TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ilé ẹjọ́ kò sọ pé adijedupo nínú ẹgbẹ́ òsèlú òṣìṣẹ́ ni ó ṣe àṣeyọrí nínú idije Ipò Gómìnà Delta
Share
Latest News
Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró
Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal
No, Nigeria no send peace support mission go Israel
A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba
Ǹjẹ́ Tinubu àti Alexander Zingman lọ sí ilé-ìwé kan náà? Èyí ni ohun tí a mọ̀
Tinubu nà Alexander Zingman ọ̀ gàrà ótù ụ́lọ̀ákwụ́kwọ́? Lèé íhé ányị́ mà
Tinubu go di same school wit Alexander Zingman? Na wetin we sabi be dis
Shin Tinubu ya halarci makaranta daya da Alexander Zingman? Ga abin da muka sani
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ilé ẹjọ́ kò sọ pé adijedupo nínú ẹgbẹ́ òsèlú òṣìṣẹ́ ni ó ṣe àṣeyọrí nínú idije Ipò Gómìnà Delta

Yemi Michael
By Yemi Michael Published September 8, 2023 4 Min Read
Share

Fídíò kan tí Olumulo kan tí a mọ̀ sí Hichief Sunny Odogwu lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ ti sọ pé ilé ẹjọ́ tí a gbekalẹ láti yanjú aawọ ìbò sọ pé Kennedy Pela, Ólùdíje nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ ni ó ṣe àṣeyọrí nínú ìbò Gómìnà ní ọdún 2023 ní Ìpínlẹ̀ Delta.

Wọ́n fi Fídíò ìṣẹ́jú mẹ́fà náà síta ní ọjọ́ kọkanlelọgbọn, oṣù kẹjọ.

“KÉRE O: Ilé ẹjọ́ kotẹmilọrun sọ wí pé Ken Pela, Ólùdíje fún Ipò Gómìnà nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ (Labor Party-LP) ni ó ṣe aseyege nínú ìdíje fún Ipò Gómìnà ní Ìpínlẹ̀ Delta,” báyìí ni àkòrí atẹjade tí àwọn ènìyàn wò/rí ní ìgbà ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin, tí wọ́n fèsì sí ní ọna igba ó lé ní ọgọ́ta àti mẹ́fà, tí wọ́n sì fẹ́ràn ní ọ̀nà ẹẹdegbèje ṣe wí.

Olumulo yìí sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n rí fídíò yìí kí wọn pín in.

ISARIDAJU

Nínú atẹjade tí kò pẹ sẹhin tí TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe, ilé ẹjọ́ kotẹmilọrun ní Abuja pàṣẹ pé kí ilé ẹjọ́ kan ní Ìpínlẹ̀ Delta tí a gbekalẹ láti yanjú àríyànjiyàn ìbò Gómìnà gbọ ẹjọ́ Pela.

The Independent National Electoral Commission (àjọ tí ó ń ṣàkóso ọ̀rọ̀ ìbò ní Nàìjíríà) sọ wí pé Sheriff Oborevwori, Ólùdíje nínú ẹgbẹ́ òsèlú Peoples Democratic Party (PDP) ni ó ṣe àṣeyọrí nínú ìbò tí a ṣe ni ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kẹta ní Ìpínlẹ̀ náà.

Ólùdíje yìí ní ìbò ọọdunrun ó lè ní òjìlénígba ó dín mẹ́fà tí ó sì fi ìdí Ovie Omo-Agege, Ólùdíje fún Ipò Gómìnà nínú ẹgbẹ́ òsèlú All Progressives Congress (APC), ẹni tí ó ní ìbò òjìlénígba àti ìgbà ó dín mọkandinlọgbọn rẹ mi.

Pela gbé ipò kẹta. Ó ní ìbò ẹgbẹrun mejidinlaaadọta ó lé ní mẹtadinlọgbọn nígbà tí Great Ogboru, Ólùdíje fún Ipò Gómìnà nínú ẹgbẹ́ òsèlú All Progressives Grand Alliance (APGA) ṣe ipò kẹrin pẹ̀lú ìbò ẹgbẹ̀rún mọ́kànlá ó lé ní ookanlelogun.

