TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé òtítọ́ ni pé a lè fi ewé efinrin fọ kíndìnrín mọ́ láìsí ìrora?
Share
Latest News
No, Emefiele no return N4trn to FG
Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà
Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn
A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba
FACT CHECK: No, Emefiele didn’t return N4trn to FG
FAKE NEWS ALERT: Akume hasn’t been replaced as SGF, says presidency
Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró
Slurs, smears, slander… how gendered disinformation targets high-profile Nigerian women
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé òtítọ́ ni pé a lè fi ewé efinrin fọ kíndìnrín mọ́ láìsí ìrora?

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published July 5, 2022 5 Min Read
Share

Àtẹ̀jáde kan lórí ayélujára tí wọ́n pín sí ojú òpó Facebook àti ìkànnì abẹ́yẹfò (Twitter) ló gbé àhesọ kan pé a lè fi ewé efinrin fọ kíndìnrín mọ́.

Àtẹ̀jáde àtijọ́ kan tí wọ́n s’àtúnpín sí orí ìkànnì Facebook ní, “Bi ọdún ṣe ń g’orí ọdún, kíndìnrín àwa ènìyàn máa ń yọ iyọ̀, májèlé àti àwọn oun míràn tí ó lè ṣe aburú fún àgọ́ ara wa kúrò ní ara.”

Àtẹ̀jáde náà gbé àhesọ pé bí ọjọ́ ṣe ń lọ, iyọ̀ á máa kórajọ sí inú kíndìnrín, eléyìí tí ó jẹ́ kí ó pọn dandan fún wa láti máa fọ kíndìnrín wa mọ́.

Ò tún fi kún un wí pé ọ̀nà kàn tí àwọn olùmúlò ojú òpó lè gbà fọ kíndìnrín ni kí wọ́n bọ ewé efinrin, kí wọ́n sì mu omi efinrin tí a ṣẹ ti a yọ ìdọ̀tí rẹ kúrò.

”Mu ife kan lójúmọ́, óò sì ri pé gbogbo iyọ̀ àti májèlé tó ti kórajọ sínú kíndìnrín rẹ yóò jáde pẹ̀lú ìtọ̀ rẹ. Èyí ni ìtọ́jú fún kíndìnrín tó dára jùlọ, àdáyébá sí ni,” báyìí ni àtẹ̀jáde náà wí.

Ocimum gratissimum ni a mọ ewé yìí sí nínú Ìjìnlẹ̀ sáyẹnsì. A tún mọ ewé yìí sí wild basil tàbí igi basil.

Ewé efinrin ni àwọn Yorùbá máa ń pèé, àwọn Ìgbò mọ̀ọ́ si Nchuanwu, àwọn Hausa a sì máa pèé ní Daidoya.

Àtẹ̀jáde lórí ìkànnì ìbáraẹnisọ̀rọ̀ WhatsApp náà gba àwọn olùmúlò ní ìmọ̀ràn pé kí wọ́n s’àtúnpín rẹ̀ sí àwọn ọ̀rẹ́ àti afẹ́nifẹ́re wọn.

Kíndìnrín jẹ́ ìkan lára àwọn ẹ̀yà ara tí ó se pàtàkì. Ó jẹ́ oun tí ó dàbí kóró ẹwa ní ẹgbẹ méjèèjì ọ̀pá ẹ̀hìn, ní abẹ iha ẹ̀gbẹ́.

Iṣẹ́ kíndìnrín ni láti yọ ìdọ̀tí inú ẹ̀jẹ̀ kúrò, àti láti rí wí pé omi ara kò pọju.

Iṣamudaju

TheCable ṣe ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ iṣẹ́ òògùn òyìnbó láti mọ̀ bóyá ẹ̀rí ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ sáyẹnsì ṣe àtìlẹ́yìn lílo ewé efinrin láti fọ kíndìnrín.

Theophilus Umeizudike, onímọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa kíndìnrín (nephrologist) ní ilé ìwòsàn ẹ̀kọ́ṣẹ́ ti ilé ìwé gíga ti ìlú Èkó, Lagos State University Teaching Hospital, ní Ikẹja sọ wí pé, “kò sí ẹ̀rí tó dájú pé a lè fi ewé efinrin fọ kíndìnrín mọ́.”

Ó tún gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní àmọ̀ràn wí pé kí wọ́n ṣọ́ra fún ìròyìn tí wọ́n pín káàkiri àwọn oun ìbáraẹnisọ̀rọ̀ ìgbàlódé tàbí orí ayélujára, pàápàá jùlọ èyí tí kò wá láti ilé ẹ̀kọ́ iṣẹ́ ètò ìlera òògùn tí àwọn onímọ̀ tí ó péye fi ọwọ́ sí.

Ó ní, “Ti àwọn ènìyàn bá ka àwọn ǹkan báyìí lórí ayélujára, òun á gbà wọ́n nímọ̀ràn pé kí wọ́n ríi dájú pé ó wá láti ilé ẹ̀kọ́ tó ṣeé gbẹkẹle, kí wọ́n ṣì ríi dájú pé ìmọ̀ sáyẹnsì ṣe àtìlẹ́yìn ọ̀rọ̀ náà àti pé ǹkan ọ̀ún ṣe àǹfààní fún ara.”

Bí a ṣe lè ṣe ìtọ́jú kíndìnrín 

TheCable tún kàn sí Awofẹsọ Ọpẹyẹmi ẹlẹgbẹ ìwádìí ní Harvard Medical School àti Dana-Farber Cancer Institute ní Massachusetts ní ìlú Amerika.

Ó ní kòsí àrídájú nínú ìmọ̀ sáyẹnsì pé a lè fi ewé efinrin fọ kíndìnrín mọ́.

“Ìlera kíndìnrín ò nílò ǹkan púpọ̀,” Ọpẹyẹmi lo sọ báyìí, ó fi kún un wí pé, “tí a bá mu omi déédéé lójoojúmọ́ (lita mẹ́ta tàbí ife méjìlá fún àgbàlagbà), èyí lè dènà àrùn kíndìnrín. Ife omi tí ó mọ́ kan ti tó, ẹ ò nílò láti fi ńkankan kún un.”

Awofẹsọ ní ìlera kíndìnrín kò ju ẹ̀dínkù jíjẹ iyọ̀, mímu ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, àti ṣíṣe ìtọ́jú ẹ̀jẹ̀ ríru. Ó ní àiṣe ìtọ́jú ẹ̀jẹ̀ ríru lè fa àrùn kíndìnrín.

“Ti àyẹ̀wò bá ti ṣàfihàn pé ènìyàn ni àìsàn ẹ̀jẹ̀ ríru, lílo òògùn tó dojúkọ àìsàn yìí, pẹ̀lú ìtọ́sọ́nà dọ́kítà, ọ̀nà tí ènìyàn yóò fi ní àìlera kíndìnrín yóò dínkù,” Awofẹsọ ló sọ báyìí.

“Ìdí ni pé ẹ̀jẹ̀ ríru kìí farahàn àyàfi tí ẹ̀yà ara bíi kíndìnrín báti bàjẹ́. Ni ọ̀pọ̀ ìgbà, àwọn ẹlòmíràn nígbà tí wọ́n ṣì jẹ́ ọ̀dọ́, àyẹ̀wò fihàn pé wọ́n ní ẹ̀jẹ̀ ríru, wọ́n sì fún wọn ní òògùn, sùgbọ́n wọn yóò ló fún ìgbà díẹ̀, wọn á sì dá dúró. Yóò wá dàbí ẹni pé kò sí wàhálà kankan títí di ọjọ́ iwájú.”

Àbájáde Ìwádìí 

Irọ́ gbáà ni àhesọ pé ewé efinrin lè fọ kíndìnrín mọ́.

TheCable ng · Yoruba: Ṣé òtítọ́ ni pé a lè fi ewé efinrin fọ kíndìnrín mọ́ láìsí ìrora?
TAGGED: ewé efinrin, health Fact-Check, hypertension, kíndìnrín

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo July 5, 2022 July 5, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

No, Emefiele no return N4trn to FG

One video wey dey waka for social media show as Facebook user claim sey Godwin…

July 4, 2025

Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà

Fídíò kan tí àwọn ènìyàn ti ń pín lórí àwọn ohun ìgbàlódé íbaraẹnise orí ayélujára,…

July 4, 2025

Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn

Ótù ihe ngosị nà soshal midia egosila ebe ótù onye ji Facebook ekesa ozi kwuru…

July 4, 2025

A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba

Wani faifan bidiyo da ke yawo a kafafen sada zumunta ya nuna wani ma’abocin Facebook…

July 4, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

No, Emefiele no return N4trn to FG

One video wey dey waka for social media show as Facebook user claim sey Godwin Emefiele, di forma govnor of…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà

Fídíò kan tí àwọn ènìyàn ti ń pín lórí àwọn ohun ìgbàlódé íbaraẹnise orí ayélujára, tí ó ṣe àfihàn ẹni…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn

Ótù ihe ngosị nà soshal midia egosila ebe ótù onye ji Facebook ekesa ozi kwuru na Godwin Emefiele, onye bụbu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba

Wani faifan bidiyo da ke yawo a kafafen sada zumunta ya nuna wani ma’abocin Facebook yana ikirarin Godwin Emefiele, tsohon…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?