TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Njẹ́ òtítọ́ ni pé bánkì àpapọ̀ Nàìjíríà fẹ́ gbé ẹgbẹ̀rún méjì àti márùn-ún náírà jáde?
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Njẹ́ òtítọ́ ni pé bánkì àpapọ̀ Nàìjíríà fẹ́ gbé ẹgbẹ̀rún méjì àti márùn-ún náírà jáde?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published November 19, 2022 5 Min Read
Share

Fọ́nrán kan tó ṣe àfihàn owó náírà ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rún márùn ni wọ́n ṣ’atunpin ní orí ayélujára.

Nínú fọ́nrán yìí ti wọ́n ṣ’atunpin sí orí ìkànnì abẹ́yẹfò (Twitter) l’ọ́jọ́ kẹtadinlọgbọn, oṣù kẹwa, a rí obìnrin kan tó ń ṣàfihàn ọ̀pọ̀lopọ̀ owó ti wọ́n tẹ N5,000 (ẹgbẹ̀rún márùn-ún náírà) àti N2,000 (ẹgbẹ̀rún méjì náírà) sí lára.

I hope this is a joke . pic.twitter.com/p8GM6YS1pA

— Dr Penking™🇳🇬🇦🇺 (@drpenking) October 27, 2022

Obìnrin tí a kò mọ orúkọ rẹ̀ yìí, sọ pé ọkùnrin ‘wèrè’ kan ló gbé owó náà wá sí ilé ìfowópamọ́ tí òun tí ń ṣiṣẹ́.

“Mo ní ìgbàgbọ́ pé àwàdà leleyii,” àkòrí yìí ni ènìyàn kan kọ sí ojú òpó rẹ̀ lẹ́yìn tí ó ṣ’atunpin fídíò náà. Àwọn olùmúlò ojú òpó wo fọ́nrán náà ní ìgbà ẹgbẹ̀rún mẹtalelọgbọn. Wọ́n sì bu ọwọ́ ìfẹ lùú ní ọna ẹgbẹ̀rún lé ní mejidinlọgbọn. Àwọn aṣàmúlò ìkànnì náà ṣ’atunpin fọ́nrán náà ní ìgbà ọdunrun lé ní ẹẹtadinlaadọrin.

Wọ́n ṣ’atunpin fọ́nrán náà sí orí ìkànnì tí àwọn ènìyàn ti lé pín àwòrán ara wọn (Instagram), ó sì wá ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ojú òpó l’órí ìkànnì ibaraẹnisọrẹ (Facebook), ọpọlọpọ àwọn ènìyàn tí kò fura sì ti fi èròngbà wọn hàn lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

Ní ọjọ́ kẹrindinlọgbọn, oṣù kẹwàá, ọdún yii,  Godwin Emefiele, Gómìnà banki àpapọ̀ orilẹ-ede Nàìjíríà sọ pé bánkì náà ti kéde pé yóò tẹ owó tuntun.

Emefiele ni owó tí bánkì náà ma tẹjade ni N200 (ìgbà náírà), N500 (ẹẹdẹgbẹta náírà) ati N1000 (ẹgbẹ̀rún náírà). Wọn yóò sì bẹ̀rẹ̀ síí kó owó náà jáde ní oṣù Kejìlá, ọdún yìí.

Gómìnà bánkì àpapọ̀ náà ṣàlàyé pé ìṣòro nípa ìṣàkóso ìṣúná owó orilẹ-ede yìí lo fàá tí bánkì ọ̀ún fi ṣe ìpinnu láti ṣe atuntẹ owó.

Iṣaridaju

TheCable lo Invid, irinṣẹ  ìgbàlódé tí a fi ń ṣe ìwòye fọ́nrán lórí ayélujára. Ìwádìí wà fihàn pé fọ́nrán náà ti wà lórí ayélujára pàápàá lórí ìkànnì ibaraẹnisọrẹ ati ìkànnì tí a ti ń wo àwòrán (YouTube) láti ọdún 2020.

A ríi wí pé àwòrán ọkùnrin kan tí ó wọ fìlà, wà ní apá kan owó pépà N5000 (ẹgbẹ̀rún márùn-ún náírà) ọun, àwòrán obìnrin mẹta wà ní apá kejì.

