TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé òtítọ́ ni wí pé ìpínlẹ̀ Borno tóbi tó orílẹ̀-èdè UK àti Sweden?
Share
Latest News
FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated
MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé òtítọ́ ni wí pé ìpínlẹ̀ Borno tóbi tó orílẹ̀-èdè UK àti Sweden?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published September 12, 2022 7 Min Read
Share

Yemi Osinbajo, igbá-kejì Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà sọ láìpẹ́ yìí pé, ìpínlẹ̀ Borno tóbi tó United Kingdom (UK) àti Sweden lápapọ̀ tàbí orílẹ̀-èdè UK àti Denmark. 

Nínú àtẹ̀jáde kan, Laolu Àkàndé, ẹni tí ó jẹ́ agbẹnusọ fún Osinbajo, fi ye wa pé igbá-kejì ààrẹ sọ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí ó ń jíròrò pẹ̀lú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ìwé tí a ti ń kọ ni nípa ọrọ ajé ti ìlú Harvard (Harvard Business School) ní ìlú Amẹ́ríkà tó ṣe abẹwo síi ní Presidential villa, ibi ibùgbé ìjọba fún Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọjọ́ àìkú, ọjọ́ kejidinlọgbọn oṣù kẹjọ, ọdún yìí.

Ní ìgbà tí ó ń bá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà sọ̀rọ̀, Osinbajo ní kí àgbáyé lè ní òye bí ọrọ̀ ajé àti rògbòdìyàn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣe tóbi tó pẹ̀lú bí ó ṣe takoko sí, o dáa kí a fi ye wọn.

“Lakọkọ, a ní láti mọriri bí Nàìjíríà ṣe tóbi tó, lára oun tí ó ṣe pàtàkì tí a gbọ́dọ̀ jẹ́ kí àwọn ènìyàn mọ ni àwọn iṣoro tí ó ń dojú kọ Nàìjíríà.

“Fún àpẹẹrẹ, ìpínlẹ̀ Borno tóbi tó orílẹ̀-èdè UK àti Sweden tabi orilẹ-èdè Denmark,” Ọjọgbọn nípa ofin náà ló sọ báyìí.

“Nítorí náà, tí ẹ bá gbọ́ ìròyìn nípa rògbòdìyàn ni Nàìjíríà, ó lè jẹ́ pé ìṣẹ̀lẹ̀ náà wáyé ní ibì kan, ó sì leè jẹ́ pé Ìpínlẹ̀ Èkó ati Abuja, olú ìlú orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nìkan ni àwọn ènìyàn ti gbọ nípa ìṣẹ̀lẹ̀ yìí lori ayélujára, bẹẹni Nàìjíríà ṣe tóbi tó.

“Tí a bá ń sọ̀rọ̀ nípa ọrọ̀ ajé orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, ni ọ̀pọ̀ ìgbà, àwọn ènìyàn máa ń sábà fi bí ọrọ ajé àti rògbòdìyàn tí ó ṣẹlẹ̀ ni Naijiria ṣe tó wé ti àwọn orílẹ̀-èdè kékeré ní ilẹ̀ Áfíríkà, ṣùgbọ́n àpapọ̀ ọrọ̀ ajé (Gross Domestic Product) Ìpínlẹ̀ mẹ́wàá ni Naijiria tóbi ju ti àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí lọ.”

Ṣé ilẹ̀ tí ìpínlẹ̀ Borno ní ju ti UK àti Sweden lapapọ tàbí ti UK àti orílẹ̀-èdè Denmark?

Ọpọlọpọ ilé iṣẹ́ ìròyìn ló gbé ìròyìn yi.

Iṣaridaju

Ìwé Ìròyìn TheCable sàyẹ̀wò bí Ìpínlẹ̀ Borno ṣe tóbi tó, Ìpínlẹ̀ náà wà ní àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. A dá Ìpínlẹ̀ náà sílẹ̀ ní oṣù kejì, ọdún 1976, a yọ Ìpínlẹ̀ Yobe (dá sílẹ) láti ara Ìpínlẹ̀ Borno ní ọdún 1991.

A máa ń pe ìpínlẹ̀ Borno ni ilẹ̀ àlàáfíà, ní apá iwọoorun ìpínlẹ̀ Borno ni ìpínlẹ̀ Yobe wà. Borno ní ààlà pẹ̀lú orílẹ̀-èdè Niger, Lake Chad àti Cameroon.

Ni orí ayélujára, ìjọba ìpínlẹ̀ Borno ṣàlàyé pé ìlú náà ní ilẹ̀ tí wiwọn rẹ tó ẹgbẹ̀rún ní ọna ọgọ́ta lé ní ọkan, le ni ẹgbẹ̀rún ati irínwó pẹ̀lú aarun dín ní ogójì (61,435sqkm), èyí tí ó fi jẹ́ ìpínlẹ̀ kejì tó tóbi jùlọ ní Nàìjíríà lẹ́yìn ìpínlẹ̀ Naija.

