TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Fídíò Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà orílẹ-èdè Gabon tẹ́lẹ̀rí tí wọ́n mú ti pẹ
Share
Latest News
Did Tinubu attend same school as Alexander Zingman? Here is what we know
FACT CHECK: No, Nigeria didn’t deploy peace support mission to Israel
FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?
FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?
FACT CHECK: Ndume erred. 22 governors didn’t endorse Jonathan in 2015
Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé
Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá
No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Fídíò Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà orílẹ-èdè Gabon tẹ́lẹ̀rí tí wọ́n mú ti pẹ

Yemi Michael
By Yemi Michael Published September 10, 2023 5 Min Read
Share

Fídíò kan lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ ti s’àfihàn àwọn tí wọn sejọba níbi tí wọ́n ti ń si ohun kan tí owó kún inú rẹ̀. Fídíò yìí fi yé wa pé Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà tẹ́lẹ̀rí ti orílẹ-èdè Gabon fẹ́ salọ lẹhin ifipagba ìjọba.

“KÉRE O: Wọ́n ti mú Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà ti orílẹ-èdè Gabon tẹ́lẹ̀rí pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ owó nígbà tí ó fẹ́ salọ,” báyìí ni àkòrí fídíò náà ṣe wí.

Nigeria News Updates ni ó ṣe atẹjade ọ̀rọ̀ yìí. Àwọn ènìyàn tí ó ju mílíọ̀nù kan àti àbọ̀ ló rí í. Ẹgbẹ̀rún mẹta àti igba ènìyàn ló sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Ẹgbẹ̀rún méjìlá ènìyàn ló fẹ́ràn ọ̀rọ̀ yìí.

Fídíò yìí tán ranyin. Àwọn ènìyàn sì pín-in ní àwọn orí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise (social media) bíi WhatsApp, X (tí a mọ̀ sí twitter tẹ́lẹ̀) àti Tik Tok. Fídíò yìí s’àfihàn àwọn ọkùnrin kan tí wọ́n wọ unifọọmu àti àwọn ènìyàn kan níbi tí wọ́n ti ń sí ohun kan tí owó wà nínú rẹ̀.

Wọ́n kọ BEAC sì ara àwọn bọndu owó yìí tí ó jẹ́ ti Bank of Central African States.

BEAC yìí ló ń ṣàkóso ọ̀rọ̀ owó àwọn orílẹ̀-èdè tí ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Economic and Monetary Community of Central Africa. Lára àwọn orílẹ̀-èdè yìí ni Cameroon, Gabon, the Central African Republic (CAR), Chad, the Republic of the Congo àti Equatorial Guinea.

Central African franc (CFA) ni owo tí àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń ńọ.

IFIPAGBA ÌJỌBA NÍ ORÍLẸ̀–ÈDÈ GABON

Gabon, orílẹ̀-èdè kan lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ní epo rọbi púpọ̀ ní Áfíríkà darapọ̀ mọ́ Commonwealth, ní oṣù kẹfà, ọdún 2022 pẹ̀lúpẹ̀lú pé orílẹ̀-èdè Faransé (France) ni ó ń se ìjọba rẹ̀ tẹ́lẹ̀. Bíi ìdá àádọ́rùn-ún Gabon ní o jẹ́ igbó.

Ní ọgbọ́n ọjọ́, oṣù kẹjọ, àwọn òṣìṣẹ́ ológun ní Gabon fi ipá gba ìjọba. Wọ́n sì yọ Ali Bongo, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Gabon, ẹni tí ó taku sí orí ìjọba, ẹni tí ó sọ ìjọba di nibininmakusi tí àwọn ará Gabon ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ìbò yàn ní ìgbà kẹta sí ipò Ààrẹ.

Ifipagba ìjọba yìí fi òpin sí isejọba Bongo àti ẹbí rẹ̀ pẹ̀lú ìwà nibininmakusi wọ́n  tàbí isọjọba di oyè ìdílé wọn (títakú sórí ìjọba) fún bíi ọdún marunlelaadọta.

Àwọn afipagba ìjọba yìí fi Bruce Oligui Nguema, ẹni tí ó jẹ́ ọga nínú iṣẹ́ ológun jẹ olórí ìṣàkóso orílẹ̀-èdè Gabon títí tí wọ́n yóò fi ṣètò ìjọba tí ó yẹ.

