TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ọ̀rọ̀ inú fídíò Tiktok tó sọ pé Ibrahim Traore sọ pé kí àwọn ará Burkina Faso má san owó orí kìí se òótọ́
Share
Latest News
FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ọ̀rọ̀ inú fídíò Tiktok tó sọ pé Ibrahim Traore sọ pé kí àwọn ará Burkina Faso má san owó orí kìí se òótọ́

Yemi Michael
By Yemi Michael Published April 17, 2025 5 Min Read
Share

Ẹni kan tí wọ́n ń pè ní @Panafrica069 lórí Tiktok, ohun ìgbàlódé ibaraẹnise tí àwọn ènìyàn ti máa ń fi àwòrán/fídíò síta, ti sọ pé Ibrahim Traore, olórí ijoba Ológun ni Orílẹ̀ èdè Burkina Faso tí sọ pé kí àwọn tó ń ṣòwò tàbí se ọ̀rọ̀ ajé má san owó orí.

Fídíò Tiktok tí ẹnì yìí fi síta ní ọjọ́ kini, oṣù kẹrin, ọdún 2025, ní ohùn ẹni kan tó ń sọ̀rọ̀ ní abẹlẹ pé Traore ti se ohun tí àwọn ènìyàn kò lè gbàgbé nítorí pé ó sọ orílẹ̀ èdè yìí di ibi tí àwọn ènìyàn kò ní máa san owó orí.

Fídíò yìí ní àkòrí tó sọ pé “Ibrahim Traore sọ pé àwọn ènìyàn kò gbọ́dọ̀ san owó orí ní Burkina Faso.” Àwọn ènìyàn tí pín ọ̀rọ̀ yìí ní ìgbà tó ju ẹgbẹ̀rún méje. Àwọn ènìyàn tó ju ẹgbẹ̀rún mọkandinlọgbọn ló fẹ́ràn ọ̀rọ̀ yìí. Àwọn ènìyàn tó lé ní ẹgbẹ̀rún méjì ló sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀.

Nínú fídíò yìí, a rí ẹni kan tí kò kìí se àkàròyìn gidi tó ń ka ìròyìn kan, ènìyàn kan síi n sọ̀rọ̀ ní abẹlẹ pẹ̀lú àwọn fídíò kan.

Ọ̀rọ̀ tí ẹnì yìí ń sọ ní abẹlẹ yìí sọ pé Elon Musk, ẹni tí ó ni X, ohun alámì krọọsi, tí a mọ̀ sí Twitter tẹ́lẹ̀, tí ó jẹ́ ohun ìgbàlódé ibaraẹnise, n ròó pé kí ohun gbé isẹ ohun lọ sí orílẹ̀ èdè yìí nítorí pé òhun kò ní san owó orí níbẹ̀.

Ọ̀rọ̀ abẹlẹ yìí tún sọ pé àwọn orílẹ̀ èdè kan fẹ́ fi ìyà jẹ Burkina Faso nítorí ọ̀rọ̀ owó orí yìí. Fídíò Tiktok yìí  tún se àfihàn àwọn fídíò mìíràn tí wọ́n sọ àwọn ohun kan tí Traore kò ṣe.

Láti oṣù kẹsàn-án, ọdún 2022, ti Traore tí gba ìjọba, àwọn ènìyàn ti fi àwọn ohun tí wọ́n kìí se òótọ́ àti àwọn ohun tó jẹ́ pé Traore kọ ló ṣe wọ́n sórí ayélujára láti lè jẹ́ kí àwọn ènìyàn rò pé ètò ìjọba ẹ dáa. Àwọn ènìyàn sọ pé ìṣẹ̀lẹ̀ yìí wáyé nítorí àwọn ohun tí àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè Russia fa níbi tí a mọ̀ sí Sahel.

AYẸWO Ọ̀RỌ̀ YÌÍ TÍ CABLECHECK SE RÈÉ 

Ara àwọn ohun tí ó wà nínú fídíò Tiktok yìí se àfihàn Traore níbi tí ó ti sọ̀rọ̀ níbi kan. Nígbà tí CableCheck lo Google Lens láti se àyẹ̀wò àwòrán yìí, a rí ìròyìn kan tí wẹbusaiti (website) Africa24TV fi síta.

Fídíò tí Traore wà nínú rẹ̀ yìí níbi tí ó ti ń sọ̀rọ̀ ní Academic Excellence Day, ti ọdún 2024, ní Burkina Faso, tó wáyé ní ọjọ́ kẹtalelogun, oṣù kẹjọ, ọdún 2024, ni wọ́n fi gbé ìròyìn náà jáde lórí Africa24TV.

A screenshot of the TikTok video

Àwọn ènìyàn lo fídíò Tiktok tí Traore ti sọ̀rọ̀ yìí láti jẹ́ kí ó dàbí pé Traore sọ pé kí àwọn ènìyàn má san owó orí. Nígbà tí ó ń sọ̀rọ̀ ní Academic Excellence Day, Traore kò sọ̀rọ̀ nípa owó orí. Ohun tí ó se ni pé ó gbóríyìn fún àwọn olùkọ́ ni Burkina Faso fún isẹ dáadáa tí wọ́n ṣe.

A screenshot of Traore on the Academic Excellence Day event

CableCheck tún ṣe àyẹ̀wò orí àwọn ohun ìgbàlódé ibaraẹnise tí ìjọba orílẹ̀ èdè Burkina Faso (Burkina Faso government social media accounts). A kò rí ọ̀rọ̀ tí ó sọ pé Traore sọ pé kí àwọn ènìyàn orílẹ̀ èdè náà má san owó orí.

Ní oṣù Kejìlá, ọdún 2024, ìjọba ológun tí Traore jẹ́ olórí rẹ̀ fi ọwọ sí ètò isuna ọdún 2025 (2025 Finance Act). Nínú ìwé òfin ètò isuna yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ètò owó orí àti àwọn àtúnṣe kan ló wà nínú rẹ̀.

Ara àwọn àtúnṣe yìí sọ pé láti oṣù kìíní, ọdún 2025, àwọn tí wọ́n ń ta nkan tàbí tí wọ́n ń ṣòwò lórí ayélujára yóò máa san owó orí.

BÍ A SE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ ṢÍ

Traore kò sọ pé àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè Burkina Faso kò níí san owó orí mọ.

TAGGED: Burkina Faso, factcheck, Factcheck in Yorùbá, Ibrahim Traore, News in Yorùbá, Tax, tax policy

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael April 17, 2025 April 17, 2025
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?

A viral post claims, based on International Monetary Fund (IMF) projections, that Nigeria ranks fourth…

May 9, 2025

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025

FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?

A social media user has claimed that Francis Arinze, a Roman Catholic cardinal, is the…

April 21, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?