TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Wọn ṣe àyípadà fídíò ifọrọwani-niẹnuwo pẹ̀lú Bill Gates lórí ọ̀rọ̀ abẹrẹ kofiidi ni
Share
Latest News
FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Wọn ṣe àyípadà fídíò ifọrọwani-niẹnuwo pẹ̀lú Bill Gates lórí ọ̀rọ̀ abẹrẹ kofiidi ni

Yemi Michael
By Yemi Michael Published April 23, 2023 5 Min Read
Share

Fídíò kan tí Bill Gates wà nínú rẹ̀ nígbà tí wọn ṣe ifọrọwani-ni-ẹnuwo pẹ̀lú rẹ̀ lórí ẹ̀rọ amohunmaworan orílẹ̀-èdè Australia tí a mọ̀ sí Australian Broadcasting Corporation (ABC) News ni àwọn ènìyàn ti se àyípadà rẹ̀ pẹlu ẹ̀rọ ìgbàlódé, tí wọ́n sì pa irọ́ lórí ọrọ abẹrẹ (vaccine) àti maikrosọfti (Microsoft).

Àwọn ènìyàn pín fídíò yìí ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ lórí ẹ̀rọ abẹyẹfo (Twitter) àti ẹ̀rọ tí a ti ń pín àwòrán ara ẹni (Instagram).

Olumulo ẹ̀rọ náà tí a mọ̀ sí @meekystudios pin fídíò náà pẹ̀lú àkòrí: “eléyìí ya ni lẹ́nu, níbo ni arábìnrin yìí tí ó ń sọ ọ̀rọ̀ tí ó pé ojú òṣùwọ̀n ti wà tí ó mú Bill Gates, ẹni tí ó lowo jù ni gbogbo àgbáyé tẹ́lẹ̀rí tí ó fi ń fikan pe méjì.”

Àwọn ènìyàn fẹ́ràn atẹjade náà ní ọna ẹgbẹ̀rún méjìdínlọgbon àti ọgọ́rùn-ún, wọn sì sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ọna ẹgbẹ̀ta àti mẹ́rìnlá. Wọn s’atunpin rẹ̀ ní ọna ẹgbẹfa àti mẹ́ta.

Olumulo míràn tí a mọ̀ sí @fqryonline s’atunpin fídíò náà lórí ẹrọ tí àwọn ènìyàn tí ń pín àwòrán ara wọn. Àwọn ènìyàn fẹ́ràn fídíò náà ní ọna tí ó ju ọgọ́rùn-ún ẹgbẹ̀rún. Wọn pín in ní ọna ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó dín mẹjọ.

Nínú fídíò náà, Sarah Ferguson, onisẹ ìròyìn ń fi ọ̀rọ̀ wá Bill Gates, oludasilẹ maikrosọfti lẹnuwo.

“Arákùnrin Gates, kí ni ó ti gbé ṣe fún àgbáyé?”, ó dàbí pé arábìnrin náà bi.

“N kò lérò pé ó mọ̀. Amọsa, èmi ni mo dá òun tí a fi máa ń lo kọnputa (computer operating system) silẹ.” O dàbí pé Gates fèsì báyìí

Lẹ́hìn ìgbà tí wọ́n fi ẹ̀sùn jiji nkan tí wọn fi máa ń lo kọnputa kan, olufiọrọwani-ni-ẹnuwo náà bèrè àwọn ìbéèrè tí ó ń mú ara fi ẹni lórí àrùn kofiidi (Covid19), ní ọna tí ó fi yé wa pé Gates jẹ́ nínú ọ̀rọ̀ abẹrẹ.

Ohùn kan tí ó dàbí tí olufiọrọwani-ni-ẹnuwo tún se ìbéèrè pé: “ìwọ ti jẹ́ agbẹnusọ nípa abẹrẹ kofiidi nígbà ajakalẹ àrùn yìí, kí ni ìdí gangan tí ó jẹ́ kí ìwọ tí o jẹ́ onímọ̀ ẹ̀rọ kọnputa tí kò ṣe agbekalẹ ètò isẹ ọwọ rẹ̀ fi di agbẹnusọ àwọn tí ó ń po òògùn?”

