TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ẹdó ni ẹhonu #EndBadGovernance tí àwọn ènìyàn pín fídíò rẹ̀ ti ṣẹlẹ̀, kìí se Ìbàdàn
Share
Latest News
FACT CHECK: Did Nigeria halt ‘mineral deal’ with US after visa restrictions?
FACT CHECK: Viral image depicting ‘Obasanjo prostrating for Ladoja’ photoshopped
Wike tụ̀rụ̀ àsị́. Peter Obi mèrè ńtụ̀líáká ọ̀chị́chị́ ḿpághárá m̀gbè ọ́ bụ̀ gọ́vánọ̀ Anambra
Irọ́ ni Wike pa. Peter Obi ṣètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ gómìnà Ìpínlẹ̀ Anambra
Wike yayi kuskure. Peter Obi ya gudanar da zaben LG a matsayin gwamnan Anambra
Wike make mistake. Peter Obi conduct LG election as Anambra governor
Video wey show as Thomas Partey dey blame ‘rape’ case on racism na fake
Bidiyon da ke nuna Partey yana zargin shari’ar ‘fyade’ akan wariyar launin fata da aka gyara ta hanyar lambobi
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ẹdó ni ẹhonu #EndBadGovernance tí àwọn ènìyàn pín fídíò rẹ̀ ti ṣẹlẹ̀, kìí se Ìbàdàn

Yemi Michael
By Yemi Michael Published October 23, 2024 4 Min Read
Share

Ní ọjọ́ ajé, àwọn ènìyàn kan tí wọ́n ń lo ohun ìgbàlódé ibaraẹnise sọ pé àwọn afiẹhonu hàn kan ní Ìbàdàn, olú ìlú Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ sọ pé kí àwọn òṣìṣẹ́ ológun gba ìjọba lọ́wọ́ Ààrẹ Bọla Tinubu.

Nínú fídíò ìṣẹ́jú kan yìí, ọkọ̀ kan tí ó ní ẹ̀hìn tí ó lè fi gbé àwọn ènìyàn tí àwọn òṣìṣẹ́ ológun/sójà wà nínú rẹ̀ ni a rí tí ó ń rìn díẹ̀díẹ̀ lójú ọ̀nà tí àwọn ènìyàn kan sì ń fi ẹhonu hàn níwájú rẹ̀.

A gbọ ohun ọkùnrin kan tó ń pariwo pé: “Tinubu gbọ́dọ̀ lọ. A fẹ́ kí àwọn òṣìṣẹ́ ológun Nàìjíríà gba ìjọba. N kò mọ ìdí tí wọ́n fi ń bẹ̀rù.”

Àwọn ènìyàn tí pín fídíò yìí lọpọlọpọ lórí àwọn ohùn ibaraẹnise/ibaraẹnisọrọ bíi fesibuuku , ohun ibaraẹnise àlámì krọọsi àti Wasapu.

Ẹnì kan tí ó ń lo X tí a mọ̀ sí @SabinaNkiru tí ó ní àwọn ènìyàn tí ó lè ní ẹgbẹ̀rún mọ́kànlá tí wọ́n ń tẹ̀lée fi fídíò kan síta tí àkòrí rẹ̀ sọ pé: “Àwọn afiẹhonu hàn ní Ìbàdàn dí ọ̀nà fún àwọn ọkọ̀ àwọn òṣìṣẹ́ ológun, wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ wọ́n pé kí ló dé tí ẹ̀ru se ń bà wọ́n láti gba ìjọba lọ́wọ́ Tinubu.”

Àwọn ènìyàn ẹgbẹ̀rún kan àti ẹẹdẹgbẹrin ni wọ́n ti rí  ọ̀rọ̀ náà tí a fi pamọ níbí. Àwọn ènìyàn méjìdínlógún ló ti fi í síta gẹ́gẹ́bí wọ́n se kọọ.

Ẹlòmíràn tí ó ń lo X tí a mọ̀ sí @PrinceUjay, tí ó ní àwọn ènìyàn tí wọ́n ń tẹ̀lée tí wọ́n lé ní ẹgbẹ̀rún marundinlogoji fi fídíò náà síta pẹ̀lú àkòrí tó sọ pé:

“Nǹkan di wàhálà síi ní Ìbàdàn bí àwọn afiẹhonu hàn tí wọ́n dí ọ̀nà tí àwọn ọkọ̀ àwọn òṣìṣẹ́ ológun yóò gbà kọjá tí wọ́n sì ní kí àwọn òṣìṣẹ́ ológun gba ìjọba, wọ́n ní ìnira ìgbà ìjọba Tinubu yìí kò ṣeé fara dà.”

Àwọn ènìyàn ẹgbẹ̀rún méjì ni wọ́n ti rí ọ̀rọ̀ yìí. Àwọn ènìyàn mẹtadinlọgbọn ló fi síta gẹ́gẹ́bí wọ́n ṣe kọọ. A fi pamọ níbí.

