TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Wọn ṣe àyípadà fídíò ifọrọwani-niẹnuwo pẹ̀lú Bill Gates lórí ọ̀rọ̀ abẹrẹ kofiidi ni
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Wọn ṣe àyípadà fídíò ifọrọwani-niẹnuwo pẹ̀lú Bill Gates lórí ọ̀rọ̀ abẹrẹ kofiidi ni

Yemi Michael
By Yemi Michael Published April 23, 2023 5 Min Read
Share

Fídíò kan tí Bill Gates wà nínú rẹ̀ nígbà tí wọn ṣe ifọrọwani-ni-ẹnuwo pẹ̀lú rẹ̀ lórí ẹ̀rọ amohunmaworan orílẹ̀-èdè Australia tí a mọ̀ sí Australian Broadcasting Corporation (ABC) News ni àwọn ènìyàn ti se àyípadà rẹ̀ pẹlu ẹ̀rọ ìgbàlódé, tí wọ́n sì pa irọ́ lórí ọrọ abẹrẹ (vaccine) àti maikrosọfti (Microsoft).

Àwọn ènìyàn pín fídíò yìí ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ lórí ẹ̀rọ abẹyẹfo (Twitter) àti ẹ̀rọ tí a ti ń pín àwòrán ara ẹni (Instagram).

Olumulo ẹ̀rọ náà tí a mọ̀ sí @meekystudios pin fídíò náà pẹ̀lú àkòrí: “eléyìí ya ni lẹ́nu, níbo ni arábìnrin yìí tí ó ń sọ ọ̀rọ̀ tí ó pé ojú òṣùwọ̀n ti wà tí ó mú Bill Gates, ẹni tí ó lowo jù ni gbogbo àgbáyé tẹ́lẹ̀rí tí ó fi ń fikan pe méjì.”

Àwọn ènìyàn fẹ́ràn atẹjade náà ní ọna ẹgbẹ̀rún méjìdínlọgbon àti ọgọ́rùn-ún, wọn sì sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ọna ẹgbẹ̀ta àti mẹ́rìnlá. Wọn s’atunpin rẹ̀ ní ọna ẹgbẹfa àti mẹ́ta.

Olumulo míràn tí a mọ̀ sí @fqryonline s’atunpin fídíò náà lórí ẹrọ tí àwọn ènìyàn tí ń pín àwòrán ara wọn. Àwọn ènìyàn fẹ́ràn fídíò náà ní ọna tí ó ju ọgọ́rùn-ún ẹgbẹ̀rún. Wọn pín in ní ọna ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó dín mẹjọ.

Nínú fídíò náà, Sarah Ferguson, onisẹ ìròyìn ń fi ọ̀rọ̀ wá Bill Gates, oludasilẹ maikrosọfti lẹnuwo.

“Arákùnrin Gates, kí ni ó ti gbé ṣe fún àgbáyé?”, ó dàbí pé arábìnrin náà bi.

“N kò lérò pé ó mọ̀. Amọsa, èmi ni mo dá òun tí a fi máa ń lo kọnputa (computer operating system) silẹ.” O dàbí pé Gates fèsì báyìí

Lẹ́hìn ìgbà tí wọ́n fi ẹ̀sùn jiji nkan tí wọn fi máa ń lo kọnputa kan, olufiọrọwani-ni-ẹnuwo náà bèrè àwọn ìbéèrè tí ó ń mú ara fi ẹni lórí àrùn kofiidi (Covid19), ní ọna tí ó fi yé wa pé Gates jẹ́ nínú ọ̀rọ̀ abẹrẹ.

Ohùn kan tí ó dàbí tí olufiọrọwani-ni-ẹnuwo tún se ìbéèrè pé: “ìwọ ti jẹ́ agbẹnusọ nípa abẹrẹ kofiidi nígbà ajakalẹ àrùn yìí, kí ni ìdí gangan tí ó jẹ́ kí ìwọ tí o jẹ́ onímọ̀ ẹ̀rọ kọnputa tí kò ṣe agbekalẹ ètò isẹ ọwọ rẹ̀ fi di agbẹnusọ àwọn tí ó ń po òògùn?”

Atẹjade náà fi yé wa pé Gates fèsì pé “mo ti ka ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwé nípa ọ̀rọ̀ yìí, mo sì ti rí àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa ọ̀rọ̀ yii káàkiri àgbáyé,” ohùn Gates ni ó dàbí pé ó fèsì.

Ni ìparí ifọrọwani-niẹnuwo náà, àwọn ènìyàn lè gbọ́ ohùn arábìnrin afọrọwanilẹnuwo náà bí ó se bèrè nípa ìwà tó kudiẹkaato tí ó jẹ́ kí Gates máa jí àwọn ohùn ẹ̀rọ kọnputa tí ó le tí “kò yé e, tí ó sì ta ohùn ẹ̀rọ kọnputa tí ó pani lára, tí ó sì ba nkan jẹ́ tí ó sì rí èrè yanturu nínú rẹ̀.”

ISARIDAJU

Nígbà tí a ka àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn ènìyàn sọ nípa ọ̀rọ̀ yìí lórí àwọn ohùn ibaraẹnise tí ìgbàlódé níbi tí wọn ti pín ọ̀rọ̀ náà, a ríi pé àwọn tí wọn wòó tàbí ríi kò mọ̀ pé wọn yí ọ̀rọ̀ náà padà.

Olumulo àwọn ohùn ibaraẹnise tí ìgbàlódé kan tí ó ti rí ifọrọwani-niẹnuwo gidi yìí pé àkíyèsí àwọn ènìyàn sì ọ̀rọ̀ náà pé fídíò yìí tí ó jẹ́ gidi kò ní ọ̀rọ̀ nípa abẹrẹ kofiidi àti maikrosọfti nínú.

Ìwé ìròyìn TheCable fi kókó ọ̀rọ̀ inú fídíò náà ṣe ayẹwo rẹ̀. A ríi fídíò gidi ọ̀rọ̀ náà tí ilé isẹ ìròyìn amohunmaworan ABC ti orílẹ̀-èdè Australia gbé jáde tí wọn pè ní “7.30”

Ayẹwo TheCable fi  yé wa pé kò sí àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn ènìyàn s’atẹjade tàbí s’atunpin nínú fídíò yii tí ó jẹ́ gidi.

Nínú ifọrọwani-niẹnuwo gidi nípa ọ̀rọ̀ yìí tí a rí, afọrọwani-ni-ẹnuwo tí ó ṣeé mẹ́nuba àyípadà wẹda, sise iranlọwọ fún àwọn ènìyàn, sísọ ọ̀rọ̀ tí kìí se òtítọ́ àti wàhálà tí ajakalẹ àrùn míràn lè fà àti ajọjẹ Gates pẹ̀lú arákùnrin Jeffrey Epstein.

Nígbà tí TheCable tún se ayẹwo fídíò náà síwájú sí, a ríi wí pé ifọrọwani-niẹnuwo náà tí ó jẹ́ ohùn lásán kò jọ ohùn afọrọwani-ni-ẹnuwo arábìnrin Ferguson  àti Gates.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ NÁÀ SÌ

Àwọn ènìyàn tí ṣe àyípadà sì fídíò tí wọn ń pín kiri yìí. Wọn sì ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ irọ́ kún un. Fídíò ọ̀rọ̀ náà tí ó jẹ́ gidi yàtọ̀ sí èyí tí àwọn ènìyàn fi irọ́ púpọ̀ kún.

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael April 23, 2023 April 23, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?