TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Fídíò tí ó sọ pé Hakainde Hichilema, Ààrẹ orílẹ-èdè Zambia fẹ́ ṣe ìjọba lẹẹkeji kìí ṣe òótọ́
Share
Latest News
FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Fídíò tí ó sọ pé Hakainde Hichilema, Ààrẹ orílẹ-èdè Zambia fẹ́ ṣe ìjọba lẹẹkeji kìí ṣe òótọ́

Yemi Michael
By Yemi Michael Published October 17, 2023 4 Min Read
Share

Ẹgbẹ́ òsèlú kan tí a mọ̀ sí the United Party for National Development (UPND) tí sọ pé fídíò tí àwọn ènìyàn ń pín kiri tí ó sọ pé Hakainde Hichilema, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Zambia kò ní díje fún Ipò Ààrẹ ní ẹẹkeji ní ọdún 2026 kìí ṣe òótọ́. 

Nínú fídíò náà, èyí tí àwọn ènìyàn pín kiri, Hichilema wọ suutu nínú àwòrán tí asia orílẹ̀-èdè Zambia wà ní abẹlẹ rẹ̀ níbi tí ó ti ń ṣe ìkéde pé òhun kò ní díje ní ẹẹkeji nínú ìbò gbogbogbo tí ó má wáyé ní ọdún 2026.

“Mo fẹ́ sọ ọ̀rọ̀ pẹ̀lú òótọ́ nípa ìṣòro tí ó ń dojú kọ wá nígbà ìjọba mi gẹgẹbi asiwaju orílẹ̀-èdè yìí. Pẹ̀lú òótọ́ ni mo fi kéde pé ń kò ní díje ní ẹẹkeji nínú ìbò gbogbogbo tí a máa ṣe ní ọdún 2026. Mo lérò pé ìpinnu yìí dára fún orílẹ̀-èdè wa,” báyìí ni ó ṣe wí.

Hichilema ti dije fún Ipò Ààrẹ ní ìgbà márùn-ún tí ó sì kùnà kí ó tó ṣe àṣeyọrí ni ọdún 2021.

Ni Orílẹ̀-èdè Zambia, àwọn ènìyàn máa ń dibo yàn Ààrẹ fún ọdún márùn-ún. Ọdún márùn-ún ni ẹẹmeji ni Ààrẹ máa ń lò.

Àyẹ̀wò tí TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe fi hàn pé irọ́ ni àwòrán yìí.

Fídíò náà jáde nígbà tí àwọn ènìyàn ń sọ̀rọ̀ nípa ìdìbò ọdún 2026.

Gẹ́gẹ́bí ó ṣe rí ní àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè, nígbà ìdìbò, oríṣiríṣi àwọn fídíò àti atẹjade tí ó lè si àwọn ènìyàn l’ọna ni àwọn ènìyàn máa ń pín kiri.

Wọ́n máa ń se àwọn nkan tí a mẹ́nuba yìí láti ba ènìyàn kan ní orúkọ jẹ́ tàbí yí èrò àwọn ènìyàn padà.

Nínú ọ̀rọ̀ tí Batuke Imenda, akọ̀wé UPND, ẹgbẹ́ òsèlú tí ó ń ṣe ìjọba lọ́wọ́ ní Zambia fi síta, ó pè wọ́n ní alainikanse, oníwà radarada tí wọ́n ń pín fídíò irọ́ tí ó ń sín Ààrẹ jẹ láti si awọn ará ìlú lọna.

Ó kìlọ̀ fún àwọn ará ìlú tí wọ́n ń pín fídíò tí ó pa irọ́ nípa ènìyàn tí Hichilema jẹ́ yìí.

Ìwà ibanilorukọ jẹ́ ti àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú alátakò ń ṣe láti kan Ààrẹ ní àbùkù yé wa, báyìí ni atẹjade yìí ṣe wí.

“A mọ́ pé àwọn olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò àti àwọn ọmọ ẹgbẹ́ wọ́n ń ṣeé láti kọ ẹhin àwọn ènìyàn sí ìjọba.

“O ye wa pé ẹ fẹ́ kí àwọn ènìyàn gba tiyín. Ṣùgbọ́n, a o fi òfin yé yín.

“Àwọn ènìyàn mọ̀ pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ yín mọọmọ hu ìwà tí kò bá òfin mu kí àwọn agbofinro lè dá sí ọ̀rọ̀ yín. Tí wọ́n bá pè yín láti fi ọ̀rọ̀ wá yín lẹ́nu wò, ariwo yín yóò pọ̀.

“Ẹgbẹ́ òsèlú UPND fẹ́ fi yé ẹnikẹ́ni tí ó wà nìdí fídíò yìí pé ọwọ́ òfin yóò bàwọ́n.”

Ààrẹ Hichilema kò tíì sọ ọ̀rọ̀ kankan nípa fídíò náà.

Àwọn Ọlọpa Zambia ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí láti lè mọ ibi tí fídíò náà ti jáde. Wọ́n ní àwọn yóò fi ojú àwọn oníwà pàlàpálá yìí fíná.

TAGGED: Yoruba FactCheck, Zambia President

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael October 17, 2023 October 17, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?

A viral post claims, based on International Monetary Fund (IMF) projections, that Nigeria ranks fourth…

May 9, 2025

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025

FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?

A social media user has claimed that Francis Arinze, a Roman Catholic cardinal, is the…

April 21, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?