TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Fídíò tí àwọn ènìyàn rí àwọn sójà ọmọ Nàìjíríà ati orílẹ̀ èdè Faransé jáde ní ọdún 2013
Share
Latest News
FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Fídíò tí àwọn ènìyàn rí àwọn sójà ọmọ Nàìjíríà ati orílẹ̀ èdè Faransé jáde ní ọdún 2013

Yemi Michael
By Yemi Michael Published December 28, 2024 4 Min Read
Share

Fídíò kan tí a ti rí àwọn sójà (soldiers) ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n fẹ́ lọ dojú ìjà kọ wàhálà àti àwọn sójà orílẹ̀ èdè Faransé tí wọ́n ń já àwọn nǹkan sílẹ̀ ti di ohun tí àwọn ènìyàn ti pín kiri.

A rí fídíò yìí lẹ́nu àríyànjiyàn tó ń lọ lọ́wọ́ pé orílẹ̀ èdè Faransé ní erongba kan nípa Nàìjíríà.

Ní ọjọ́ alamisi, Mohammed Idris, minisita fún fífi ọ̀rọ̀ tó àwọn ènìyàn létí ní Nàìjíríà sọ pé ọ̀rọ̀ kan tí àwọn ènìyàn ń sọ pé Nàìjíríà ti fi àwọn ilẹ̀ rẹ̀ kan tọrẹ fún orílẹ̀ èdè Faransé láti máa se àkóso rẹ̀ kìí se òótọ́.

Idris sọ ọ̀rọ̀ yìí laipẹ nígbà tí àwọn ènìyàn ń sọ pé Nàìjíríà fẹ́ pawọ pọ̀ pẹ̀lú orílẹ̀ èdè Faransé láti da orílẹ̀ èdè Niger Republic rú.

Ní bíi ọ̀sẹ̀ díẹ̀ sẹhin, Mahdi Shehu, ẹni kan tí ó máa ń sọ ọ̀rọ̀ nípa àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ láwùjọ, sọ ọ̀rọ̀ kan tí ìdí rẹ̀ kò múlẹ̀ pé ètò àti fi ibijoko àwọn ológun orílẹ̀ èdè Faransé tẹ́lẹ̀ sì àríwá-orun Naijiria ń lọ lọ́wọ́, lẹhin ìgbà tí àwọn ọmọ ológun orílẹ̀ èdè Faransé wá rí Femi Oluyede, ẹni tí ó jẹ ọga pátápátá fún àwọn sójà (Chief of Army Staff-COAS) ní Nàìjíríà.

Àmọ́sá, nígbà tí ó ń fèsì sí ọ̀rọ̀ Idris ní ọjọ́ alamisi, Shehu sọ pé kí Idris ye pa irọ, ó ní pé kí ó ye máa sọ pé ọ̀rọ̀ yìí kì í ṣe òótọ́. Àwọn adarí ọ̀rọ̀ àwọn sójà sọ pé ọ̀rọ̀ yìí kì í se òótọ́.

Nínú fọ́nrán kan tí ẹnì kan fi síta pẹ̀lú atẹsita kan tí wọn tí mú kúrò lórí ayélujára, àwọn ènìyàn ní àwọn ń gbọ́ ohun kan bí ariwo níbi tí àwọn ọmọ ológun Nàìjíríà ti ń já àwọn nǹkan kan silẹ, tí ara wọn jẹ́ àpò ìrẹsì, láti inú ọkọ̀, nígbà tí àwọn ọmọ ológun orílẹ̀ èdè Faransé ń já ọkọ baalu ológun silẹ láti inú ọkọ̀ òfuurufú tí wọ́n fi máa ń kó ẹrù.

Àwọn ọkọ̀ tí àwọn ọmọ ológun wà nínú rẹ̀ ń káàkiri, ènìyàn sì lè gbọ́ ìró bàtà wọn lórí títì.
Ọkọ̀ (bọọsi) méjì, ìkan ní àsíá orílẹ̀ èdè Faransé, ni àwọn ènìyàn padà rí tí wọ́n ń gbé àwọn ọmọ sójà tí wọ́n fẹ́ lọ dojú ìjà kọ wàhálà lọ.

Sójà ọmọ Nàìjíríà kan sọ̀rọ̀ nínú fídíò náà. Ó ní àwọn sójà yìí tí kúrò níbi tí wọ́n ti lọ dojú ìjà kọ wàhálà, níbi tí wọ́n ti kọ nípa gbigbogun ti rògbòdìyàn.

Àmọ́sá, TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára ríi pé fídíò yìí ti wà níta láti oṣù kìíní, ọdún 2013.

Àwọn onisẹ ìròyìn kan tí a mọ̀ sí Associated Press (AP) sọ pé àwọn sójà yìí jẹ́ ara àwọn sójà tí wọ́n fẹ́ dojú ìjà kọ rògbòdìyàn tí Economic Community of West African States (ECOWAS) fi se iranlọwọ fún àlàáfíà ní àwọn orílẹ̀ èdè tí wọ́n jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ ECOWAS.

“Ọmọ Nàìjíríà mẹrindinlọgọjọ, ọmọ orílẹ̀ èdè Togo ọgọ́rùn-ún, ọmọ orílẹ̀ èdè Benin Republic marunlelogun àti àwọn marunlelogun mìíràn láti Benin Republic ni wọ́n ń bọ̀ ní alẹ yìí,” ọga àwọn sójà ní orílẹ̀ èdè Faransé ló sọ ọ̀rọ̀ yìí nínú fídíò yìí.

Àwọn ọmọ ológun náà dé sí Senou International Airport, Bamako, Mali, èyí tí ó jẹ́ ìkan lára àwọn orílẹ̀ èdè tí àwọn sójà yìí dé sí láti lé jẹ́ kí wàhálà má wà.

TAGGED: Fact check in Yoruba, French troops, News in Yorùbá, Nigerian troops, old video

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael January 3, 2025 December 28, 2024
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?

A viral post claims, based on International Monetary Fund (IMF) projections, that Nigeria ranks fourth…

May 9, 2025

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025

FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?

A social media user has claimed that Francis Arinze, a Roman Catholic cardinal, is the…

April 21, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?