Wọ́n fi Bongo sí àtìmọ́lé. Wọ́n mú ọmọ rẹ̀ ọkùnrin. Wọ́n sì fi ẹ̀sùn pé ó fẹ́ dá ojú ìjọba bolẹ kàn-án.

“A ti pinnu láti jẹ́ kí àlàáfíà wà nípa fífi òpin sí ìjọba yìí.” Ìkan nínú àwọn òṣìṣẹ́ ológun ló sọ bayìí lórí tẹlifisọn tí a tún máa ń pè ní ẹ̀rọ amohunmaworan (television) tí a mọ̀ sí Gabon24.

Nígbà ifiọrọtonileti tí àwọn òṣìṣẹ́ ológun méjìlá ṣe, àwọn ológun ṣe ìkéde pé èsì ìbò tí àwọn ẹgbẹ́ òsèlú alátakò pè ní jìbìtì kò ní ṣe lo mọ́. Wọ́n fi kún-un pe “gbogbo ẹ̀ka ìjọba kò ní agbára kankan mọ́.”

Ní ọjọ́ keje, oṣù kẹsàn-án, ọjọ́ kẹjọ lẹhin tí wọ́n yọ Bongo kúrò ní ipò Ààrẹ, tí wọ́n sì fi sí àtìmọ́lé, àwọn ológun fi sílẹ̀ nítorí “àìlera rẹ̀.”

Ninu ọ̀rọ̀ tí wọn fi tó àwọn ènìyàn létí lórí tẹlifisọn, Ulrich Manfoumbi, agbẹnusọ àwọn òṣìṣẹ́ ológun sọ pé: “Tí ó bá fẹ́, ó lè lọ sí orílẹ̀-èdè míràn fún àyẹ̀wò ara ẹ.”

ÀYẸ̀WÒ ÌRÒYÌN YÌÍ 

TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe àyẹ̀wò fídíò yìí pẹ̀lú Yandex. Àyẹ̀wò yìí fi yé wa pé wọ́n ya fídíò yìí ní ọdún 2022.

Wọ́n ya fídíò yìí nígbà tí wọ́n mú Guy Nzouba-Ndama, ẹni tí ó jẹ́ Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà tẹ́lẹ̀rí, tí ó sì tún jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò ní Gabon, ní bodè/bọ́dà (border) Gabon nígbà tí ó ń padà bọ láti Congo pẹ̀lú owó tí ó tó bíi mílíọ̀nù méjì uro (two million euros).

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Fídíò tí ó s’àfihàn pé Ààrẹ ilé igbimọ asofin àgbà tẹ́lẹ̀rí ni orílẹ̀-èdè Gabon fẹ́ salọ lẹhin ifipagba ìjọba kìí se òótọ́.

Wọ́n ya fídíò yìí ní ọdún kan sẹhin kí àwọn òṣìṣẹ́ ológun tó fi ipá gba ìjọba.

TAGGED: Ali Bongo, coup d'etat, Gabon coup, Guy Nzouba-Ndama

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael September 10, 2023 September 10, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Did Tinubu attend same school as Alexander Zingman? Here is what we know

During the launch of the renewed hope mechanisation programme in Abuja on Monday, President Bola…

June 24, 2025

FACT CHECK: No, Nigeria didn’t deploy peace support mission to Israel

A Facebook video purports that Nigeria deployed troops for a joint peace support mission in…

June 24, 2025

FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?

A viral X post claims that Nigeria’s new national anthem was not recited during the…

June 13, 2025

FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?

Reports of a military coup in Cameroon ousting President Paul Biya have gone viral on…

June 13, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé

Ẹni kan tí ó ń lo Facebook, ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ orí ayélujára sọ pé Robert Francis Prevost, Pope Leo XIV…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá

Ótù onye na Facebook ekwuola na Pope Leo na ụfọdụ ndị Bishop yọrọ onye isiala Bola Tinubu ka ọ tọpụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu

One Facebook user claim sey Pope Leo XVI and oda bishops join mouth beg President Bola Tinubu to release Nnamdi…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

A’a, Paparoma Leo bai nemi Tinubu ya saki Nnamdi Kanu ba

Wani mai amfani da Facebook ya yi ikirarin cewa Paparoma Leo na 16 da wasu limaman coci sun roki shugaban…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?