TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjẹ́ lóòótọ́ ni pé wọ́n ti mú Naira Marley àti Sam Larry?
Share
Latest News
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027
FACT CHECK: Picture of Kwankwaso wearing cap with ‘Tinubu’s insignia’ photoshopped
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjẹ́ lóòótọ́ ni pé wọ́n ti mú Naira Marley àti Sam Larry?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published September 20, 2023 5 Min Read
Share

Atẹjade kan tí àwọn ènìyàn ń pín kiri lórí àwọn ohun ìgbàlódé ibaraẹnise ti sọ pé àwọn Ọlọpa ti mú Naira Marley, gbajúmọ̀ olórin àti Samson Balógun, agborinlarugẹ tí a fi bẹẹ mọ̀ sí Sam Larry lẹ́hìn ikú Mohbad, olórin gbajúgbajà.

“Ọwọ ti tẹ Naira Marley àti Sam Larry!! Wọn yóò sọ tẹnu wọn nípa ifiyajẹ tí wọ́n fi jẹ Mohbad,” báyìí ni atẹjade láti ọwọ @Mrklassiq_ ṣe wí.

Àwọn ènìyàn tí rí ọ̀rọ̀ yìí ní ọ̀nà mílíọ̀nù mẹ́ta àti ọọdunrun ẹgbẹ̀rún, wọ́n sì fẹ́ràn rẹ̀ ní ẹgbẹ̀rún ni ọna ọgbọn ó lé ní irinwo, wọ́n sì pín in ní ọna ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀ta ó lé ní méjìlélógún ní orí ibaraẹnise ẹlẹyẹ tí a mọ̀ sí X (tí a mọ̀ ṣí twitter tẹ́lẹ̀).

Lẹ́hìn X, a tún rí ọ̀rọ̀ tí ó jọ ọ̀rọ̀ yìí lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ níbi tí wọ́n ti sọ pé àwọn Ọlọpa ti mú Naira Marley àti Sam Larry.

Mohbad jẹ olórin tí Marlian Records ń gbé orin rẹ̀ jáde tẹ́lẹ̀rí. Naira Marley ni ó ni Marlian Records.

Mohbad kú ní ọjọ́ Kejìlá, ọdún 2023. Ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹtadinlọgbọn. Wọ́n sì sin ní ọjọ́ kejì.

Ikú rẹ̀ rú àwọn ènìyàn lójú. Ó sì ti fà àríyànjiyàn lórí àwọn ohun ìgbàlódé ibaraẹnise (social media) àti láàrin ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn tí kò sí ní orí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise.

Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹwàá, ọdún 2022, Mohbad pariwo lórí ibaraẹnise ẹlẹyẹ lórí nkan ti ó pè ní “ipalara” láti ọwọ Marlian Records.

“Nítorí pé mo fẹ́ paarọ ẹni tí ó ń ṣàkóso orin mi, wo ohun tí wọ́n ṣe fún mi ní ilé Marlian,” Ó tẹ ọrọ àwòrán tí ó ti fi ara pá jáde.

O sì tọrọ iranlọwọ nínú ọ̀rọ̀ yìí. Ó sì ní, “mò ń kú sára.”

Àwọn ènìyàn sọ pé awọn eniyan Marlian Record dẹrubaa léraléra, wọ́n sì ṣe ìpalára fún un ní àìmọye ìgbà títí di ìgbà tí ó fi kú.

Pẹtisọn (petition) kan tí ó dé ọwọ àwọn Ọlọpa ní ọjọ́ kẹtadinlọgbọn, oṣù kẹfà, ọdún 2023, ni a ti rí ní orí ayélujára. Nínú pẹtisọn yìí, Mohbad sọ ọ̀rọ̀ pé Sam Larry pa òhun lára, ó ba nkan òhun jẹ́, ó sì ń fi ajulọ han òhun. Ó fi pẹtisọn yìí ránṣẹ́ sí Force Criminal Investigation Department (FCID) Annex, tí ó wà ní Alagbọn ní ìlú Èkó (Lagos).

Sam Larry kò lo ohun ìgbàlódé ibi tí àwọn ènìyàn ti ń pín àwòrán ara wọn mọ́ nítorí ọ̀rọ̀ kobakungbe tí àwọn ènìyàn sọ síi nítorí pé wọ́n rò pé ohun ló ṣe ìpalára fún Mohbad, Naira Marley tí bẹ̀rẹ̀ sí ní pàdánù àwọn ènìyàn tí ó n tẹlee lórí àwọn ohun ìgbàlódé ibaraẹnise nítorí ọ̀rọ̀ yìí.

ÀWỌN AGBOFINRO KÒ TÍÌ MÚ NAIRA MARLEY ÀTI SAM LARRY

Àyẹ̀wò tí TheCable Newspaper, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe fi yé wa pé àwọn Ọlọpa kò tíì mú Naira Marley àti Sam Larry láti fi ọ̀rọ̀ wá wọn lẹnu wò nípa ikú Mohbad.

“Irọ́ ni ìròyìn yìí. Wọn kò tíì mú ẹni kankan,” Oluniyi Ogundeji, agbẹnusọ fún FCID ní ìlú Èkó ló sọ bayii.

TheCable ti ṣe atẹjade pé àwọn Ọlọpa ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí ikú akọrin náà.

Ní ọjọ́ Ajé, ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kẹsàn-án, ọdún 2023, àwọn ènìyàn mẹ́tàlá tí a kó jọ láti lè ṣe ìwádìí ọ̀rọ̀ náà sọ pé wọn máa wú òkú rẹ̀ láti lè mọ irú ikú tí ó paa.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Ọ̀rọ̀ tí ènìyàn kan sọ pé àwọn Ọlọpa ti mú Naira Marley àti Sam Larry kìí se òótọ́.

Ìwádìí sì ń lọ lọ́wọ́. Wọn kò tíì mú ẹni kankan.

TAGGED: Imole, Marlian Records, Mohbad, Naira Marley, Sam Larry

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael September 20, 2023 September 20, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025

FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?

A social media user has claimed that Francis Arinze, a Roman Catholic cardinal, is the…

April 21, 2025

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀…

April 20, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?