TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé owó pẹtiroolu lítà kan ní Nàìjíríà ló kéré jù l’agbaye bí Ẹniọlá Badmus ṣe wí?
Share
Latest News
Did Tinubu attend same school with Alexander Zingman? Here is what we know
FACT CHECK: Did Nigeria deploy peace support mission to Israel?
FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?
FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?
FACT CHECK: Ndume erred. 22 governors didn’t endorse Jonathan in 2015
Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé
Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá
No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé owó pẹtiroolu lítà kan ní Nàìjíríà ló kéré jù l’agbaye bí Ẹniọlá Badmus ṣe wí?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published July 30, 2023 8 Min Read
Share

Ẹniọlá Badmus, òṣèré gbajúmọ̀ ti sọ pé biotilẹjẹpe ìjọba Nàìjíríà ti yọ owó kiaramabani àwọn ènìyàn fún epo pẹtiroolu tí ó sì jẹ́ kí owó lítà epo kan lé ju owó tí wọ́n ń tàá tẹ́lẹ̀, iye tí Nàìjíríà ń ta epo pẹtiroolu ló kéré jù ní àgbáyé.

Òṣèré náà, ẹni tí ó jẹ́ gbajúgbajà alátìlẹ́yìn Ààrẹ Bọla Tinubu, sọ ọ̀rọ̀ yìí níbi tí wọ́n ti fi ọ̀rọ̀ wáa lẹ́nu wò lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise tí àwọn ènìyàn ti ń pín àwòrán wọn tí Daddy Freeze, ẹni tí ó jẹ́ ìlúmọ̀ọ́ká agbohunsafẹfẹ ṣe.

Badmus sọ wí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ pé ìjọba Tinubu sedakoseda kò mọ àǹfààní owó kiaramabani àwọn ènìyàn tí Tinubu yọ yìí.

“Gẹ́gẹ́bí ọmọ orílẹ̀-èdè yìí, mo ní ẹ̀tọ́ láti lè sọ ọ̀rọ̀ bí mo ṣe rò. Mo lè ṣe atilẹyin fún ẹni tí mo bá fẹ́,” arábìnrin yìí ni ó sọ báyìí.

“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn tí ó jẹ́ wí pé orí ayélujára nìkan ni wọ́n ti máa ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí kò ti ẹ̀ mọ ohun tí owó kiaramabani àwọn ènìyàn jẹ́. Ìgbà tí Ìjọba yọọ́ ni wọ́n tó mọ nkan tí Ìjọba ń ṣe. Títí di àsìkò yìí, mo rò pé àwa ló sìí ń ra epo pẹtiroolu ní iye tí owó rẹ̀ kéré jù ní àgbáyé.

“Mímí kan kò lè mi Ààrẹ Tinubu. Lẹ́hìn pé mò ń ṣe atilẹyin fún un, mo ti rí nkan tí ó ti ṣe. Mo sì mọ ohun tí yóò ṣe. N kò tíì rí onínúrere, afunnimawobẹ, oluranlọwọ àwọn aláìní bíi ti Ààrẹ wa yìí. N yóò ṣe àtilẹyin fun títí yóò fi kúrò ní ipò Ààrẹ.

YÍYỌ OWÓ KIARAMABANI ÀWỌN ÈNÌYÀN FÚN PẸTIROOLU 

Ní ọjọ́ kọkàndínlógún, ọdún 2023, Ààrẹ Tinubu nígbà tí ó ń bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ lẹ́hìn tí wọ́n ṣe ìbúra fún un tán gẹ́gẹ́bí Ààrẹ ilẹ̀ Nàìjíríà sọ wí pé òpin ti dé bá owó kiaramabani àwọn ènìyàn fún epo pẹtiroolu.

“Nípa owó kiaramabani àwọn ènìyàn fún epo pẹtiroolu, ètò owó níná tí ó wà ní ilẹ̀ kí n tó di Ààrẹ ní wí pé kò sí agbekalẹ kankan fún owó kiaramabani àwọn ènìyàn fún epo pẹtiroolu. Nípa ìdí èyí, òpin ti dé bá owó yìí,” Tinubu ni ó wí báyìí.