Pela àti ẹgbẹ́ Òṣèlú rẹ̀ kọ ìwé ipẹjọ láti lè sọ pé àwọn Ólùdíje yòókù tí wọ́n ṣe ipò Kínní ati èkejì tí a sì fi ẹ̀sùn afọwọra kan tí wọ́n ko sì tẹle òfin ìdìbò kò yẹ kí wọ́n kopa ninu ìdìbò náà.

Wọ́n ní kí ilé ẹjọ́ náà kéde Pela gẹ́gẹ́bí ẹni tí ó se àṣeyọrí tàbí kí wọ́n fagile ìbò náà kí wọ́n sì tún-un ṣe.

ÌDÁJỌ́ ILÉ ẸJỌ KOTẸMILỌRUN

Nígbà tí ilé ẹjọ́ kọ́kọ́ wo ẹjọ́ yìí, Damian Dodo, agbẹjọro fun Gómìnà àti igbakeji rẹ̀ sọ pé wọn tí pá ẹjọ́ ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ tì.

Ó ní wí pé olupẹjọ kò lo ọjọ́ méje tí òfin sọ fún ìpẹjo àkọ́kọ́ tí ó wáyé ní ọjọ́ kọkàndínlógún kí ìparí ẹjọ́ tó wáyé.

Asiwaju àwọn agbẹjọro fún Gómìnà àti igbakeji rẹ̀ sọ pé olupẹjọ pe ẹjọ́ tí wọ́n kọ́kọ́ ma gbọ ní ọjọ́ kọkàndínlógún, oṣù karùn-ún, kí ẹjọ́ tó wá sopin. Nípa ìdí èyí, ẹjọ́ tó pè yìí kò dáa tó. Ó yẹ kí a daanu ni.

C.H. Ahuchaogu, alaga àwọn tí ó ń jókòó lórí ẹjọ́ náà da ẹjọ́ náà ni nígbà tí ó ń ṣe ìdájọ́.

Ọ̀rọ̀ yìí bí Pela àti ẹgbẹ́ Òṣèlú àwọn òṣìṣẹ́ nínú. Wọ́n sì kọri sì ilé ẹjọ́ kotẹmilọrun.

Ni ọjọ́ kọkanlelọgbọn, oṣù kẹjọ, ilé ẹjọ́ kotẹmilọrun dáhùn sí ọ̀rọ̀ yìí. Wọ́n sì ní pe ki àwọn adajọ tún yẹ ọ̀rọ̀ náà wò.

BI A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Atẹjade tí ó sọ pé ilé ẹjọ́ tí a gbekalẹ láti yanjú aawọ ìbò sọ pé Pela ni ó ṣe àṣeyọrí gẹ́gẹ́bí Gómìnà nínú ìdíje fún Ipò Gómìnà Delta kìí ṣe òótọ́.

TAGGED: Delta Tribunal, Ken Pela

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael September 8, 2023 September 8, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró

Ìròyìn lati inú fídíò Facebook kan sọ pé Nàìjíríà fi àwọn ọmọ ogun ránṣẹ́ sí…

June 28, 2025

Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal

Ótù ihe ngosị si na Facebook kwuru na Naijiria zipụrụ ndị agha ka ha gaa…

June 28, 2025

No, Nigeria no send peace support mission go Israel

One Facebook video claim sey Nigeria send soldiers go Israel for joint peace support mission.…

June 28, 2025

A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba

Wani faifan bidiyo na Facebook ya nuna cewa Najeriya ta tura dakaru domin aikin hadin…

June 28, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró

Ìròyìn lati inú fídíò Facebook kan sọ pé Nàìjíríà fi àwọn ọmọ ogun ránṣẹ́ sí orílẹ̀ èdè Ísírẹ́lì kí rògbòdìyàn…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal

Ótù ihe ngosị si na Facebook kwuru na Naijiria zipụrụ ndị agha ka ha gaa kwàdó udo na mba Isreal.…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

No, Nigeria no send peace support mission go Israel

One Facebook video claim sey Nigeria send soldiers go Israel for joint peace support mission. One male broadcaster wey dey…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba

Wani faifan bidiyo na Facebook ya nuna cewa Najeriya ta tura dakaru domin aikin hadin gwiwa na tallafawa zaman lafiya…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?