TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní George Weah sọ nípa ifipagba ìjọba ní orílẹ̀-èdè Nije kìí ṣe òótọ́
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní George Weah sọ nípa ifipagba ìjọba ní orílẹ̀-èdè Nije kìí ṣe òótọ́

Yemi Michael
By Yemi Michael Published August 11, 2023 7 Min Read
Share

Ọ̀rọ̀ kan tí wọ́n ní George Weah, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Liberia sọ ni àwọn ènìyàn ti se atunpin rẹ̀ lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise.

Lára àwọn atẹsita náà lórí ohun ibaraẹnise ẹlẹyẹ (twitter, now called X), ọ̀rọ̀ náà wà nínú ohun kan tí wọ́n yà tí ó ní àwòrán Ààrẹ náà ní abẹlẹ.

“Ǹjẹ́ òótọ́ ni pé Ààrẹ George Weah sọ ọ̀rọ̀ burúkú sí @OfficialABAT (Asiwaju Bola Ahmed Tinubu)? Mo fẹ́ràn ọ̀rọ̀ yìí”, báyìí ni àkòrí ọ̀rọ̀ yìí ṣe wí.

Àwọn ènìyàn ti wo àwòrán náà ní ọ̀nà ẹgbẹrin mẹrindinlọgọta láti ọjọ́ kẹta, oṣù kẹjọ tí wọ́n ti fi sórí àwọn ohun ibaraẹnise.

Is this true @officialABAT was slammed by Liberian President 🤣😂😂
I love this quote

Augmentin | RCCG | Transcorp Hilton Hotel | David Hundeyin | GOLIATH HAS FALLEN | Niger pic.twitter.com/VFtLyw99mb

— Work ethics (@workethicsng) August 3, 2023

“As long as ECOWAS tolerates institutional coups that allow lifetime presidencies, there will always be military coups.

And we cannot condemn military coups when we do not condemn those who carry out institutional coups."~George Weah.

The President of Liberia 🇱🇷 pic.twitter.com/jusGWQIENZ

— Charly Boy Area Fada 1 (@AreaFada1) August 4, 2023

“Níwọ̀n ìgbà tí ẸKOWAASI (Economic Community of West African States) fi ara mọ́ ifipagba ìjọba tí ènìyàn kan fi lè ṣe Ààrẹ títí di ìgbà tí yóò fi kú, ifipagba ìjọba yóò máa ṣẹlẹ̀”, ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní Weah sọ nìyí.

IFIPAGBA ÌJỌBA TÍ ÀWỌN ÒṢÌṢẸ́ OLÓGUN ṢE NÍ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NIJE

Ní ọjọ́ kẹrindinlọgbọn, ọdún 2023, àwọn òṣìṣẹ́ ológun orílẹ̀-èdè Nije fipá yọ Mohamed Bazoum, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nije kúrò ní ipò Ààrẹ. Wọ́n sì fi sí àtìmọ́lé. Orúkọ asiwaju àwọn tí ó ṣe nkan yìí ni Abdourahamane Tchiani.

Wákàtí díẹ̀ lẹ́hìn ifipagba ìjọba yìí, Amadou Abdramane, agbẹnusọ àwọn òṣìṣẹ́ ológun ní Nije kéde pé “àwọn òṣìṣẹ́ alaabo ti fi òpin sí ìjọba tí àwọn ènìyàn mọ̀ nípa rẹ̀.”

Ọjọ́ méjì lẹhin èyí, Tchiani sọ pé ohùn ni Ààrẹ báyìí fún àwọn tí ó pè ní the National Council for the Safeguard of the Homeland (CNSP).

Nije, orílẹ̀-èdè tí ó ní uranium, godi (gold) gba òmìnira ní ọjọ́ kẹta, oṣù kẹjọ, ọdún 1960 ní ọwọ́ orílẹ̀-èdè Faransé (France).

Láti ìgbà yìí, ifipagba ìjọba márùn-ún ló ti ṣẹlẹ̀ níbẹ̀. Èyí tí kò pẹ́ lára ifipagba ìjọba yìí ló ṣẹlẹ̀ ní oṣù keje, ọdún 2023.

Ifipagba ìjọba àkọ́kọ́ ṣẹlẹ̀ ní ọdún 1974. Àwọn yòókù ṣẹlẹ̀ ní ọdún 1996, 1999 àti 2010.

Àwọn orílẹ̀-èdè tí ó sún mọ́ Nije ni Mali, Burkina Faso àti Guinea tí wọ́n jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ ẸKOWAASI. Àwọn ológun ni wọ́n ń ṣe ìjọba ni àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí lọ́wọ́lọ́wọ́.

Ní ọgbọ́n ọjọ́, oṣù keje, ní ìdáhùn sí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí, Bọla Tinubu, Ààrẹ Nàìjíríà, ẹni tí ó tún jẹ́ alága ẸKOWAASI pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè míràn tí ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ ẸKOWAASI ṣe ìpàdé ní Abuja, olú ìlú Nàìjíríà. Kókó ìpàdé náà ni bí wọ́n yóò ṣe yanjú rògbòdìyàn tí ifipagba ìjọba fà ní Nije.

