TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Se ìwọ́de ẹgbẹ́ òsèlú PDP ní Ìpínlẹ̀ Ọsun ní wọn ti ya fọ́tò ogunlọgọ ènìyàn yìí?
Share
Latest News
FACT CHECK: Video wey show sey gunmen bin seize armoured vehicles na for Burkina Faso — NO BE Nigeria
FACT CHECK: Video showing people using ropes to cross river NOT from Nigeria
Burkina Faso ni ìṣẹ̀lẹ̀ nínú fídíò tó sàfihàn àwọn agbébọn pẹ̀lú ọkọ̀ ogun jíjà ti ṣẹlẹ̀ — kìí se Nàìjíríà
Íhé ńgósị́ ébé ndị́ ómékómè nà-éwèghárá ụ́gbọ́àlà ndị́ ághá sì Burkina Faso
Bidiyon da ke nuna yan ta’adda na kwace motoci masu sulke daga Burkina Faso – BA Najeriya ba
FACT CHECK: Video showing gunmen seizing armoured vehicle from Burkina Faso — NOT Nigeria
Viral post wey claim sey dem don pass ‘Cybercrimes Act 2025’ no correct
Ózí na-ekwu nà é mepụ̀tálá ìwú megidere cybercrime bụ̀ àsị́
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Se ìwọ́de ẹgbẹ́ òsèlú PDP ní Ìpínlẹ̀ Ọsun ní wọn ti ya fọ́tò ogunlọgọ ènìyàn yìí?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published July 26, 2022 4 Min Read
Share

Àwòrán kan tí ó se àfihàn ogunlọgọ ènìyàn tí wọn pé jọ sí ibi àpéjọ ẹgbẹ́  òsèlú Peoples Democratic Party ní Ìpínlẹ̀ Ọsun ń tán káàkiri orí ayélujára. 

Ni Ọjọ́bọ̀, ọjọ́ kẹrìnlá, osù keje, ọdún yìí, ẹgbẹ́ òsèlú PDP se ìwọ́de ní Ìpínlẹ̀ Ọsun ṣáájú ètò ìbò gómìnà tí ó wáyé ni ọjọ́ àbámẹ́ta, ọjọ́ kẹrìndínlógún, oṣù keje, ọdún yìí.

Abban Atiku, olùmúlò ìkànnì abẹ́yẹfò (Twitter), tí ó ń lo ọrọ idanimọ @abbalala3, ṣ’atunpin àwòrán náà pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ìfòrí yìí, “Ìpínlẹ̀ Ọsun kì ń se ẹgbẹ́ yín.”

Àwòrán náà se àfihàn ọ̀pọ̀lọpọ̀  ènìyàn tó wà ní òpópónà kan láàrín igi àti àwọn ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́. Àwọn olùmúlò ojú òpó náà bu ọwọ́ ìfẹ́ lùú ní ọ̀nà ọ̀run-dín-ní-okoo, wọ́n sì se àtúnpín rẹ̀ l’ọ̀nà ẹdẹgbẹta pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ìwòyè/èsì Ọgọ́rùn-ún dín ní ẹgbẹ̀ta ó lé àádọ́ta àti méjì.

Osun State no be your mate. pic.twitter.com/46lQ8sdRed

— Abban Atiku (@abbalala3) July 13, 2022

Ìwádìí l’órí ojú òpó abẹ́yẹfò rẹ̀ fihàn pé olùmúlò náà jẹ́ ọmọlẹ́yìn ẹgbẹ́ òsèlú PDP.

Àwòrán tó káàkiri orí ayélujára yìí gbé àhesọ pé àpéjọ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ PDP ni Ìpínlẹ̀ Òṣun jẹ àṣeyọrí.

Àwọn olùmúlò ojú òpó náà gbóríyìn fún ẹgbẹ́ òsèlú náà fún ọgọọrọ èrò tó wà níbi àpéjọ náà.

“Inú mi a dùn gaan tí èyí bá jẹ́ ìlú Ọsun nítorí mo fẹ́ràn PDP ní ìlọ́po mẹwàá ju àwọn olè ẹgbẹ́ òsèlú APC. Bí olùdíje ẹgbẹ́ òsèlú Labor Party, ẹgbẹ́ òsèlú àwọn osisẹ kò rí ipò náà gbà, ẹ fún sẹ́nétọ̀ oníjó láàyè. Àwọn ‘Obidients’, ọmọlẹ́yìn tàbí olùfẹ́ràn Peter Obi, Ólùdíje fún Ipò Ààrẹ nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òsìsẹ́, inú wọn á dùn fún Adeleke.” Olùmúlò ojú òpó kán kọ èyí sí ojú òpó rẹ̀.

“Tikẹẹti ọ̀fẹ́ láti wo Davido, ilumọka olórin àti àwọn eléré míràn yóò wà. Báwo ní àwọn ènìyàn kò se ní péjọ? Sẹ́nétọ̀ oníjó máa fi ijó dá àwọn ènìyàn lára yá. Ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú àwọn osisẹ  ni mo jẹ́, ṣùgbọ́n bí mo bá dé Ìpínlẹ̀ Ọsun ní ọla, máa lọ ṣe fàájì,” olùmúlò míràn dahùn báyìí.

