TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Fídíò tí ó sọ pé Hakainde Hichilema, Ààrẹ orílẹ-èdè Zambia fẹ́ ṣe ìjọba lẹẹkeji kìí ṣe òótọ́
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Fídíò tí ó sọ pé Hakainde Hichilema, Ààrẹ orílẹ-èdè Zambia fẹ́ ṣe ìjọba lẹẹkeji kìí ṣe òótọ́

Yemi Michael
By Yemi Michael Published October 17, 2023 4 Min Read
Share

Ẹgbẹ́ òsèlú kan tí a mọ̀ sí the United Party for National Development (UPND) tí sọ pé fídíò tí àwọn ènìyàn ń pín kiri tí ó sọ pé Hakainde Hichilema, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Zambia kò ní díje fún Ipò Ààrẹ ní ẹẹkeji ní ọdún 2026 kìí ṣe òótọ́. 

Nínú fídíò náà, èyí tí àwọn ènìyàn pín kiri, Hichilema wọ suutu nínú àwòrán tí asia orílẹ̀-èdè Zambia wà ní abẹlẹ rẹ̀ níbi tí ó ti ń ṣe ìkéde pé òhun kò ní díje ní ẹẹkeji nínú ìbò gbogbogbo tí ó má wáyé ní ọdún 2026.

“Mo fẹ́ sọ ọ̀rọ̀ pẹ̀lú òótọ́ nípa ìṣòro tí ó ń dojú kọ wá nígbà ìjọba mi gẹgẹbi asiwaju orílẹ̀-èdè yìí. Pẹ̀lú òótọ́ ni mo fi kéde pé ń kò ní díje ní ẹẹkeji nínú ìbò gbogbogbo tí a máa ṣe ní ọdún 2026. Mo lérò pé ìpinnu yìí dára fún orílẹ̀-èdè wa,” báyìí ni ó ṣe wí.

Hichilema ti dije fún Ipò Ààrẹ ní ìgbà márùn-ún tí ó sì kùnà kí ó tó ṣe àṣeyọrí ni ọdún 2021.

Ni Orílẹ̀-èdè Zambia, àwọn ènìyàn máa ń dibo yàn Ààrẹ fún ọdún márùn-ún. Ọdún márùn-ún ni ẹẹmeji ni Ààrẹ máa ń lò.

Àyẹ̀wò tí TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe fi hàn pé irọ́ ni àwòrán yìí.

Fídíò náà jáde nígbà tí àwọn ènìyàn ń sọ̀rọ̀ nípa ìdìbò ọdún 2026.

Gẹ́gẹ́bí ó ṣe rí ní àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè, nígbà ìdìbò, oríṣiríṣi àwọn fídíò àti atẹjade tí ó lè si àwọn ènìyàn l’ọna ni àwọn ènìyàn máa ń pín kiri.

Wọ́n máa ń se àwọn nkan tí a mẹ́nuba yìí láti ba ènìyàn kan ní orúkọ jẹ́ tàbí yí èrò àwọn ènìyàn padà.

Nínú ọ̀rọ̀ tí Batuke Imenda, akọ̀wé UPND, ẹgbẹ́ òsèlú tí ó ń ṣe ìjọba lọ́wọ́ ní Zambia fi síta, ó pè wọ́n ní alainikanse, oníwà radarada tí wọ́n ń pín fídíò irọ́ tí ó ń sín Ààrẹ jẹ láti si awọn ará ìlú lọna.

Ó kìlọ̀ fún àwọn ará ìlú tí wọ́n ń pín fídíò tí ó pa irọ́ nípa ènìyàn tí Hichilema jẹ́ yìí.

Ìwà ibanilorukọ jẹ́ ti àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú alátakò ń ṣe láti kan Ààrẹ ní àbùkù yé wa, báyìí ni atẹjade yìí ṣe wí.

“A mọ́ pé àwọn olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò àti àwọn ọmọ ẹgbẹ́ wọ́n ń ṣeé láti kọ ẹhin àwọn ènìyàn sí ìjọba.

“O ye wa pé ẹ fẹ́ kí àwọn ènìyàn gba tiyín. Ṣùgbọ́n, a o fi òfin yé yín.

“Àwọn ènìyàn mọ̀ pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ yín mọọmọ hu ìwà tí kò bá òfin mu kí àwọn agbofinro lè dá sí ọ̀rọ̀ yín. Tí wọ́n bá pè yín láti fi ọ̀rọ̀ wá yín lẹ́nu wò, ariwo yín yóò pọ̀.

“Ẹgbẹ́ òsèlú UPND fẹ́ fi yé ẹnikẹ́ni tí ó wà nìdí fídíò yìí pé ọwọ́ òfin yóò bàwọ́n.”

Ààrẹ Hichilema kò tíì sọ ọ̀rọ̀ kankan nípa fídíò náà.

Àwọn Ọlọpa Zambia ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí láti lè mọ ibi tí fídíò náà ti jáde. Wọ́n ní àwọn yóò fi ojú àwọn oníwà pàlàpálá yìí fíná.

TAGGED: Yoruba FactCheck, Zambia President

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael October 17, 2023 October 17, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?