TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ìròyìn Ẹlẹ́jẹ̀: Ilé-ẹjọ́ ọ fagile èsì ìbò abẹ́nú APC ní Èkìtì
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ìròyìn Ẹlẹ́jẹ̀: Ilé-ẹjọ́ ọ fagile èsì ìbò abẹ́nú APC ní Èkìtì

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published June 18, 2022 4 Min Read
Share

Ilé ẹjọ́ gíga ti ìjọba àpapọ̀ ìlú Abuja ò jòkó ni ọjọ́bọ̀ lórí ìbò abẹ́nú ti egbé òsèlú All Progressives Congress ní Ìpínlè Èkìtì.

Ìròyìn tán ràn-ìn lórí ayélujára pé ilé ẹjọ́ gíga Abuja fagilé ìbò abẹ́nú ẹgbẹ́ òsèlú APC ní Èkìtì, èyí sí túmọ sí wípé Bíọ́dún Oyèbanji, olùdíje ẹgbẹ́ náà, kò ní kópa nínú ìdìbò òún.

Ọjọ kejìdínlógún oṣù kẹfà ní ìdìbò gómìnà Èkìtì yóò wáyé.

Àyẹwò TheCable fihàn wípé kò sí irúfé ìjòkó bẹẹ ní Ọjọ́bọ̀.

Catherine Oby-Christopher, ẹni tí ó jẹ amugbalẹgbẹ olùdarí fún ìròyìn ní Ilé ẹjọ́ gíga ti ìjọba àpapọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde kàn wípé irọ́ ni èyí.

“Ilé ẹjọ́ gíga ti ìjọba àpapọ̀ ti rí ìròyìn tí ó ń tàn ká’lé ká’ko lórí àkòrí yìí pelu suit nọmbà FHC/ABJ/CS/528/22, pé Adájọ́ àgbà Inyang Ekwo ṣe ìdájọ́ wípé Biodun Oyebanji, kòlè kópa nínú ìdìbò gómìnà Èkìtì, ní wákàtí díẹ̀ sí ìdíje náà,” àtẹ̀jáde yìí wí.

“Kò sí oun tó jọ bẹ́ẹ̀. Kódà kò sí ẹjọ́ kan-kan tó tan mọ́ ọ̀rọ̀ náà ní sàkání agbára ilé ẹjọ́ yìí.

“Ilé ẹjọ́ yìí fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé a kò gbé irúfẹ́ ẹjọ́ báyìí wá síwájú Adájọ àgbà I.E. Ekwo.

“Ìròyìn òfégè ni ìròyìn yìí, wọ́n sì fẹ fí tan ará ìlú jẹ ní, kí o sí dá rògbòdìyàn ati àìbalẹ̀ ọkàn.

“Ìròyìn ẹlẹ́jẹ̀ yìí burú jái, a sì lòdì síi pẹ̀lú. Arọ àwọn ará ìlú kí wọn má ṣe f’ọkan síi.

Segun Dipe, agbẹnusọ ẹgbẹ́ òṣèlú APC ní ìlú Ekiti sọ pé ìrọ́ tó jìnà sí òtítọ́ ni ìròyìn náà, ofi kun wípé bótilè jẹ́ wípé oríṣi ẹjọ́ ló wà níwájú ilé ẹjọ́ káàkiri, kò sí èyí tí ó ti kọjá ipele àkọ́kọ́.

“Ìròyìn ẹlẹ́jẹ̀ náà jẹ ète àwọn ẹgbẹ́ alátakò tí wọ́n kò mọ̀ wípé ète yìí yóò mú àbùkù bá wọn ní inú ìdíje náà.

“Bótilẹ̀ jẹ́ wípé kò yẹ ki ẹnikẹni f’ọkan sí ìròyìn yìí, ojúṣe wa ni láti sọ fún àwọn ènìyàn kí wọn má ṣe kọbiarasi ìròyìn tó jìnà sí òótọ́ yìí.

“Looto, awọn kan fí esun le’lẹ nípa ìdìbò abẹ́lé ti o waye ni oṣù kínní tí Biodun Abayomi Oyebanji sí ṣe Olubori nínú re party, àmọ́, àwọn ẹjọ́ yìí ò kọjá ipele àkọ́kọ́, wọ́n sì ti gbé àwọn ẹjọ́ yìí lọ sí Ekiti fún igbẹ́jọ́.

“Kò sí ilé ẹjọ́ gíga kan-kan ti o jòkó lórí ìdìbò abẹ́lé wa ni Abuja lónìí. Pẹ̀lú pẹ̀lú, ilé ẹjọ́ ti sún gbogbo igbẹ́jọ́ nípa ọ̀rọ̀ ìdìbò abẹ́lé wa sí Ọwẹ́wẹ̀, ọdún yìí. Kò sí ẹ̀yí tí igbẹ́jọ́ rẹ̀ ń wáyé lásìkò yìí. Gbogbo akitiyan ẹgbẹ́ òṣèlú wa ni kí a ṣe àṣeyọrí nínú ìdìbò yìí.

“Wàyí Egbẹ́ òsèlú APC ń sọ fún gbogbo olùdibò ní Ìpínlè Èkìtì kí wọ́n f’ọkàn balẹ̀, kí wọn sì má ṣe ojo nínú ìpinu wọn láti dìbò fún àyànfẹ olùdíje, Oyebanji àti ẹgbẹ́ òṣèlú APC ní ọjọ́ àbámẹ́ta, ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kẹfà, ọdún 2022.”

 

A kọ ìròyìn yìí ni ajọṣepọ pẹlu Report for the World, eto agbaye ti o ṣe atilẹyin iṣẹ iroyin tiwa-n-tiwa.

TAGGED: APC, Biodun Oyebanji, Ekiti

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo June 18, 2022 June 18, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?