TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú APC nìkan ni àwọn abankanjẹ ń kọlù bí Uzodimma ṣe sọ?
Share
Latest News
Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró
Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal
No, Nigeria no send peace support mission go Israel
A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba
Ǹjẹ́ Tinubu àti Alexander Zingman lọ sí ilé-ìwé kan náà? Èyí ni ohun tí a mọ̀
Tinubu nà Alexander Zingman ọ̀ gàrà ótù ụ́lọ̀ákwụ́kwọ́? Lèé íhé ányị́ mà
Tinubu go di same school wit Alexander Zingman? Na wetin we sabi be dis
Shin Tinubu ya halarci makaranta daya da Alexander Zingman? Ga abin da muka sani
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú APC nìkan ni àwọn abankanjẹ ń kọlù bí Uzodimma ṣe sọ?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published January 11, 2023 4 Min Read
Share

Hope Uzodimma, Gómìnà Ìpínlẹ̀ Imo sọ wí pé àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú All Progressives Congress (APC) àti àwọn tí ó sún mọ́ ìjọba rẹ̀ nìkan ni àwọn abankanjẹ ń kọlù ní Ìpínlẹ̀ náà.

Uzodimma fi ẹ̀sùn kan àwọn olóṣèlú pé àwọn ni ó wà ní ìdí aisifọkanbalẹ ní Ìpínlẹ̀ náà.

Gómìnà Ìpínlẹ̀ Imo náà sọ ọ̀rọ̀ yìí ní ọjọ́ alamisi ní orí ètò kan lórí ẹ̀rọ amohunmaworan tí a mọ̀ sí Channels Television.

Events of the past have shown clearly that politicians are the ones behind the insecurity in Imo State.

– Sen. Hope Uzodimma, Governor of Imo State.#CTVTweets pic.twitter.com/hW2Pc2vm14

— Channels Television (@channelstv) January 5, 2023

“Ní ọjọ́ eni, nínú ìjíròrò mi pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ọ̀rọ̀ Ìpínlẹ̀ Imo jẹ lógún/kàn, mo fi yé wọn pé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tí ó ti ṣẹlẹ̀ fi yé wa pé àwọn olóṣèlú ni ó wà ní ìdí aisifọkanbalẹ ní Ìpínlẹ̀ Imo,” Uzodimma wí báyìí.

“Fún àpẹẹrẹ, nínú ọ̀rọ̀ agbekalẹ tí mo ṣe, mo fi yé àwọn ènìyàn pé gbogbo àwọn ènìyàn tí wọn ti rí akọlukọgba ní Ìpínlẹ̀ Imo, gbogbo àwọn ilé tí wọn fi iná sun jẹ́ ti àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú APC àti àwọn tí ó sún mọ́ ìjọba mi.

“Tí o bá wòó, kò sí ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú kankan tí ó rí àkọlù ni Ìpínlẹ̀ Imo, kò sí ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọn sun ilé rẹ̀ ní iná. Ìṣẹ̀lẹ̀ yìí kò sì dawọ dúró.

“O sọ̀rọ̀ nípa Ikedi Ohakim, Gómìnà Ìpínlẹ̀ Imo tẹ́lẹ̀rí. Ọjọ́ kẹta tí ó pe àpéjọ àjọjẹ-ajọmu fún àwọn tí ọ̀rọ̀ Ìpínlẹ̀ Imo kàn/jẹ lógún tí ó sì rọ̀ wọn pé kí wọ́n ṣe atilẹyin fún ẹgbẹ́ òsèlú APC, ọjọ́ kejì rẹ̀ ni àwọn ọ̀daràn pa àwọn tí ó ń sọọ.

“Nípa ìdí èyí, mo ti gbé ọ̀rọ̀ yìí kalẹ̀ níwájú àwọn ènìyàn Ìpínlẹ̀ Imo, ọwọ́ àwọn agbofinro ti tẹ lára àwọn obayejẹ yìí.

“Mo ti rọ àwọn agbofinro Ìpínlẹ̀ Imo pé kí wọ́n jẹ́ kí àwọn ènìyàn mọ̀ nípa àbájáde ìwádìí wọn àti àwọn ẹni tí ó wà ní ìdí ipaniyan yìí.