A ṣe ìmúlò data tí àjọ ètò ìṣirò-National Bureau of Statistics (NBS) gbé jáde ní ọdún 2020, a ríi wí pé gẹ́gẹ́bí data lati àjọ National Population Commission, èyí ni àjọ tí ó ń ṣètò ìkànìyàn ní ọdún 2019, iye ènìyàn tí ó ń gbé ní Ìpínlẹ̀ Borno jẹ́ mílíọ̀nù márùn pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún ní ọna ẹẹdẹgbẹrin (5.7 million).

Àwọn ìlú tí ó kórapọ tí ó ń jẹ UK ni England, Wales, Scotland àti Northern Ireland-àríwá orílẹ̀-èdè Republic of Ireland.

Data láti bánkì àpapọ̀ àgbáyé (World Bank) ni ọdún 2021 fihàn pé ilẹ̀ tí UK ní jẹ́ ọ̀kẹ́ méjìlá le ni ẹgbẹ̀rún ó dín ni àádọ́rin (241,930 km²).

Àjọ ètò ìṣirò orílẹ̀-èdè UK (UK’s Office of National Statistics), àjọ ètò ìṣirò tó tóbi jùlọ sọ wí pé iye ènìyàn orílẹ̀-èdè náà jẹ miliọnu mẹ́tadínníàádọ́rin (67 million).

Sweden wá ní ilẹ̀ Lárúbáwá tí agbegbe Scandinavia ni àríwá ilẹ̀ Yúrópù. Láti ọdún 1523 ni Olú ìlú orílẹ̀-èdè Sweden ti wà ní Stockholm. Ilẹ̀ tí Sweden wá ni ó pọju ní erékùṣù tí a mọ sí Scandinavia. Ilẹ̀ Sweden ni ààlà pẹ̀lú orílẹ̀-èdè Norway.

Biotilẹjẹpe orílẹ̀-èdè náà tí wà láti bí ẹgbẹ̀rún ọdún, àyípadà ń dé bá ilẹ tí ó wà títí di bí ọdún 1809. Data Banki fún Àgbáyé (World Bank) fi ye wa pé ilẹ̀ tí orílẹ̀-èdè náà wà tó bí ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà irinwolenimeje àti ọdunrun lé ní mẹwa, ó sì ní iye ènìyàn tí ó jẹ miliọnu mẹwa àti ẹgbẹ̀rún ní ọna irinwo.

Denmark wa ní erékùṣù ìlú Jutland, tó ràn lọ sí iha àríwá láti àárín agbègbè ila oorun ti Yúrópù. Jutland gba méjì nínú idamẹta iwọn ilẹ̀ orílè-èdè naa.

Ní ọdún 2021, data banki agbaye fihàn pé iwọn ilẹ̀ ìlú Denmark jẹ ẹgbẹ̀rún ní ọna ogójì (40,000 km²), iye ènìyàn tó si n gbe ni orílẹ̀-èdè náà jẹ mílíọ̀nù márùn-ún lé ní ẹgbẹ̀rún ní ọna ẹgbẹrin (5.8m).

Ní òtítọ́ ni Borno ju ìlú Denmark lọ, ó sì fẹrẹ ní iye ènìyàn kan náà. Sùgbọ́n Ìpínlẹ̀ Borno kéré sí iwọn ilẹ̀ àti iye ènìyàn Sweden àti UK.

Ìwádìí TheCable fihàn pé ìwọn ilẹ̀ ati iye ènìyàn tó wà ni UK nikan ju ti ìpínlẹ̀ Borno lọ, laiti mẹnuba Sweden tàbí Denmark.

Borno United Kingdom  Sweden Denmark United Kingdom + Sweden United Kingdom + Denmark
Landmass (km²) 61,435 241,930  407,310  40,000  649,240  281,930
Population 5,751,590 67,081,000 10,415,811 5,856,733 77,496,811 72,937,733

Àbájáde Ìwádìí 

Irọ́ àti àsọdùn ni ọ̀rọ̀ tí Osinbajo, igbá-kejì Ààrẹ orílè-èdè Nàìjíríà sọ pé ilẹ̀ Ìpínlẹ̀ Borno tóbi tó àpapọ̀ ilẹ̀ UK ati Sweden tàbí tí UK àti Denmark.

TAGGED: borno state, Check Am For Wazobia, Harvard Business School, United Kingdom, Yemi Osinbajo.

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo September 12, 2022 September 12, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Video showing ‘bridge collapsing in Nasarawa’ is AI-generated

A video showing a bridge collapse incident is circulating across social media platforms, especially on…

July 24, 2025

MISINFO ALERT: Viral video of ‘foreign arms dealer’ in Zamfara is from 2021, says army

The Nigerian Army says a viral video claiming the arrest of a foreign arms dealer…

July 24, 2025

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?