A fi àwọn ọ̀rọ̀ mìíràn tí àwọn ènìyàn sọ nípa ọ̀rọ̀ náà pamọ níbí àti níbí.

AYẸWO 

Ayẹwo fídíò náà fi yé wa pé ẹni kan tí ó ń lo Tiktok tí a mọ̀ sí @mikkyforlife0 ló fi fídíò náà síta. Àwọn àyẹ̀wò lórí Tiktok ẹni yìí fi yé wa pé wọ́n fi fídíò náà síta ní ọjọ́ kejì, oṣù kẹjọ, ọdún 2024 nígbà tí àwọn ènìyàn se ẹhonu tí wọ́n pè ní #EndBadGovernance ní Nàìjíríà.

Ẹhonu nípa ọ̀wọ́n gógó àwọn nǹkan yìí wáyé ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ibi ní Nàìjíríà láti ọjọ́ Kínní sí ọjọ́ kẹwàá, oṣù kẹjọ, ọdún 2024.

Ní àfikún, àwọn ènìyàn fi ohun ìpolongo ìbò fún Asue Ighodalo, Ólùdíje fún Ipò Gómìnà nínú ẹgbẹ́ òsèlú Peoples Democratic Party (PDP) sí orí ohun ìpolówó kan lójú ọ̀nà nígbà ìfiẹhonuhan yìí ní Benin City,olú ìlú Ìpínlẹ̀ Edo.

Àwọn afiẹhonu hàn yìí rìn kọjá òpópónà tí ó dá sí méjì tí ó wà ní iwájú ibi tí àwọn ọkọ̀ ilé epo TotalEnergies máa ń wà ní Benin City. Ilé epo yìí wà ní ojú ọ̀nà tí a mọ̀ sí Upper Mission Road, ní Benin City.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ ṢÍ 

Ọ̀rọ̀ tí ó sọ pé àwọn afiẹhonu hàn ní Ìbàdàn sọ pé kí àwọn òṣìṣẹ́ ológun gba ìjọba kìí se òótọ́ nítorí pé Benin City ni wọ́n ti ya fídíò náà nínú oṣù kẹjọ nígbà tí àwọn ọmọ Nàìjíríà ń fi ẹhonu hàn nípa àwọn nǹkan tí wọ́n wọ́n gógó ní Nàìjíríà.

TAGGED: #EndBadGovernance protest, Benin, Fact check in Yoruba, Ibadan, News in Yorùbá

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael October 23, 2024 October 23, 2024
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Did Nigeria halt ‘mineral deal’ with US after visa restrictions?

A Facebook user has claimed that Nigeria retaliated against the recent United States visa restrictions…

July 15, 2025

FACT CHECK: Viral image depicting ‘Obasanjo prostrating for Ladoja’ photoshopped

An image showing a person prostrating for Rashidi Ladoja, the Olubadan-in-waiting and former governor of…

July 11, 2025

Wike tụ̀rụ̀ àsị́. Peter Obi mèrè ńtụ̀líáká ọ̀chị́chị́ ḿpághárá m̀gbè ọ́ bụ̀ gọ́vánọ̀ Anambra

Nyesom Wike, onye minista nke isi obodo Naijiria bụ FCT, kwuru na Peter Obi, onye…

July 11, 2025

Irọ́ ni Wike pa. Peter Obi ṣètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ gómìnà Ìpínlẹ̀ Anambra

Nyesom Wike, minisita fún Federal Capital Territory (FCT), Abuja, olú ìlú orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, sọ…

July 11, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Wike tụ̀rụ̀ àsị́. Peter Obi mèrè ńtụ̀líáká ọ̀chị́chị́ ḿpághárá m̀gbè ọ́ bụ̀ gọ́vánọ̀ Anambra

Nyesom Wike, onye minista nke isi obodo Naijiria bụ FCT, kwuru na Peter Obi, onye bụ buru gọvanọ Anambra steetị…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 11, 2025

Irọ́ ni Wike pa. Peter Obi ṣètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ gómìnà Ìpínlẹ̀ Anambra

Nyesom Wike, minisita fún Federal Capital Territory (FCT), Abuja, olú ìlú orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, sọ pé Peter Obi, ẹni tí…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 11, 2025

Wike yayi kuskure. Peter Obi ya gudanar da zaben LG a matsayin gwamnan Anambra

Nyesom Wike, ministan babban birnin tarayya Abuja, ya ce Peter Obi, tsohon gwamnan Anambra kuma dan takarar shugaban kasa na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 11, 2025

Wike make mistake. Peter Obi conduct LG election as Anambra governor

Nyesom Wike, minister of di Federal Capital Territory (FCT), tok sey Peter Obi, forma govnor of Anambra and 2023 Labour…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 11, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?