TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Peter Obi kò kúnlẹ̀ fún Tinubu ní Rome
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Peter Obi kò kúnlẹ̀ fún Tinubu ní Rome

Yemi Michael
By Yemi Michael Published May 24, 2025 6 Min Read
Share

Àwọn ènìyàn ti ń pín àwòrán kan kiri lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise orí ayélujára, tí ó se àfihàn Peter Obi, Ólùdíje fún Ipò Ààrẹ nínú ẹgbẹ́ òsèlú Labour Party (LP), ní ọdún 2023, níbi tí ó ti kúnlẹ̀ láti kí Bọla Tinubu, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

Àwọn ènìyàn tí wọ́n ń lo ohun ìgbàlódé ibaraẹnise yìí sọ pé Obi kúnlẹ̀ láti kí Tinubu nígbà tí wọ́n ń se ètò lati fi Pope Leo XIV, olórí ni gbogbo àgbáyé fún àwọn ẹlẹ́sìn Kátólíìkì (catholic church adherents) ní Rome, olú ìlú orílẹ̀ èdè Italy.

Ní ogunjọ, oṣù karùn-ún, ọdún 2025, Atu Lazarus, ẹni kan tó ń lo Facebook, ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ lórí ayélujára, fi aworan yìí síta pẹ̀lú àkòrí tó sọ pé “Peter Obi ṣe ohun tí mo fẹ́ràn. Ó kúnlẹ̀ fún bàbá mi. Kó gba ti Tinubu. Kó so ọwọ pọ̀ pẹ̀lú Tinubu láti tún Nàìjíríà ṣe.”

Ẹni kan tí ó ń jẹ́ Pankwaye Bulus Kanam tí ohun náà ń lo Facebook, fi àwòrán yìí síta pẹ̀lú àkòrí tó sọ pé: “Peter Obi kúnlẹ̀ síwájú Ààrẹ Bọla Ahmed Tinubu ní àjọ ìjọsìn ti Vatican. Obi yìí kan náà ló ń pariwo, tó sì í ń tiraka láti kó àwọn ẹgbẹ́ alátakò jọ láti yọ Tinubu kúrò ní ipò Ààrẹ.”

Ẹ lè rí àwòrán yìí wò níbí, níbí àti níbí.

OHUN TÍ Ó YẸ KÍ Ẹ KỌ́KỌ́ MỌ̀ KÍ Ọ̀RỌ̀ ÌKÚNLẸ̀ YÌÍ TÓ WÁYÉ

Ètò yíyan Pope Leo XIV (Pope kẹrìnlá) wáyé ní Saint Peter’s Square, ní Vatican City, ní ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù karùn-ún, ọdún 2025.

Àwọn tí wọ́n wà nípò àti yàn Pope sí ipò gẹ́gẹ́bí olórí ẹ̀sìn ìgbàgbọ́ ti àwọn Catholic yàn án sípò Pope, ní ọjọ́ kẹjọ, oṣù karùn-ún, ọdún 2025, lẹ́hìn ìgbà tí Pope kẹtàlá kú. Tinubu àti àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn olórí ní àgbáyé ni wọ́n wà níbi tí wọ́n ti se ètò ìyannisípò fún Pope Leo yìí.

Nígbà ètò ìsìn fún ìyannisípò fún Pope Leo, Tinubu kí Káyọ̀dé Fayemi, gómìnà tẹ́lẹ̀ fún Ìpínlẹ̀ Èkìtì àti Obi, àwọn méjèèjì jẹ́ ẹlẹ́sìn Catholic pọnbele. Bayo Onanuga, ẹni tí ó máa ń gba Tinubu ní àmọ̀ràn lórí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ìjọba fi tó àwọn ọmọ Nàìjíríà létí àti ètò, fi ọ̀rọ̀ kan síta, ó sì se àlàyé bí Tinubu se bá Obi àti Fayẹmi sọ̀rọ̀ níbi ètò ìyannisípò náà.