Ó fikùn ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé kò sí àlàyé tí ó munadoko tí Ìjọba lè ṣe lórí owó iyebíye tí wọ́n ń nọ́ lórí owó kiaramabani àwọn ènìyàn tí Ìjọba ń nọ́ ní gbogbo ìgbà ní àsìkò tí kò sí owó yìí.
“A gbóríyìn fún ìjọba tí ó lọ lórí owó kiaramabani àwọn ènìyàn tí wọ́n yọ, èyí tí ó ń ṣe àǹfààní fún àwọn olówó, tí ó sì ń jẹ́ kí ebi pa àwọn aláìní.

“A máa nọ́ owó tí a yọ yìí lórí àwọn ohun tí ó lè mú owó wọlé bíi ojú ọ̀nà, ètò ẹ̀kọ́, ètò ìlera àti ìpèsè iṣẹ́ àti àwọn ohun amayedẹrun fún àwọn ènìyàn púpọ̀.

Ní aipẹ tí Tinubu sọ ọ̀rọ̀ yìí, owó epo pẹtiroolu lọ sókè. Kí ó tó sọ ọ̀rọ̀ yìí, owó lítà epo kan jẹ́ igba ó dín mẹwa náírà. Lẹ́hìn tí ó sọ ọ̀rọ̀ yìí, owó lítà kan di ẹẹdẹgbẹta náírà.

Ní ọjọ́ kejìdínlógún, àwọn alagbata epo sọ iye owó lítà kan di ẹgbẹtalelogun ó dín mẹ́ta náírà ní Abuja àti ẹẹdẹgbẹta àti àádọ́rin ó dín méjì náírà ní ìlú Èkó.

Ǹjẹ́ owó lítà epo ní Nàìjíríà ni ó kéré jù ní àgbáyé?

TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe ìwádìí iye owó lítà epo kan ni àwọn oríṣiríṣi orílẹ̀-èdè. Àbájáde wa rèé.

ÀYẸ̀WÒ OWÓ EPO NÍ ÀGBÁYÉ

Gẹ́gẹ́bí globalpetrolprices, àwọn tí wọ́n máa ń mọ iye owó pẹtiroolu, iná mọ̀nàmọ́ná àti gaasi ni àwọn orílẹ̀-èdè tó ju àádọ́jọ lọ ṣe wi, orílẹ̀-èdè Venezuela ni owó epo ti kéré jù. Iye owó lítà kan níbẹ̀ lé díẹ̀ ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta náírà.

Ìwádìí tí a tún ṣe síwájú fi yé wa pé iye owó epo ní orílẹ̀-èdè ogún dín ní ẹgbẹtalelogun ó dín mẹ́ta náírà.

Lára àwọn orílẹ̀-èdè yìí ni Ìran, Libya, Algeria, Kuwait, Angola, Egypt, Turkmenistan, Malaysia, Kazakhstan, Bahrain, Bolivia, Iraq, Quartar, Azerbaijan,Russia, Oman, Saudi Arabia, Ecuador, Kyrgyzstan, and Afghanistan.

S/N Country Price in $ as of July 24 CBN Exchange rate on July 24 price in Naira
1. Venezuela 0.004 781.85 3.1274
2. Iran 0.029 781.85 22.67365
3. Libya 0.031  781.85 24.23735
4. Algeria* 0.34 781.85 265.829
5. Kuwait* 0.342 781.85 267.3927
6. Angola 0.364  781.85 284.5934
7. Egypt* 0.372 781.85 290.8482
8. Turkmenistan 0.429 781.85 335.41365
9. Malaysia* 0.448 781.85 350.2688
10. Kazakhstan 0.488  781.85 381.5428
11. Bahrain 0.531  781.85 415.16235
12. Bolivia* 0.542  781.85 423.7627
13. Iraq 0.573  781.85 448.00005
14. Qatar* 0.577  781.85 451.12745
15. Azerbaijan 0.588  781.85 459.7278
16. Russia* 0.589 781.85 460.50965
17. Oman* 0.621 781.85 485.52885
18. Saudi Arabia* 0.621 781.85 485.52885
19. Ecuador* 0.634 781.85 495.6929
20. Kyrgyzstan* 0.741 781.85 579.35085
21. Afghanistan 0.743 781.85 580.91455
22. Nigeria 0.778 781.85 608.2793
23. UAE* 0.787 781.85 615.31595
24. Tunisia 0.832 781.85 650.4992
25. Bhutan 0.845 781.85 660.66325
26. Lebanon* 0.863 781.85 674.73655
27. Indonesia* 0.864 781.85 675.5184
28. Colombia* 0.867 781.85 677.86395
29. Pakistan* 0.878 781.85 686.4643
30. Argentina* 0.924 781.85 722.4294
31. Belarus* 0.935 781.85 731.02975

Mọkandinlogun nínú mẹ́tàlélógún àwọn orílẹ̀-èdè tí a ṣe ìwádìí iye tí wọ́n ń ta epo lítà kan ni wọ́n ń tàá ní owó tí ó dín ní ẹẹdẹgbẹtalelaadọrin ó dín méjì náírà (N568), èyí tí ó jẹ́ owó lítà epo tí ó kéré jù ní Nàìjíríà.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÍ SÍ

Ọ̀rọ̀ tí Ẹniọlá Badmus sọ pé owó epo lítà kan ní Nàìjíríà ni ó kéré jù nínú owó tí wọ́n ń ta lítà kan ní àgbáyé kìí se òótọ́. Irọ́ ni.

Lọ́wọ́lọ́wọ́, orílẹ̀-èdè mọkandinlogun nínú àwọn orílẹ̀-èdè àgbáyé ni wọ́n ń ta lítà epo ní owó tí ó dín ní ẹẹdẹgbẹtalelaadọrin ó dín méjì náírà, iye owó lítà epo kan ní ìlú Èkó.

Fún ìròyìn yìí, owó orílẹ̀-èdè miran tí a fi wo ọ̀rọ̀ yìí tàbí fiwé/ṣe pasipaarọ ni dọla kan ($1), èyí tí ó jẹ́ ẹgbẹrin dín ní mọkandinlogun náírà owó Nàìjíríà gẹ́gẹ́bí Bánkì ijọba Àpapọ̀ Nàìjíríà (Central Bank of Nigeria) ṣe tẹ̀ẹ́ síta ní ọjọ́ kẹrinlelogun, oṣù keje, ọdún 2023 nígbà tí arábìnrin òṣèré yìí sọ̀rọ̀ yìí.

TAGGED: àgbáyé, Eniola Badmus, Ifiidiododomulẹ, kéré jù, Nàìjíríà, owó epo pẹtiroolu lítà kan

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael July 30, 2023 July 30, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Did Tinubu attend same school with Alexander Zingman? Here is what we know

During the launch of the renewed hope mechanisation programme in Abuja on Monday, President Bola…

June 24, 2025

FACT CHECK: Did Nigeria deploy peace support mission to Israel?

A Facebook video purports that Nigeria deployed troops for a joint peace support mission in…

June 24, 2025

FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?

A viral X post claims that Nigeria’s new national anthem was not recited during the…

June 13, 2025

FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?

Reports of a military coup in Cameroon ousting President Paul Biya have gone viral on…

June 13, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé

Ẹni kan tí ó ń lo Facebook, ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ orí ayélujára sọ pé Robert Francis Prevost, Pope Leo XIV…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá

Ótù onye na Facebook ekwuola na Pope Leo na ụfọdụ ndị Bishop yọrọ onye isiala Bola Tinubu ka ọ tọpụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu

One Facebook user claim sey Pope Leo XVI and oda bishops join mouth beg President Bola Tinubu to release Nnamdi…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

A’a, Paparoma Leo bai nemi Tinubu ya saki Nnamdi Kanu ba

Wani mai amfani da Facebook ya yi ikirarin cewa Paparoma Leo na 16 da wasu limaman coci sun roki shugaban…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?