanu fi ikọ̀ akọgun ESN wé ikọ̀ ẹ̀ṣọ́ aláàbò Amọtẹkun ni iwọ oòrùn gúúsù Nàìjíríà àti Miyetti-Allah ni àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Ó ní, aiṣedede àwọn gómìnà Ìpínlẹ̀ gúúsù ilà-oòrùn Nàìjíríà nípa ètò ààbò tó dájú fún àwọn ará ìlú ló fàá tí wọ́n fi dá ESN silẹ.

Ní ọdún 2021, àwọn gómìnà ìpínlẹ̀ gúúsù ilà-oòrùn ṣ’agbekalẹ ikọ̀ ẹ̀ṣọ́ aláàbò Ebube Agu, “lati gbógun ti ìwà ọ̀daràn ní agbègbè náà.”

Dave Umahi, gómìnà Ìpínlẹ̀ Ebonyi, tó tún jẹ́ alága ẹgbẹ́ àwọn gómìnà gúúsù ìlà-oòrùn sọ pé wọ́n da ìkọ aláàbò náà silẹ torí àìsí-ààbò tí ó ń burú sí ní agbègbè náà.

“Gbogbo wá ti fẹnukò láti fi ìmọ̀ ṣọ̀kan lórí ètò ààbò nì ilẹ̀ wa. Ikọ̀ ẹ̀ṣọ́ aláàbò tí a gbekalẹ fún gúúsù ilà-oòrùn ni a ń pé ní Ebube Agu. Olú ilé-isẹ ikọ̀ náà yóó wà ní ipinlẹ Enugu, láti ibi tí yóò ti máa darí ètò àbò káàkiri gúúsù ilà-oòrùn orílẹ̀-èdè wa,” Umahi ló sọ báyìí.

Àbájáde ìwádìí

Irọ àti isinilọna ni ọrọ ti Obi sọ nípa idasilẹ ESN. Ẹgbẹ́ ajijagbara IPOB ló dá ikọ̀ ẹ̀ṣọ́ aláàbò náà silẹ kìíse àwọn gómìnà Ìpínlẹ̀ gúúsù ila-oorun/ilẹ Igbo. Adijedupo fún Ipò Ààrẹ nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn osisẹ náà gbé idasilẹ IPOB àti ESN fún ara wọn.

TAGGED: ESN, Fact Check, Labour Party, peter obi

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo November 1, 2022 November 1, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Amupitan, INEC chair nominee, wasn’t part of Tinubu’s legal team at election tribunal

Some social media users claim that Joash Amupitan, the newly nominated chairman of the Independent…

October 11, 2025

Anambra guber: Offences that can get you arrested during elections in Nigeria

The Independent National Electoral Commission (INEC) has continually warned against vote-buying, ballot box snatching, underage…

October 9, 2025

Charly Boy yayi da’awar karya kan cewa Dan Nnamdi Kanu yaci gasar ‘kwakwalwa ta Duniya’

Charly Boy, mawakin Najeriya, ya yi ikirarin cewa dan Nnamdi Kanu, shugaban kungiyar masu fafutukar…

October 7, 2025

Charly Boy no tok true sey Nnamdi Kanu son win ‘international brain competition’

Charly Boy, chief Nigerian musician, don claim sey di son of Nnamdi Kanu, leader of…

October 7, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Charly Boy yayi da’awar karya kan cewa Dan Nnamdi Kanu yaci gasar ‘kwakwalwa ta Duniya’

Charly Boy, mawakin Najeriya, ya yi ikirarin cewa dan Nnamdi Kanu, shugaban kungiyar masu fafutukar kafa kasar Biafra (IPOB), yaci…

CHECK AM FOR WAZOBIA
October 7, 2025

Charly Boy no tok true sey Nnamdi Kanu son win ‘international brain competition’

Charly Boy, chief Nigerian musician, don claim sey di son of Nnamdi Kanu, leader of di proscribed Indigenous People of…

CHECK AM FOR WAZOBIA
October 7, 2025

Irọ́ ni Charly Boy pa pé ọmọ Nnamdi Kanu ọkùnrin ṣàṣeyọrí nínú ìdíje àwọn ọlọ́pọlọ pípé ní àgbáyé

Charly Boy, gbajúgbajà ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ti sọ pé ọmọkùnrin kan tó jẹ́ ọmọ Nnamdi Kanu, olórí Indigenous People…

CHECK AM FOR WAZOBIA
October 7, 2025

FACT CHECK: Report claiming police rescued 300 people in Kaduna building is from 2019

Several Facebook pages reported that the police command in Kaduna rescued 300 people from a house in the Rigasa community…

Fact Check
October 7, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?