TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ju miliọnu kan àti ọọdunrun bí Ohanaeze se wí?
Share
Latest News
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Ǹjẹ́ Nàìjíríà dá àjọṣe lórí àwọn àlùmọ́ọ́nì láàárín òhun àti Amẹ́ríkà dúró nítorí visa?
Nigeria stop ‘mineral deal’ with US afta visa restriction?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ju miliọnu kan àti ọọdunrun bí Ohanaeze se wí?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published November 24, 2024 5 Min Read
Share

Ohanaeze Ndigbo, ẹgbẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n jẹ́ ígbò, sọ pé àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ẹgbẹ̀rún ni wọ́n wà nínú àwọn ẹ̀wọ̀n ní orílẹ̀ èdè India.

Okechukwu Isiguzoro, akọ̀wé ẹgbẹ́ yìí ló sọ báyìí nínú ọ̀rọ̀ tí ó sọ nígbà tí Nàìjíríà se ikinikaabọ fún Narendra Mordi, Ààrẹ India sí Nàìjíríà.

Isiguzoro sọ pé ẹ̀rí tó dájú wà fún ọ̀rọ̀ tí òhun sọ yìí. Ó ní iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ló pọ̀jù ní gbogbo àgbáyé.

“Ohun kan tí ó kọmilominu ni ipò àti ìyè àwọn ọmọ Nàìjíríà, tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ẹgbẹ̀rún tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n káàkiri Ìpínlẹ̀ mejidinlọgbọn tó wà ní India, èyí tí iye rẹ̀ pọ̀ jù ní orílẹ̀ èdè kọ̀ọ̀kan ní àgbáyé,” Isiguzoro ló sọ báyìí.

 Ó ní pé orílẹ̀ èdè Nàìjíríà àti India gbọ́dọ̀ wá nnkan se nípa ọ̀rọ̀ yìí. Ó fi ẹ̀sùn kan àwọn olórí ìjọba India pé wọ́n kàn máa ń ti àwọn ọmọ Nàìjíríà tí kò hu ìwà búburú mọ ẹ̀wọ̀n àti pé ọ̀rọ̀ yìí gbọ́dọ̀ jẹ́ ara àwọn ohun pàtàkì tí Ààrẹ Bọla Tinubu ti Nàìjíríà gbọ́dọ̀ bá Mordi sọ.

“A rọ Tinubu láti se ètò fún bí India yóò ṣe dárí ji àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India, kí wọ́n sì tú wọn sílẹ̀ kí àjọṣe gidi tó wà láàárín àwa àti India lè máa lọ síwájú síi,” báyìí ni akọ̀wé yìí se wí.

Akọ̀wé yìí sọ pé òhun sọ ọ̀rọ̀ yìí kí ẹ̀tọ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà máa baà di ohun tí àwọn ènìyàn ń tẹ̀ mọ́lẹ̀.

ǸJẸ́ ÀWỌN ỌMỌ NÀÌJÍRÍÀ TÍ WỌ́N JU MILIỌNU KÀN ÀTI ỌỌDUNRUN ẸGBẸ̀RÚN NI WỌ́N Ń SE Ẹ̀WỌ̀N NÍ INDIA?

Láti lè se àyẹ̀wò, TheCable Newspaper, ìwé ìròyìn orí ayélujára wo àwọn ọ̀rọ̀ tí wọ́n wà lórí National Prisons Information Portal (NPIP) tí India fi kọmputa (computer) ṣe agbekalẹ rẹ̀, eléyìí tí ó ní í se pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àwọn ẹ̀wọ̀n ní gbogbo India.

Gẹ́gẹ́bí ọ̀rọ̀ tí a rí lórí ohun ẹ̀rọ ìgbàlódé yìí se wí, wákàtí mẹ́rin-mẹ́rin ni wọ́n máa ń se àtúnse ọ̀rọ̀ orí kọmputa yìí. Ọ̀rọ̀ tí a rí lórí nǹkan yìí fi iye àwọn ènìyàn tí wọ́n wà ní ẹ̀wọ̀n ní gbogbo ẹ̀wọ̀n India ye wa. 

Ayẹwo fínnífínní tí a se fi ye wa pé àwọn Ìpínlẹ̀ marunlelogun nínú Ìpínlẹ̀ méjìdínlógún tó wà ní India ni àwọn ọmọ Nàìjíríà ti ń se ẹ̀wọ̀n.

Ní ogunjọ, oṣù kọkànlá, ọdún 2024, àyẹ̀wò tí a se fi hàn wá pé ẹẹdẹgbẹta àti mẹrindinlọgbọn àti ẹẹdẹgbẹta ó lé ní ọgọ́ta àti mẹsan ènìyàn ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India. Iye àwọn ènìyàn yìí tí wọ́n jẹ́ ọmọ Nàìjíríà jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ní mẹtalelọgbọn.

Ìpínlẹ̀ Manipur ní ó ní iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n se ẹ̀wọ̀n tó pọ̀ jù ní India. Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní Manipur jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan àti mẹsan. Ọmọ Nàìjíríà kan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Ìpínlẹ̀ kan tí wọ́n ń pè ní Meghalaya, ọmọ Nàìjíríà kan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Andhra Pradesh, ìkan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Assam, ìkan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Puducherry. Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ní ọdún 2015 jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan àti ọgọ́rùn-ún, eleyii tí ó túmọ̀ sí pé iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ti lé síi gẹ́gẹ́bí Ajjampur Ghanashyam, asojú India ní Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ se wí.

Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí Isiguzoro sọ pé wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India kéré gan-an sí iye tí a rí lórí komputa àwọn tó ń ṣètò ẹ̀wọ̀n ní India.

BÍ A SE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ ṢÍ

Ọ̀rọ̀ tí Isiguzoro sọ pé àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India kìí se òótọ́. Ahesọ lásán-làsàn ni.

Ọ̀rọ̀ tí ìjọba India fi ye wa nípa ọ̀rọ̀ yìí sọ pé ọmọ Nàìjíríà ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ní mẹtalelọgbọn ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India.

TAGGED: Fact Check, Fact check in Yoruba, India Prisons, News in Yorùbá, Nigerians, Ohanaeze

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael December 7, 2024 November 24, 2024
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative…

July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?