“Wọ́n sì máa ṣe gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀. Èmi kò ní ṣe bí ẹni pé ọ̀rọ̀ yìí kò ṣẹlẹ̀. Èmi kò sì níí fi aisifọkanbalẹ àwọn ènìyàn Ìpínlẹ̀ yìí ṣe ọ̀rọ̀ òsèlú.”

ISARIDAJU

Ní aipẹ, Ìwé Ìròyìn TheCable gbé ìròyìn nípa bí àwọn ọ̀daràn agbebọnkiri ṣe ń kọlu àwọn olóṣèlú àti oun ìní ní Ìpínlẹ̀ Imo.

Ní ọjọ́ mélòó kan sẹhin, àwọn ọ̀daràn agbebọnkiri kọlu àwọn ọkọ̀ Ikedi Ohakim. Àwọn Ọlọpa mẹ́rin ni ó pàdánù ẹ̀mí wọn.

Nínú oṣù Kejìlá, ọdún 2022, ilé ẹjọ́ kan ní ìjọba ìbílẹ̀ Owerri àti ilé ẹjọ́ gíga ní ìjọba ìbílẹ̀ Orlu ní Ìpínlẹ̀ Imo ni àwọn agbebọnkiri dá iná sun láàárín wákàtí mẹ́rìnlélógún.

Ní àfikún, nínú oṣù Kejìlá, ọdún 2022, àwọn agbebọnkiri pa Christopher Eleghu, Ólùdíje nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ (Labour Party-LP) fún agbègbè ìṣejọba/isofin Onuimo ní ilé igbimọ asofin ti Ìpínlẹ̀ Imo.

Ní ọjọ́ Kejìlá, àwọn ọ̀daràn agbebọnkiri kọlu ọ́fíìsì Independent National Electoral Commission (INEC), ẹ̀ka ìjọba Àpapọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ó ń ṣe ètò nípa ìbò ni Owerri, olú ìlú Ìpínlẹ̀ Imo.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Ọ̀rọ̀ tí Uzodimma sọ wí pé àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òsèlú APC àti àwọn ènìyàn tí ó sún mọ́ ìjọba òun nìkan ni àwọn abankanjẹ ń kọlù kìí se òótọ́/òtítọ́.

Christopher Eleghu, Ólùdíje nínú ẹgbẹ́ òsèlú àwọn òṣìṣẹ́ fún agbègbè ìṣejọba Onuimo rí àkọlù, àwọn ọ̀daràn agbebọnkiri sì gba ẹ̀mí rẹ̀ ní ìlú rẹ̀ ní Ìpínlẹ̀ Imo.

TAGGED: APC, attack, Fact Check, Imo, Insecurity, Uzodinma

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael January 11, 2023 January 11, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró

Ìròyìn lati inú fídíò Facebook kan sọ pé Nàìjíríà fi àwọn ọmọ ogun ránṣẹ́ sí…

June 28, 2025

Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal

Ótù ihe ngosị si na Facebook kwuru na Naijiria zipụrụ ndị agha ka ha gaa…

June 28, 2025

No, Nigeria no send peace support mission go Israel

One Facebook video claim sey Nigeria send soldiers go Israel for joint peace support mission.…

June 28, 2025

A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba

Wani faifan bidiyo na Facebook ya nuna cewa Najeriya ta tura dakaru domin aikin hadin…

June 28, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró

Ìròyìn lati inú fídíò Facebook kan sọ pé Nàìjíríà fi àwọn ọmọ ogun ránṣẹ́ sí orílẹ̀ èdè Ísírẹ́lì kí rògbòdìyàn…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

Ḿbà, Naijiria ézipụ̀ghị̀ ńdị́ ágha ńkwàdó ùdó nà òbòdò Isreal

Ótù ihe ngosị si na Facebook kwuru na Naijiria zipụrụ ndị agha ka ha gaa kwàdó udo na mba Isreal.…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

No, Nigeria no send peace support mission go Israel

One Facebook video claim sey Nigeria send soldiers go Israel for joint peace support mission. One male broadcaster wey dey…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

A’a, Najeriya ba ta tura tawagar taimakon zaman lafiya zuwa Isra’ila ba

Wani faifan bidiyo na Facebook ya nuna cewa Najeriya ta tura dakaru domin aikin hadin gwiwa na tallafawa zaman lafiya…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 28, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?