Wọ́n se àtúnpín àtẹ̀jáde náà sí orí Facebook, ìkànnì ibaraẹniṣọrẹ.

Isaridaju

TheCable ṣe àyẹ̀wò àwòrán  at’ẹyin wá fún àwòrán yìí pẹ̀lú Labnol, oun àmúlò ìgbàlódé láti mọ orísun àwòrán yìí àti àwọn míràn tí ó jọọ́ láti fi ìdí òdodo múlẹ̀.

A ríi wí pé wọ́n ya àwòrán yìí ní Ilọrin, olú ìlú Ìpínlẹ̀ Kwara. Ahesọ ni àwòrán yìí. Ìwádìí kíkún fihàn pé wọ́n ya àwòrán yìí níbi ìrun iléyá tó wáyé ní Ìpínlẹ̀ Kwara, wọn fi àwòrán náà sí orí ayélujára ní ọjọ́ kẹsàn-án, oṣù keje.

Àwòrán náà wà ní ojú òpó ìjọba Ìpínlẹ̀ Kwara lórí ìkànnì abẹ́yẹfò pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ìfòrí yìí: “Àwọn olújọ́sìn ni Ilọrin ni ọjọ́ àbámẹ́ta jáde lọ̀pọ̀lọpọ̀ láti kirun iléyá pẹ̀lú Gómìnà AbdulRahman AbdulRasaq, tí ó n jẹ @RealAARahman ni orí abẹ́yẹfò, wọ́n se ètò ilẹ̀ fún àlàáfíà láti jọba ni ìlú nípasẹ̀ ibaṣepọ wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú alátakò #EidMubarak.”

Ìwádìí Ìwé Ìròyìn TheCable fi yé wa pé olùmúlò ìkànnì abẹ́yẹfò kan ni ó pín oríṣiríṣi àwòrán tí a yà nígbà àdúrà iléyá tó wáyé ní ìlú Ilọrin, èyí tó tún bọ̀ fi ìdí àyẹ̀wò ìwé ìròyìn yìí múlẹ̀ pé àwòrán yìí kò wá láti àpéjọ PDP ni ìlú Ọsun.

https://twitter.com/TheWorldCamera_/status/1546220740487282690?s=20&t=1r9OOyYdTzYBW0-Oip7yVw

Kwara State Eid Prayers today ❤️ pic.twitter.com/lbUldv0RIV

— Mohammed Jammal (@whitenigerian) July 9, 2022

Àbájáde ìwádìí 

Àwòrán tí ó ń sini lọ́nà ni àwòrán tí ó kálékáko yii tí ó se àfihàn ogunlọgọ ènìyàn ní ìwọ́de ẹgbẹ́ òsèlú PDP ní ìlú Ọ̀sun.

TAGGED: Fact Check, kwara, Labour Party, osun state, PDP

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo July 26, 2022 July 26, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video wey show sey gunmen bin seize armoured vehicles na for Burkina Faso — NO BE Nigeria

Some pesin for social media don dey put Naija name on top one video wey…

September 3, 2025

FACT CHECK: Video showing people using ropes to cross river NOT from Nigeria

On August 9, a Facebook user identified as Asare Obed posted a video showing people…

September 3, 2025

Burkina Faso ni ìṣẹ̀lẹ̀ nínú fídíò tó sàfihàn àwọn agbébọn pẹ̀lú ọkọ̀ ogun jíjà ti ṣẹlẹ̀ — kìí se Nàìjíríà

Àwọn ènìyàn kan tí wọ́n ń lo ohun íbaraẹnise orí ayélujára tí sọ pé fidio…

September 2, 2025

Íhé ńgósị́ ébé ndị́ ómékómè nà-éwèghárá ụ́gbọ́àlà ndị́ ághá sì Burkina Faso

Ótù ihe ngosi ebe ndị ojiegbe egbu na-ákụ̀rụ́ ụgbọala ndị agha bụ nke ndị ji…

September 2, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

FACT CHECK: Video wey show sey gunmen bin seize armoured vehicles na for Burkina Faso — NO BE Nigeria

Some pesin for social media don dey put Naija name on top one video wey show some men wey mount…

CHECK AM FOR WAZOBIA
September 3, 2025

FACT CHECK: Video showing people using ropes to cross river NOT from Nigeria

On August 9, a Facebook user identified as Asare Obed posted a video showing people using ropes to cross a…

Fact Check
September 3, 2025

Burkina Faso ni ìṣẹ̀lẹ̀ nínú fídíò tó sàfihàn àwọn agbébọn pẹ̀lú ọkọ̀ ogun jíjà ti ṣẹlẹ̀ — kìí se Nàìjíríà

Àwọn ènìyàn kan tí wọ́n ń lo ohun íbaraẹnise orí ayélujára tí sọ pé fidio kan tí ó sàfihàn àwọn…

CHECK AM FOR WAZOBIA
September 2, 2025

Íhé ńgósị́ ébé ndị́ ómékómè nà-éwèghárá ụ́gbọ́àlà ndị́ ághá sì Burkina Faso

Ótù ihe ngosi ebe ndị ojiegbe egbu na-ákụ̀rụ́ ụgbọala ndị agha bụ nke ndị ji soshal midia ebipụta ozi sịrị…

CHECK AM FOR WAZOBIA
September 2, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?