Atẹjade náà fi yé wa pé Gates fèsì pé “mo ti ka ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwé nípa ọ̀rọ̀ yìí, mo sì ti rí àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa ọ̀rọ̀ yii káàkiri àgbáyé,” ohùn Gates ni ó dàbí pé ó fèsì.

Ni ìparí ifọrọwani-niẹnuwo náà, àwọn ènìyàn lè gbọ́ ohùn arábìnrin afọrọwanilẹnuwo náà bí ó se bèrè nípa ìwà tó kudiẹkaato tí ó jẹ́ kí Gates máa jí àwọn ohùn ẹ̀rọ kọnputa tí ó le tí “kò yé e, tí ó sì ta ohùn ẹ̀rọ kọnputa tí ó pani lára, tí ó sì ba nkan jẹ́ tí ó sì rí èrè yanturu nínú rẹ̀.”

ISARIDAJU

Nígbà tí a ka àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn ènìyàn sọ nípa ọ̀rọ̀ yìí lórí àwọn ohùn ibaraẹnise tí ìgbàlódé níbi tí wọn ti pín ọ̀rọ̀ náà, a ríi pé àwọn tí wọn wòó tàbí ríi kò mọ̀ pé wọn yí ọ̀rọ̀ náà padà.

Olumulo àwọn ohùn ibaraẹnise tí ìgbàlódé kan tí ó ti rí ifọrọwani-niẹnuwo gidi yìí pé àkíyèsí àwọn ènìyàn sì ọ̀rọ̀ náà pé fídíò yìí tí ó jẹ́ gidi kò ní ọ̀rọ̀ nípa abẹrẹ kofiidi àti maikrosọfti nínú.

Ìwé ìròyìn TheCable fi kókó ọ̀rọ̀ inú fídíò náà ṣe ayẹwo rẹ̀. A ríi fídíò gidi ọ̀rọ̀ náà tí ilé isẹ ìròyìn amohunmaworan ABC ti orílẹ̀-èdè Australia gbé jáde tí wọn pè ní “7.30”

Ayẹwo TheCable fi  yé wa pé kò sí àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn ènìyàn s’atẹjade tàbí s’atunpin nínú fídíò yii tí ó jẹ́ gidi.

Nínú ifọrọwani-niẹnuwo gidi nípa ọ̀rọ̀ yìí tí a rí, afọrọwani-ni-ẹnuwo tí ó ṣeé mẹ́nuba àyípadà wẹda, sise iranlọwọ fún àwọn ènìyàn, sísọ ọ̀rọ̀ tí kìí se òtítọ́ àti wàhálà tí ajakalẹ àrùn míràn lè fà àti ajọjẹ Gates pẹ̀lú arákùnrin Jeffrey Epstein.

Nígbà tí TheCable tún se ayẹwo fídíò náà síwájú sí, a ríi wí pé ifọrọwani-niẹnuwo náà tí ó jẹ́ ohùn lásán kò jọ ohùn afọrọwani-ni-ẹnuwo arábìnrin Ferguson  àti Gates.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ NÁÀ SÌ

Àwọn ènìyàn tí ṣe àyípadà sì fídíò tí wọn ń pín kiri yìí. Wọn sì ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ irọ́ kún un. Fídíò ọ̀rọ̀ náà tí ó jẹ́ gidi yàtọ̀ sí èyí tí àwọn ènìyàn fi irọ́ púpọ̀ kún.

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael April 23, 2023 April 23, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?

A viral post claims, based on International Monetary Fund (IMF) projections, that Nigeria ranks fourth…

May 9, 2025

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025

FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?

A social media user has claimed that Francis Arinze, a Roman Catholic cardinal, is the…

April 21, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?