TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjẹ́ lóòótọ́ ni pé wọ́n ti mú Naira Marley àti Sam Larry?
Share
Latest News
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Ǹjẹ́ Nàìjíríà dá àjọṣe lórí àwọn àlùmọ́ọ́nì láàárín òhun àti Amẹ́ríkà dúró nítorí visa?
Nigeria stop ‘mineral deal’ with US afta visa restriction?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjