TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Rárá, òògùn parasitamọ kò ní machupo virus
Share
Latest News
REVEALED: The social media accounts using AI videos to amplify pro-Traore propaganda
FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Rárá, òògùn parasitamọ kò ní machupo virus

Yemi Michael
By Yemi Michael Published August 21, 2023 5 Min Read
Share

Ọ̀rọ̀ kan tí àwọn ènìyàn ń pín lórí  ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọ̀rọ̀ (WhatsApp) ti gba àwọn ènìyàn ní amọran kí wọ́n má lo òògùn parasitamọ tí ó ní lẹta P àti nọ́mbà ẹẹdẹgbẹta. 

“Sọra. Má lo parasitamọ tí wọ́n kọ P-500 sára rẹ̀. Ó jẹ́ parasitamọ tuntun tí ó ń dán. Àwọn dọkita sọ pé ó ní “machupo” virus (kòkòrò àrùn), eléyìí tí wọ́n ní ó burú, tí ó sì lè ṣekú pani/pa ènìyàn,” báyìí ni ọ̀rọ̀ yìí ṣe wí.

Lẹ́hìn WhatsApp, a rí ọ̀rọ̀ yìí ní ori ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọ̀rọ̀.

“Ẹ jọ̀wọ́ pín ọ̀rọ̀ yìí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ mọ̀ àti àwọn ẹbí yín, kí ẹ sì rán wọn lọ́wọ́ láti wà láyé…mo ti ṣe ohun tí Ọlọ́run rán mi. Ẹ̀yin ló kàn. Ẹ rántí pé àwọn tí ó bá ran ara wọn lọ́wọ́ ni Ọlọ́run máa ń ràn lọ́wọ́. Ẹ pín ọ̀rọ̀ yìí,” bí ọ̀rọ̀ ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọ̀rọ̀ yìí ṣe wí nìyí.

Ọ̀rọ̀ yìí kò sọ fún wa bóyá wọ́n bèèrè lọ́wọ́ àwọn onímọ̀ nípa iṣẹ́ ìlera tàbí àwọn tí ó ń po òògùn kí wọ́n tó parí ọ̀rọ̀ yìí.

Egbògi parasitamọ jẹ́ òògùn tí a máa ń lò fún ara ríro. Àwọn dọkita máa n sọ pé kí àwọn tí ara bá ń ro tàbí ní ibà lo. Iye tí wọ́n máa ń ní kí àwọn àgbàlagbà lò ni ẹẹdẹgbẹta miligraamu tàbí graamu kan.

Machupo jẹ́ virus tí àwọn ènìyàn máa ń kó láti ara ẹran. Wọ́n tún máa ń pèé ní black typhus tàbí Bolivian hemorrhagic fever.

Àwọn ènìyàn kọ́kọ́ mọ̀ nípa ẹ ní ọdún 1959 ní orílẹ̀-èdè Bolivia. Orílẹ̀-èdè yìí tí ó wà ní South America (Gúúsù orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà) nìkan ni virus yìí tí ṣẹlẹ̀.

Gẹ́gẹ́bí Stanford Unifasiti ṣe wí, virus yìí máa ń tán ká lára nkan jíjẹ àti àwọn ohun tí a bá fi ara kàn tàbí fi ara kó.

Ǹjẹ́ virus yìí wa nínú parasitamọ?

ISARIDAJU

Ayẹwo tí TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára se fi yé wa pé àwọn ènìyàn tí ń pín ọ̀rọ̀ yìí kiri láti ọdún 2017. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ibi tí àwọn ènìyàn tí ń pín ọ̀rọ̀ ni wọ́n ti sọ pé irọ́ ni.

Ní ọdún 2017, àwọn eleto ìlera tí orílẹ̀-èdè Malaysia sọ pé kìí ṣe òótọ́.

Malaysia fi kún-un pé àwọn kò mọ̀ nípa ọ̀rọ̀ kankan nípa parasitamọ tí ó ní virus tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó mọ nípa òògùn ṣíṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.

Ní ọjọ́ keje, oṣù karùn-ún, àjọ tí ó ṣàkóso ọ̀rọ̀ ìlera ní orílẹ̀ èdè Zambia sọ pé ọ̀rọ̀ yìí tí àwọn ènìyàn ń pín lórí àwọn ohun ibaraẹnise kìí ṣe òtítọ́. Wọ́n fi kún un pé parasitamọ kò ní ohunkóhun ṣe pẹ̀lú virus yìí.

Nonso Odili, onímọ̀ bí a ṣe ń po egbògi/òògùn tí ó tún jẹ́ ọga ilé iṣẹ́ tí a mọ̀ sí DrugIT sọ fún TheCable pé irọ́ ni ọ̀rọ̀ yìí.

“Eléyìí tí pẹ. Ìgbà kan wà bí ọdún díẹ̀ sẹhin tí àwọn ènìyàn ti ń pín ọ̀rọ̀ yìí kiri. Ní ìgbà yìí, wọ́n sọ pé irọ́ ni.

“Ní ìgbà yẹn, WHO-World Health Organization, àjọ àgbáyé tí ó ń rí sí ọ̀rọ̀ ìlera àti NAFDAC-National Agency for Food and Drug Administration and Control, àwọn tí ó ń ṣàkóso ọ̀rọ̀ oúnjẹ àti òògùn ní Nàìjíríà kò sọ nkankan nípa ẹ, bóyá nítorí pé kò tó nkan tí ó tó sọ nkan nípa ẹ,” èyí ni èsì Nonso.

“Ó ṣe kókó kí àwọn ènìyàn máa lo oògùn tàbí àwọn ohun tí NAFDAC lọ́wọ́ sí.”

Nígbà tí ó ń dáhùn sì ọ̀rọ̀ yìí, Olusayo Akintola, agbẹnusọ fún NAFDAC sọ pé ọ̀rọ̀ yìí kìí ṣe ohun tí àwọn ènìyàn gbọ́dọ̀ kà sí nítorí pé kò sí aridaju ayẹwo kankan láti laabu (laboratory).

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÍ SÍ

Ọ̀rọ̀ tí àwọn ènìyàn sọ pé parasitamọ tí ó ní lẹta P àti nọ́mbà ẹẹdẹgbẹta lára ní machupo virus nínú kìí se òótọ́.

Àwọn ènìyàn ti pin-in ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní oríṣiríṣi orílẹ̀-èdè. Irọ́ gbáà ni.

TAGGED: Machupo virus, òògùn parasitamọ

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael August 21, 2023 August 21, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

REVEALED: The social media accounts using AI videos to amplify pro-Traore propaganda

Many social media accounts owned by young Africans have touted Ibrahim Traore, Burkina Faso's military…

May 17, 2025

FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?

A viral post claims, based on International Monetary Fund (IMF) projections, that Nigeria ranks fourth…

May 9, 2025

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?