TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ilé ẹjọ́ kò sọ pé adijedupo nínú ẹgbẹ́ òsèlú òṣìṣẹ́ ni ó ṣe àṣeyọrí nínú idije Ipò Gómìnà Delta
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ilé ẹjọ́ kò sọ pé adijedupo nínú ẹgbẹ́ òsèlú òṣìṣẹ́ ni ó ṣe àṣeyọrí nínú idije Ipò Gómìnà Delta

Yemi Michael
By Yemi Michael Published September 8, 2023 4 Min Read
Share

Fídíò kan tí Olumulo kan tí a mọ̀ sí Hichief Sunny Odogwu lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ ti sọ pé ilé ẹjọ́ tí a gbekalẹ láti yanjú aawọ ìbò sọ pé Kennedy Pela, Ólùdíje nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ ni ó ṣe àṣeyọrí nínú ìbò Gómìnà ní ọdún 2023 ní Ìpínlẹ̀ Delta.

Wọ́n fi Fídíò ìṣẹ́jú mẹ́fà náà síta ní ọjọ́ kọkanlelọgbọn, oṣù kẹjọ.

“KÉRE O: Ilé ẹjọ́ kotẹmilọrun sọ wí pé Ken Pela, Ólùdíje fún Ipò Gómìnà nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ (Labor Party-LP) ni ó ṣe aseyege nínú ìdíje fún Ipò Gómìnà ní Ìpínlẹ̀ Delta,” báyìí ni àkòrí atẹjade tí àwọn ènìyàn wò/rí ní ìgbà ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin, tí wọ́n fèsì sí ní ọna igba ó lé ní ọgọ́ta àti mẹ́fà, tí wọ́n sì fẹ́ràn ní ọ̀nà ẹẹdegbèje ṣe wí.

Olumulo yìí sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n rí fídíò yìí kí wọn pín in.

ISARIDAJU

Nínú atẹjade tí kò pẹ sẹhin tí TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe, ilé ẹjọ́ kotẹmilọrun ní Abuja pàṣẹ pé kí ilé ẹjọ́ kan ní Ìpínlẹ̀ Delta tí a gbekalẹ láti yanjú àríyànjiyàn ìbò Gómìnà gbọ ẹjọ́ Pela.

The Independent National Electoral Commission (àjọ tí ó ń ṣàkóso ọ̀rọ̀ ìbò ní Nàìjíríà) sọ wí pé Sheriff Oborevwori, Ólùdíje nínú ẹgbẹ́ òsèlú Peoples Democratic Party (PDP) ni ó ṣe àṣeyọrí nínú ìbò tí a ṣe ni ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kẹta ní Ìpínlẹ̀ náà.

Ólùdíje yìí ní ìbò ọọdunrun ó lè ní òjìlénígba ó dín mẹ́fà tí ó sì fi ìdí Ovie Omo-Agege, Ólùdíje fún Ipò Gómìnà nínú ẹgbẹ́ òsèlú All Progressives Congress (APC), ẹni tí ó ní ìbò òjìlénígba àti ìgbà ó dín mọkandinlọgbọn rẹ mi.

Pela gbé ipò kẹta. Ó ní ìbò ẹgbẹrun mejidinlaaadọta ó lé ní mẹtadinlọgbọn nígbà tí Great Ogboru, Ólùdíje fún Ipò Gómìnà nínú ẹgbẹ́ òsèlú All Progressives Grand Alliance (APGA) ṣe ipò kẹrin pẹ̀lú ìbò ẹgbẹ̀rún mọ́kànlá ó lé ní ookanlelogun.

Pela àti ẹgbẹ́ Òṣèlú rẹ̀ kọ ìwé ipẹjọ láti lè sọ pé àwọn Ólùdíje yòókù tí wọ́n ṣe ipò Kínní ati èkejì tí a sì fi ẹ̀sùn afọwọra kan tí wọ́n ko sì tẹle òfin ìdìbò kò yẹ kí wọ́n kopa ninu ìdìbò náà.

Wọ́n ní kí ilé ẹjọ́ náà kéde Pela gẹ́gẹ́bí ẹni tí ó se àṣeyọrí tàbí kí wọ́n fagile ìbò náà kí wọ́n sì tún-un ṣe.

ÌDÁJỌ́ ILÉ ẸJỌ KOTẸMILỌRUN

Nígbà tí ilé ẹjọ́ kọ́kọ́ wo ẹjọ́ yìí, Damian Dodo, agbẹjọro fun Gómìnà àti igbakeji rẹ̀ sọ pé wọn tí pá ẹjọ́ ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ tì.

Ó ní wí pé olupẹjọ kò lo ọjọ́ méje tí òfin sọ fún ìpẹjo àkọ́kọ́ tí ó wáyé ní ọjọ́ kọkàndínlógún kí ìparí ẹjọ́ tó wáyé.

Asiwaju àwọn agbẹjọro fún Gómìnà àti igbakeji rẹ̀ sọ pé olupẹjọ pe ẹjọ́ tí wọ́n kọ́kọ́ ma gbọ ní ọjọ́ kọkàndínlógún, oṣù karùn-ún, kí ẹjọ́ tó wá sopin. Nípa ìdí èyí, ẹjọ́ tó pè yìí kò dáa tó. Ó yẹ kí a daanu ni.

C.H. Ahuchaogu, alaga àwọn tí ó ń jókòó lórí ẹjọ́ náà da ẹjọ́ náà ni nígbà tí ó ń ṣe ìdájọ́.

Ọ̀rọ̀ yìí bí Pela àti ẹgbẹ́ Òṣèlú àwọn òṣìṣẹ́ nínú. Wọ́n sì kọri sì ilé ẹjọ́ kotẹmilọrun.

Ni ọjọ́ kọkanlelọgbọn, oṣù kẹjọ, ilé ẹjọ́ kotẹmilọrun dáhùn sí ọ̀rọ̀ yìí. Wọ́n sì ní pe ki àwọn adajọ tún yẹ ọ̀rọ̀ náà wò.

BI A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Atẹjade tí ó sọ pé ilé ẹjọ́ tí a gbekalẹ láti yanjú aawọ ìbò sọ pé Pela ni ó ṣe àṣeyọrí gẹ́gẹ́bí Gómìnà nínú ìdíje fún Ipò Gómìnà Delta kìí ṣe òótọ́.

TAGGED: Delta Tribunal, Ken Pela

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael September 8, 2023 September 8, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?