Lẹ́hìn ìpàdé náà, ẸKOWAASI fún àwọn òṣìṣẹ́ ológun tí wọ́n fi ipá gba ìjọba ni Nije ní ọjọ́ méje láti dá Bazoum sí ipò rẹ̀, kí wọ́n sì gbé ìjọba fún àwọn tí ará ìlú dìbò yàn tàbí kí wọ́n kabamọ.

Láfikún, ní ọgbọ́n ọjọ́, oṣù keje, ẹgbẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè adúláwọ̀/Áfíríkà (African Union-AU) sọ fún àwọn olórí ológun kí wọ́n dá Bazoum padà sí ipò Ààrẹ láàárín ọjọ́ mẹẹdogun.

Nígbà tí ó ń sọ̀rọ̀ nípa ọ̀sẹ̀ kan tí ẸKOWAASI fún àwọn afipagba ìjọba yìí, Abdramane sọ pé “a fẹ́ rán ẸKOWAASI tàbí ẹnikẹ́ni létí pé mìmì kan kò lè mi ìlérí wa láti dá ààbò bo ilẹ̀ wa.”

Ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní Weah, ẹni tí ó jẹ́ agbabọọlu tẹ́lẹ̀rí ní ìdáhùn sí nkan tí ẸKOWAASI fẹ́ ṣe ní Nije sọ pé “A kò lè sọ pé ifipagba ìjọba kò dára nígbà tí a kò sọ wí pé àwọn tí wọ́n sọ ìjọba di nibinimakusi, oyè ìdílé kò ṣe dáadáa.”

Ǹjẹ́ Weah sọ báyìí? Níbo ló ti sọ?

ÀBÁJÁDE ÀYẸ̀WÒ WA RÈÉ

Agbeyẹwo wa fi yé wa pé biotilẹjẹpe ọ̀rọ̀ yìí ti ń tàn rànyìn lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise láti oṣù kẹjọ, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀rọ̀ àti ìròyìn kò sọ ìgbà tàbí ibi tí Weah ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.

Ayẹwo tí a tún ṣe sí jẹ́ kí a rí atẹjade kan tí ìwé ìròyìn Sierra Leone Telegraph gbé tí ó ní àkọ́lé: “Àwọn olórí orílẹ̀-èdè ẸKOWAASI dá ìjọba Guinea dúró. Wọ́n sì dá àwọn afipagba ìjọba lẹ́bi nípa ààbò Conde.”

He made the statement 2021, it’s still valid.

— Bethel Anunihu (@Bethel_Anun) August 4, 2023

Wọ́n gbé ìròyìn yìí jáde ní ọjọ́ Kẹwa, oṣù kẹsàn-án, Ọdún 2021. Ọ̀rọ̀ yìí sì jọ ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní Weah sọ yìí nígbà ìpàdé onifidio tí àwọn olórí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ ẸKOWAASI ṣe.

Ìjíròrò níbi ìpàdé náà dá lórí ifipagba ìjọba tí wọ́n fi yọ Alpha Conde, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Guinea, ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹtalelọgọrin nígbà tí ifipagba ìjọba yìí ṣẹlẹ̀.

Nígbà ìpàdé yìí, Weah sọ pé ifipagba ìjọba ní Guinea wá yé nítorí pé Conde fẹ́ yí ìwé òfin iselu láti lè ṣe ìjọba ẹkẹta.

“Biotilẹjẹpe a kò fẹ́ràn ìwà yìí, a gbọ́dọ̀ wo ohun tí ó fa àwọn ifipagba ìjọba yìí. Ṣé kìí se pé a kò tẹ́lẹ̀ ìlànà ìjọba tí ó ṣe agbekalẹ iye ìgbà tí ènìyàn gbọ́dọ̀ lò lórí ìjọba ni? Weah ló sọ bayii fún àwọn olórí orílẹ̀-èdè Áfíríkà ní ọdún 2021.

Biotilẹjẹpe ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní Weah sọ kìí ṣe ohun tí ó sọ ní ìpàdé ẸKOWAASI ní ọdún méjì sẹhin, ohun kan náà ni ó fẹ́ jẹ́ kí àwọn ènìyàn mọ̀.

Ledgerhood Renni, minisita fún ifiọrọtonileti sọ fún TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára pé ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní Weah sọ yìí nípa ifipagba ìjọba ní Nije kìí se òtítọ́.

Ní ọjọ́ kejìdínlọgbọn, oṣù keje, ọdún 2023, ìjọba Liberia sọ pé ifipagba ìjọba ní Nije kò dára.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Ọ̀rọ̀ tí wọ́n ní Weah sọ pé òun fi ara mọ́ ifipagba ìjọba ní Nije kìí se òótọ́. Irọ́ gbáà ni.

TAGGED: George Weah, Ifiidiododomulẹ, ifipagba ìjọba, òótọ́, orílẹ̀-èdè Nije (Niger), Oro, So

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael August 11, 2023 August 11, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?