Onanuga sọ pé Fayẹmi rí Tinubu níbi tí ó jókòó sí, ó sì sọ fún Obi kó tẹ̀lé ohun láti lọ bọ̀wọ̀ fún Tinubu.

“Nígbà tí Fayẹmi àti Obi dé ibi tí Tinubu wà, Fayẹmi sọ pé: “Ààrẹ, ẹ kaabọ sí ìjọ wá, mo dúpẹ́ lọ́wọ́ yín fún yiyẹ Pope sí nípa wíwá sí ibi ètò yìí.”

Tinubu dáhùn, ó sọ pé: “Èmi ni ó yẹ kí n kí ìwọ Fayẹmi àti Obi kaabọ. Èmi ni olórí àwọn tó wá ṣojú àwọn ènìyàn láti Nàìjíríà.” Èsì Tinubu pa Obi ní ẹ̀rín, Obi sì gbà pè lóòótọ́ ni nnkan tí Tinubu sọ,” báyìí ni ọ̀rọ̀ tí Onanuga fi síta lórí X (formerly Twitter), ohun ìgbàlódé ibaraẹnise alámì krọọsi se wí.

Onanuga tún fi àwòrán bí Tinubu se kí Obi àti Fayẹmi níbi ètò ìyannisípò náà sórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise orí ayélujára (social media). Obi fi ọ̀rọ̀ tó sọ pé òhun kí Tinubu àti Fayẹmi níbi ètò ìyannisípò yìí síta lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise. Àwòrán àti fídíò àwọn olórí ẹ̀sìn àti ìjọba ni àgbáyé tí wọ́n wà ní ibi ètò náà jáde ní orí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise (social media) lórí ayélujára (the internet). Àwọn ènìyàn bẹ̀rẹ̀ sí níí se àríyànjiyàn nípa bí ipò Tinubu àti Obi se tó ní àgbáyé. Àwòrán ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ti jáde káàkiri orí àwọn ohun ìgbàlódé ibaraẹnise orí ayélujára.

AYẸWO Ọ̀RỌ̀ YÌÍ TÍ CABLECHECK SE RÈÉ 

Nígbà tí CableCheck se àyẹ̀wò àwòrán yìí, a ríi pé àwọn ènìyàn dá ọgbọ́n síi ní láti lè jẹ́ kí ó rí bí ó se rí. Wọn gbé àwọn àwòrán yìí lórí ara wọn ni.

Nínú àwòrán yìí, Ọwọ́ (hands) Obi níbi tí wọ́n ní ó ti kúnlẹ̀ yìí kò dà bí Ọwọ́ gidi. Ọwọ́ yìí dàbí Ọwọ́ tí wọ́n dá ọgbọ́n sí láti gbé lórí nǹkan.

Ayẹwo tí a tún se síi fi yé wa pé Olusegun Dada, oluranlọwọ lórí ọ̀rọ̀ ohun ìgbàlódé ibaraẹnise fún Tinubu (special assistant to Tinubu on social media) fi àwòrán yìí to jẹ́ gidi síta lórí X, ní ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù karùn-ún, ọdún 2025. Nínú àwòrán tí Dada fi síta yìí, Tinubu dá jókòó níwájú níbi ètò ìyannisípò yìí nígbà tí Fayẹmi àti Obi ń bọ̀ lẹ́hìn láti rí Tinubu.

Ọ̀rọ̀ kan tí Valentine Obienyem, ẹni tí ó máa ń gba Obi ni àmọ̀ràn lórí ọ̀rọ̀ ìròyìn fi sita sọ pé wọn dá ọgbọ́n sí àwòrán yìí ni kí ó ba lè rí bí ó se rí.

BÍ A SE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ ṢÍ

Àwòrán tó ṣe àfihàn Obi níbi tí ó ti kúnlẹ̀ sí iwájú Tinubu kìí se àwòrán ohùn tó jẹ́ òótọ́.

TAGGED: factcheck, Factcheck in Yorùbá, News in Yorùbá, peter obi, Rome, Tinubu

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael May 24, 2025 May 24, 2025
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?