TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé òtítọ ni wí pé Aregbesola pẹgan Oyetola nínú fónrán yìí?
Share
Latest News
Did Tinubu attend same school as Alexander Zingman? Here is what we know
FACT CHECK: No, Nigeria didn’t deploy peace support mission to Israel
FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?
FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?
FACT CHECK: Ndume erred. 22 governors didn’t endorse Jonathan in 2015
Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé
Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá
No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé òtítọ ni wí pé Aregbesola pẹgan Oyetola nínú fónrán yìí?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published October 10, 2022 3 Min Read
Share

Fónrán fídíò kàn tó ṣ’àfihàn Rauf Aregbesola, mínísítà fún ọrọ abẹlé, tó sì jẹ gómìnà Ìpínlẹ Osun tẹlẹrí ní ibi tó ti ń ṣ’àjọyọ, ni àwọn ènìyàn ń pín káàkiri orí ayélujára.

Àwọn olumulo ìkànnì abẹ́yẹfò (Twitter) ti ṣ’atunpin fídíò náà níbi tí wọn ti ṣe àhesọ pé mínísítà náà ń jó/yọ̀, ó sì ń pẹgan Gboyega Oyetola, gómìnà Ìpínlẹ̀ Osun lẹ́yìn àṣẹ ilé-ẹjọ́ gíga ní ìlú Abuja tó ní Oyetola kò yẹ láti díje du ipò gómìnà ní ìgbà kejì.

Olùmúlò ìkànnì abẹ́yẹfò tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ @IfedolapoOsun fi àtẹ̀jáde náà sí ojú òpó rè ní ọgbọ̀n ọjọ́, oṣù kẹsàn-án, ọjọ́ tí ilé-ẹjọ́ gíga fagilé iyansipo Oyetola àti igbá-kejì rẹ̀ tí a mọ sí Benedict Alabi.

Àwọn aṣàmúlò ojú òpó ti wo fónrán náà ní ìgba ẹgbèrún mẹtalelogun àti irinwo, wọ́n bu ọwọ́ ìfẹ́ lúù ni ìgba ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ́rún dín ní mókànlá, wọ́n sì ṣ’atunpin rẹ̀ ní ọna ọọdunrun àti mejilelaaadọta.

Aregbesola Today after Court Nullified Gboyega Oyetola's candidacy 🤣🤣 pic.twitter.com/2fEi8tbS1P

— Governor Ifedolapo Osun (@IfedolapoOsun) September 30, 2022

Wọ́n ṣ’atunpin fídíò náà pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ìfòrí yìí: “Aregbesola lónìí, lẹ́yìn tí ilé-ẹjọ́ fagilé iyansipo Gboyega Oyetola.”

Àwòrán Ademola Adeleke, ẹni tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ìbò yàn sí ipò Gómìnà ni Ìpínlẹ̀ Ọsun ló wà ní profaili ojú òpó tó ṣ’atunpin fídíò náà, èyí tó si ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùmúlò lọ́nà, tí wọn sì rò pé Adeleke ló pín fídíò náà.

Ìròyìn atẹhinwa

Emeka Nwite ni adajọ tó jókòó lórí ẹjọ́ náà pẹ̀lú nomba: FHC/ABJ/CS/468/2022 tí ẹgbẹ ́òṣèlú Peoples Democratic Party (PDP) sì jẹ́ olupẹjọ.

Nínú igbẹjọ náà, Mai Mala Buni, ẹni tí ó jẹ́ alága ẹgbẹ ́òṣèlú All Progressives Congress (APC) àti àwọn mẹ́rin míràn ni wọ́n jẹ́ olujẹjọ.

Nwite dá ẹjọ́ pé iyansipo Oyetola àti igbá-kejì rẹ̀ lòdì sí òfin nítorípé lábẹ́ òfin, Buni, ẹni tí ó fi orúkọ àwọn Oludije náà ransẹ sí àjọ elétò ìdìbò ní orílẹ̀-èdè Naijiria, Independent National Electoral Commission (INEC) kùnà nínú abala òfin ọgọsan lé ní mẹ́ta àti ìpín kẹta abala eejilelọgọrin, 82 (3) ti òfin ìdìbò (Electoral Act) ti ọdún 2022.

Iṣaridaju

Àyẹwò ìwé ìròyìn TheCable fihàn pé olùmúlò ìtàkùn ibaraẹnidọrẹ (Facebook), Ajiboye Maroof Akinlabi, fi fídíò náà sí ojú òpó rẹ̀ ní ọjọ́ ajé, ọjọ́ kẹrindinlọgbọn, oṣù kẹsàn-án, pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ìfòrí yìí: ”Minisita ọ̀rọ̀ abẹle, Ogbẹni Rauf Aregbesola ṣ’àjọyọ̀ ọjọ́ ìbí ìyàwó rẹ̀, Ìyáàfin Sherifat Aregbesola, ẹni tí ó pé ọmọ ọdún mejilelọgọta.”

TheCable kàn sí Kikiowo Ileowo, olùrànlọ́wọ́ Rauf Aregbesola, ó ní: “ajọyọ ọ̀ún kò níí ṣe pẹ̀lú ìdájọ́ ilé-ẹjọ́ lórí iyansipo Oyetola”, ó fi kún-un wí pé wọ́n gbà fídíò náà sílẹ̀ ní àwọn ọjọ́ díẹ̀ sẹ́yìn ní ibi ayẹyẹ ọjọ́ ìbí aya Aregbesola.

Àbájáde ìwádìí

Aṣinilọ́nà ní fídíò tó s’àfihàn Aregbesola ní ibi tí ó ti ń ṣ’àjọyọ̀ ìdájọ́ tó fagile iyansipo Gboyega Oyetola.

Ìgbà àkọ́kọ́ tí fídíò náà dé orí ayélujára ni ọjọ́ kẹtalelogun oṣù kẹsàn-án, ilé-ẹjọ́ sí jókòó lọ́jọ́ kejidinlọgbọn, oṣù kẹsan.

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo October 10, 2022 October 10, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Did Tinubu attend same school as Alexander Zingman? Here is what we know

During the launch of the renewed hope mechanisation programme in Abuja on Monday, President Bola…

June 24, 2025

FACT CHECK: No, Nigeria didn’t deploy peace support mission to Israel

A Facebook video purports that Nigeria deployed troops for a joint peace support mission in…

June 24, 2025

FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?

A viral X post claims that Nigeria’s new national anthem was not recited during the…

June 13, 2025

FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?

Reports of a military coup in Cameroon ousting President Paul Biya have gone viral on…

June 13, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé

Ẹni kan tí ó ń lo Facebook, ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ orí ayélujára sọ pé Robert Francis Prevost, Pope Leo XIV…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá

Ótù onye na Facebook ekwuola na Pope Leo na ụfọdụ ndị Bishop yọrọ onye isiala Bola Tinubu ka ọ tọpụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu

One Facebook user claim sey Pope Leo XVI and oda bishops join mouth beg President Bola Tinubu to release Nnamdi…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

A’a, Paparoma Leo bai nemi Tinubu ya saki Nnamdi Kanu ba

Wani mai amfani da Facebook ya yi ikirarin cewa Paparoma Leo na 16 da wasu limaman coci sun roki shugaban…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?