TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Fídíò Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà orílẹ-èdè Gabon tẹ́lẹ̀rí tí wọ́n mú ti pẹ
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Fídíò Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà orílẹ-èdè Gabon tẹ́lẹ̀rí tí wọ́n mú ti pẹ

Yemi Michael
By Yemi Michael Published September 10, 2023 5 Min Read
Share

Fídíò kan lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ ti s’àfihàn àwọn tí wọn sejọba níbi tí wọ́n ti ń si ohun kan tí owó kún inú rẹ̀. Fídíò yìí fi yé wa pé Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà tẹ́lẹ̀rí ti orílẹ-èdè Gabon fẹ́ salọ lẹhin ifipagba ìjọba.

“KÉRE O: Wọ́n ti mú Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà ti orílẹ-èdè Gabon tẹ́lẹ̀rí pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ owó nígbà tí ó fẹ́ salọ,” báyìí ni àkòrí fídíò náà ṣe wí.

Nigeria News Updates ni ó ṣe atẹjade ọ̀rọ̀ yìí. Àwọn ènìyàn tí ó ju mílíọ̀nù kan àti àbọ̀ ló rí í. Ẹgbẹ̀rún mẹta àti igba ènìyàn ló sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Ẹgbẹ̀rún méjìlá ènìyàn ló fẹ́ràn ọ̀rọ̀ yìí.

Fídíò yìí tán ranyin. Àwọn ènìyàn sì pín-in ní àwọn orí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise (social media) bíi WhatsApp, X (tí a mọ̀ sí twitter tẹ́lẹ̀) àti Tik Tok. Fídíò yìí s’àfihàn àwọn ọkùnrin kan tí wọ́n wọ unifọọmu àti àwọn ènìyàn kan níbi tí wọ́n ti ń sí ohun kan tí owó wà nínú rẹ̀.

Wọ́n kọ BEAC sì ara àwọn bọndu owó yìí tí ó jẹ́ ti Bank of Central African States.

BEAC yìí ló ń ṣàkóso ọ̀rọ̀ owó àwọn orílẹ̀-èdè tí ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Economic and Monetary Community of Central Africa. Lára àwọn orílẹ̀-èdè yìí ni Cameroon, Gabon, the Central African Republic (CAR), Chad, the Republic of the Congo àti Equatorial Guinea.

Central African franc (CFA) ni owo tí àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń ńọ.

IFIPAGBA ÌJỌBA NÍ ORÍLẸ̀–ÈDÈ GABON

Gabon, orílẹ̀-èdè kan lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ní epo rọbi púpọ̀ ní Áfíríkà darapọ̀ mọ́ Commonwealth, ní oṣù kẹfà, ọdún 2022 pẹ̀lúpẹ̀lú pé orílẹ̀-èdè Faransé (France) ni ó ń se ìjọba rẹ̀ tẹ́lẹ̀. Bíi ìdá àádọ́rùn-ún Gabon ní o jẹ́ igbó.

Ní ọgbọ́n ọjọ́, oṣù kẹjọ, àwọn òṣìṣẹ́ ológun ní Gabon fi ipá gba ìjọba. Wọ́n sì yọ Ali Bongo, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Gabon, ẹni tí ó taku sí orí ìjọba, ẹni tí ó sọ ìjọba di nibininmakusi tí àwọn ará Gabon ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ìbò yàn ní ìgbà kẹta sí ipò Ààrẹ.

Ifipagba ìjọba yìí fi òpin sí isejọba Bongo àti ẹbí rẹ̀ pẹ̀lú ìwà nibininmakusi wọ́n  tàbí isọjọba di oyè ìdílé wọn (títakú sórí ìjọba) fún bíi ọdún marunlelaadọta.

Àwọn afipagba ìjọba yìí fi Bruce Oligui Nguema, ẹni tí ó jẹ́ ọga nínú iṣẹ́ ológun jẹ olórí ìṣàkóso orílẹ̀-èdè Gabon títí tí wọ́n yóò fi ṣètò ìjọba tí ó yẹ.

Wọ́n fi Bongo sí àtìmọ́lé. Wọ́n mú ọmọ rẹ̀ ọkùnrin. Wọ́n sì fi ẹ̀sùn pé ó fẹ́ dá ojú ìjọba bolẹ kàn-án.

“A ti pinnu láti jẹ́ kí àlàáfíà wà nípa fífi òpin sí ìjọba yìí.” Ìkan nínú àwọn òṣìṣẹ́ ológun ló sọ bayìí lórí tẹlifisọn tí a tún máa ń pè ní ẹ̀rọ amohunmaworan (television) tí a mọ̀ sí Gabon24.

Nígbà ifiọrọtonileti tí àwọn òṣìṣẹ́ ológun méjìlá ṣe, àwọn ológun ṣe ìkéde pé èsì ìbò tí àwọn ẹgbẹ́ òsèlú alátakò pè ní jìbìtì kò ní ṣe lo mọ́. Wọ́n fi kún-un pe “gbogbo ẹ̀ka ìjọba kò ní agbára kankan mọ́.”

Ní ọjọ́ keje, oṣù kẹsàn-án, ọjọ́ kẹjọ lẹhin tí wọ́n yọ Bongo kúrò ní ipò Ààrẹ, tí wọ́n sì fi sí àtìmọ́lé, àwọn ológun fi sílẹ̀ nítorí “àìlera rẹ̀.”

Ninu ọ̀rọ̀ tí wọn fi tó àwọn ènìyàn létí lórí tẹlifisọn, Ulrich Manfoumbi, agbẹnusọ àwọn òṣìṣẹ́ ológun sọ pé: “Tí ó bá fẹ́, ó lè lọ sí orílẹ̀-èdè míràn fún àyẹ̀wò ara ẹ.”

ÀYẸ̀WÒ ÌRÒYÌN YÌÍ 

TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe àyẹ̀wò fídíò yìí pẹ̀lú Yandex. Àyẹ̀wò yìí fi yé wa pé wọ́n ya fídíò yìí ní ọdún 2022.

Wọ́n ya fídíò yìí nígbà tí wọ́n mú Guy Nzouba-Ndama, ẹni tí ó jẹ́ Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà tẹ́lẹ̀rí, tí ó sì tún jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò ní Gabon, ní bodè/bọ́dà (border) Gabon nígbà tí ó ń padà bọ láti Congo pẹ̀lú owó tí ó tó bíi mílíọ̀nù méjì uro (two million euros).

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Fídíò tí ó s’àfihàn pé Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà tẹ́lẹ̀rí ni orílẹ̀-èdè Gabon fẹ́ salọ lẹhin ifipagba ìjọba kìí se òótọ́.

Wọ́n ya fídíò yìí ní ọdún kan sẹhin kí àwọn òṣìṣẹ́ ológun tó fi ipá gba ìjọba.

TAGGED: Ali Bongo, coup d'etat, Gabon coup, Guy Nzouba-Ndama

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael September 10, 2023 September 10, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?