TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Se ìwọ́de ẹgbẹ́ òsèlú PDP ní Ìpínlẹ̀ Ọsun ní wọn ti ya fọ́tò ogunlọgọ ènìyàn yìí?
Share
Latest News
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Ǹjẹ́ Nàìjíríà dá àjọṣe lórí àwọn àlùmọ́ọ́nì láàárín òhun àti Amẹ́ríkà dúró nítorí visa?
Nigeria stop ‘mineral deal’ with US afta visa restriction?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Se ìwọ́de ẹgbẹ́ òsèlú PDP ní Ìpínlẹ̀ Ọsun ní wọn ti ya fọ́tò ogunlọgọ ènìyàn yìí?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published July 26, 2022 4 Min Read
Share

Àwòrán kan tí ó se àfihàn ogunlọgọ ènìyàn tí wọn pé jọ sí ibi àpéjọ ẹgbẹ́  òsèlú Peoples Democratic Party ní Ìpínlẹ̀ Ọsun ń tán káàkiri orí ayélujára. 

Ni Ọjọ́bọ̀, ọjọ́ kẹrìnlá, osù keje, ọdún yìí, ẹgbẹ́ òsèlú PDP se ìwọ́de ní Ìpínlẹ̀ Ọsun ṣáájú ètò ìbò gómìnà tí ó wáyé ni ọjọ́ àbámẹ́ta, ọjọ́ kẹrìndínlógún, oṣù keje, ọdún yìí.

Abban Atiku, olùmúlò ìkànnì abẹ́yẹfò (Twitter), tí ó ń lo ọrọ idanimọ @abbalala3, ṣ’atunpin àwòrán náà pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ìfòrí yìí, “Ìpínlẹ̀ Ọsun kì ń se ẹgbẹ́ yín.”

Àwòrán náà se àfihàn ọ̀pọ̀lọpọ̀  ènìyàn tó wà ní òpópónà kan láàrín igi àti àwọn ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́. Àwọn olùmúlò ojú òpó náà bu ọwọ́ ìfẹ́ lùú ní ọ̀nà ọ̀run-dín-ní-okoo, wọ́n sì se àtúnpín rẹ̀ l’ọ̀nà ẹdẹgbẹta pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ìwòyè/èsì Ọgọ́rùn-ún dín ní ẹgbẹ̀ta ó lé àádọ́ta àti méjì.

Osun State no be your mate. pic.twitter.com/46lQ8sdRed

— Abban Atiku (@abbalala3) July 13, 2022

Ìwádìí l’órí ojú òpó abẹ́yẹfò rẹ̀ fihàn pé olùmúlò náà jẹ́ ọmọlẹ́yìn ẹgbẹ́ òsèlú PDP.

Àwòrán tó káàkiri orí ayélujára yìí gbé àhesọ pé àpéjọ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ PDP ni Ìpínlẹ̀ Òṣun jẹ àṣeyọrí.

Àwọn olùmúlò ojú òpó náà gbóríyìn fún ẹgbẹ́ òsèlú náà fún ọgọọrọ èrò tó wà níbi àpéjọ náà.

“Inú mi a dùn gaan tí èyí bá jẹ́ ìlú Ọsun nítorí mo fẹ́ràn PDP ní ìlọ́po mẹwàá ju àwọn olè ẹgbẹ́ òsèlú APC. Bí olùdíje ẹgbẹ́ òsèlú Labor Party, ẹgbẹ́ òsèlú àwọn osisẹ kò rí ipò náà gbà, ẹ fún sẹ́nétọ̀ oníjó láàyè. Àwọn ‘Obidients’, ọmọlẹ́yìn tàbí olùfẹ́ràn Peter Obi, Ólùdíje fún Ipò Ààrẹ nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òsìsẹ́, inú wọn á dùn fún Adeleke.” Olùmúlò ojú òpó kán kọ èyí sí ojú òpó rẹ̀.

“Tikẹẹti ọ̀fẹ́ láti wo Davido, ilumọka olórin àti àwọn eléré míràn yóò wà. Báwo ní àwọn ènìyàn kò se ní péjọ? Sẹ́nétọ̀ oníjó máa fi ijó dá àwọn ènìyàn lára yá. Ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú àwọn osisẹ  ni mo jẹ́, ṣùgbọ́n bí mo bá dé Ìpínlẹ̀ Ọsun ní ọla, máa lọ ṣe fàájì,” olùmúlò míràn dahùn báyìí.

Wọ́n se àtúnpín àtẹ̀jáde náà sí orí Facebook, ìkànnì ibaraẹniṣọrẹ.

Isaridaju

TheCable ṣe àyẹ̀wò àwòrán  at’ẹyin wá fún àwòrán yìí pẹ̀lú Labnol, oun àmúlò ìgbàlódé láti mọ orísun àwòrán yìí àti àwọn míràn tí ó jọọ́ láti fi ìdí òdodo múlẹ̀.

A ríi wí pé wọ́n ya àwòrán yìí ní Ilọrin, olú ìlú Ìpínlẹ̀ Kwara. Ahesọ ni àwòrán yìí. Ìwádìí kíkún fihàn pé wọ́n ya àwòrán yìí níbi ìrun iléyá tó wáyé ní Ìpínlẹ̀ Kwara, wọn fi àwòrán náà sí orí ayélujára ní ọjọ́ kẹsàn-án, oṣù keje.

Àwòrán náà wà ní ojú òpó ìjọba Ìpínlẹ̀ Kwara lórí ìkànnì abẹ́yẹfò pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ìfòrí yìí: “Àwọn olújọ́sìn ni Ilọrin ni ọjọ́ àbámẹ́ta jáde lọ̀pọ̀lọpọ̀ láti kirun iléyá pẹ̀lú Gómìnà AbdulRahman AbdulRasaq, tí ó n jẹ @RealAARahman ni orí abẹ́yẹfò, wọ́n se ètò ilẹ̀ fún àlàáfíà láti jọba ni ìlú nípasẹ̀ ibaṣepọ wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú alátakò #EidMubarak.”

Ìwádìí Ìwé Ìròyìn TheCable fi yé wa pé olùmúlò ìkànnì abẹ́yẹfò kan ni ó pín oríṣiríṣi àwòrán tí a yà nígbà àdúrà iléyá tó wáyé ní ìlú Ilọrin, èyí tó tún bọ̀ fi ìdí àyẹ̀wò ìwé ìròyìn yìí múlẹ̀ pé àwòrán yìí kò wá láti àpéjọ PDP ni ìlú Ọsun.

https://twitter.com/TheWorldCamera_/status/1546220740487282690?s=20&t=1r9OOyYdTzYBW0-Oip7yVw

Kwara State Eid Prayers today ❤️ pic.twitter.com/lbUldv0RIV

— Mohammed Jammal (@whitenigerian) July 9, 2022

Àbájáde ìwádìí 

Àwòrán tí ó ń sini lọ́nà ni àwòrán tí ó kálékáko yii tí ó se àfihàn ogunlọgọ ènìyàn ní ìwọ́de ẹgbẹ́ òsèlú PDP ní ìlú Ọ̀sun.

TAGGED: Fact Check, kwara, Labour Party, osun state, PDP

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo July 26, 2022 July 26, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative…

July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?