Ìwádìí wà fihàn pé ni ọdún 2012, bánkì àpapọ̀ orilẹ-ede Nàìjíríà kéde pé wọn yóò gbé owó náírà ẹgbẹ̀rún márùn jáde.

Sanusi Lamido, tí ó jẹ́ gómìnà bánkì àpapọ̀ nígbà náà, sọ pé àwòrán obìnrin mẹ́ta ni wọn yóò tẹ sára owó náírà náà. Àwọn obìnrin náà ni Ajijagbara Margaret Ekpo, olóṣèlú tó ti ṣe aláìsí; Hajia Gambo Sawaba, ajijagbara àti olóṣèlú tó ti ṣe aláìsí àti Funmilayo Kuti, olóṣèlú àti ẹni tí máa n já fún ẹ̀tọ́ àwọn obìnrin ní ìgbà ayé rẹ̀.

Lamido ṣàlàyé pé àtẹ̀jáde owó pépà náà yóò ṣe iranlọwọ fún owó náírà, a máa ṣe iranlọwọ fún àwọn tí kò riran dáadáa, yóò sì mú idinku ba ìdíyelé ṣíṣe atẹjade, pínpín àti kikokuronilẹ owó náírà.

Ṣùgbọ́n, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn lo tako ìpinnu yìí. Àjọ fún àwọn tí ó mọ nípa ìṣirò owó (Institute of Chartered Accountants of Nigeria-ICAN) sọ nígbà náà pé ṣíṣe àgbéjáde owó pépà ẹgbẹ̀rún márùn-ún náírà yóò mú ifasẹyin bá owó náírà.

Ìjọba àpapọ̀ ṣe ìdádúró ṣíṣe àgbéjáde owó pépà ẹgbẹ̀rún márùn-ún náírà náà láti jẹ́ kí “bánkì àpapọ̀ Nàìjíríà tan imọlẹ si ọrọ náà.”

Ní ọjọ́ kọkanlelọgbọn, oṣù Kàrún, ọdún 2020, bánkì àpapọ̀ Nàìjíríà kéde lori ìkànnì abẹ́yẹfò pé kí àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà má ṣe àkíyèsí àwòrán àti fọ́nrán èké tí àwọn ènìyàn kan ń pín káàkiri orí ayélujára nígbà náà.

“Ayédèrú fídíò àti àwòrán owó pépà ẹgbẹ̀rún méjì àti márùn náírà ni àwọn ènìyàn kan pín káàkiri orí ayélujára. Kí àwùjọ ẹ̀dá ma ṣe àkíyèsí àwọn ìròyìn èké yìí. Tí ẹ bá rí ẹnikẹ́ni tí ó ní owó náà lọ́wọ́, ẹ fi èyí tó àwọn ẹṣọ aláàbò létí,” èyí ní ọ̀rọ̀ ìwòye tí CBN kọ sí ojú òpó abẹ́yẹfò rẹ̀.

Videos and pictures of purported circulation of N2,000:00 and N5,000:00 banknotes are false and fake. Members of the public are advised to disregard such falsehood and to report anyone found in possession of such banknotes to the law enforcement agencies

— Central Bank of Nigeria (@cenbank) May 31, 2020

Fọ́nrán àtijọ́ náà ni àwọn ènìyàn pin káàkiri ayélujára lásìkò yìí ṣáájú àsìkò ti bánkì àpapọ̀ máa gbé owó náírà tuntun jáde ní oṣù Kejìlá, ọdún yìí.

Àmọ̀ṣá, bánkì àpapọ̀ nínú ìkéde rẹ̀ ṣàlàyé pé àwọn owó tí wọn yóò ṣe atuntẹ rẹ̀ ní N200, N500 ati N1000, bánkì àpapọ̀ náà kò kéde owó náírà ẹgbẹ̀rún méjì tàbí márùn kankan.

Àbájáde Ìwádìí

Ayédèrú ni fọ́nrán tí a pín kalekako tí ó gbé àhesọ pé ìjọba àpapọ̀ fẹ́ ṣe àgbéjáde owó pépà ẹgbẹ̀rún méjì àti márùún náírà. Asinilọna ni fídíò náà, ó ti wà lórí ayélujára láti ọdún 2020.

TAGGED: cbn, godwin emefiele, N2000, N5000, Naira redesign

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo November 19, 2022 November 19, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?