TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ju miliọnu kan àti ọọdunrun bí Ohanaeze se wí?
Share
Latest News
FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ju miliọnu kan àti ọọdunrun bí Ohanaeze se wí?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published November 24, 2024 5 Min Read
Share

Ohanaeze Ndigbo, ẹgbẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n jẹ́ ígbò, sọ pé àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ẹgbẹ̀rún ni wọ́n wà nínú àwọn ẹ̀wọ̀n ní orílẹ̀ èdè India.

Okechukwu Isiguzoro, akọ̀wé ẹgbẹ́ yìí ló sọ báyìí nínú ọ̀rọ̀ tí ó sọ nígbà tí Nàìjíríà se ikinikaabọ fún Narendra Mordi, Ààrẹ India sí Nàìjíríà.

Isiguzoro sọ pé ẹ̀rí tó dájú wà fún ọ̀rọ̀ tí òhun sọ yìí. Ó ní iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ló pọ̀jù ní gbogbo àgbáyé.

“Ohun kan tí ó kọmilominu ni ipò àti ìyè àwọn ọmọ Nàìjíríà, tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ẹgbẹ̀rún tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n káàkiri Ìpínlẹ̀ mejidinlọgbọn tó wà ní India, èyí tí iye rẹ̀ pọ̀ jù ní orílẹ̀ èdè kọ̀ọ̀kan ní àgbáyé,” Isiguzoro ló sọ báyìí.

 Ó ní pé orílẹ̀ èdè Nàìjíríà àti India gbọ́dọ̀ wá nnkan se nípa ọ̀rọ̀ yìí. Ó fi ẹ̀sùn kan àwọn olórí ìjọba India pé wọ́n kàn máa ń ti àwọn ọmọ Nàìjíríà tí kò hu ìwà búburú mọ ẹ̀wọ̀n àti pé ọ̀rọ̀ yìí gbọ́dọ̀ jẹ́ ara àwọn ohun pàtàkì tí Ààrẹ Bọla Tinubu ti Nàìjíríà gbọ́dọ̀ bá Mordi sọ.

“A rọ Tinubu láti se ètò fún bí India yóò ṣe dárí ji àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India, kí wọ́n sì tú wọn sílẹ̀ kí àjọṣe gidi tó wà láàárín àwa àti India lè máa lọ síwájú síi,” báyìí ni akọ̀wé yìí se wí.

Akọ̀wé yìí sọ pé òhun sọ ọ̀rọ̀ yìí kí ẹ̀tọ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà máa baà di ohun tí àwọn ènìyàn ń tẹ̀ mọ́lẹ̀.

ǸJẸ́ ÀWỌN ỌMỌ NÀÌJÍRÍÀ TÍ WỌ́N JU MILIỌNU KÀN ÀTI ỌỌDUNRUN ẸGBẸ̀RÚN NI WỌ́N Ń SE Ẹ̀WỌ̀N NÍ INDIA?

Láti lè se àyẹ̀wò, TheCable Newspaper, ìwé ìròyìn orí ayélujára wo àwọn ọ̀rọ̀ tí wọ́n wà lórí National Prisons Information Portal (NPIP) tí India fi kọmputa (computer) ṣe agbekalẹ rẹ̀, eléyìí tí ó ní í se pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àwọn ẹ̀wọ̀n ní gbogbo India.

Gẹ́gẹ́bí ọ̀rọ̀ tí a rí lórí ohun ẹ̀rọ ìgbàlódé yìí se wí, wákàtí mẹ́rin-mẹ́rin ni wọ́n máa ń se àtúnse ọ̀rọ̀ orí kọmputa yìí. Ọ̀rọ̀ tí a rí lórí nǹkan yìí fi iye àwọn ènìyàn tí wọ́n wà ní ẹ̀wọ̀n ní gbogbo ẹ̀wọ̀n India ye wa. 

Ayẹwo fínnífínní tí a se fi ye wa pé àwọn Ìpínlẹ̀ marunlelogun nínú Ìpínlẹ̀ méjìdínlógún tó wà ní India ni àwọn ọmọ Nàìjíríà ti ń se ẹ̀wọ̀n.

Ní ogunjọ, oṣù kọkànlá, ọdún 2024, àyẹ̀wò tí a se fi hàn wá pé ẹẹdẹgbẹta àti mẹrindinlọgbọn àti ẹẹdẹgbẹta ó lé ní ọgọ́ta àti mẹsan ènìyàn ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India. Iye àwọn ènìyàn yìí tí wọ́n jẹ́ ọmọ Nàìjíríà jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ní mẹtalelọgbọn.

Ìpínlẹ̀ Manipur ní ó ní iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n se ẹ̀wọ̀n tó pọ̀ jù ní India. Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní Manipur jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan àti mẹsan. Ọmọ Nàìjíríà kan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Ìpínlẹ̀ kan tí wọ́n ń pè ní Meghalaya, ọmọ Nàìjíríà kan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Andhra Pradesh, ìkan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Assam, ìkan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Puducherry. Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ní ọdún 2015 jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan àti ọgọ́rùn-ún, eleyii tí ó túmọ̀ sí pé iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ti lé síi gẹ́gẹ́bí Ajjampur Ghanashyam, asojú India ní Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ se wí.

Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí Isiguzoro sọ pé wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India kéré gan-an sí iye tí a rí lórí komputa àwọn tó ń ṣètò ẹ̀wọ̀n ní India.

BÍ A SE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ ṢÍ

Ọ̀rọ̀ tí Isiguzoro sọ pé àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India kìí se òótọ́. Ahesọ lásán-làsàn ni.

Ọ̀rọ̀ tí ìjọba India fi ye wa nípa ọ̀rọ̀ yìí sọ pé ọmọ Nàìjíríà ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ní mẹtalelọgbọn ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India.

TAGGED: Fact Check, Fact check in Yoruba, India Prisons, News in Yorùbá, Nigerians, Ohanaeze

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael December 7, 2024 November 24, 2024
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?

A viral post claims, based on International Monetary Fund (IMF) projections, that Nigeria ranks fourth…

May 9, 2025

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025

FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?

A social media user has claimed that Francis Arinze, a Roman Catholic cardinal, is the…

April 21, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?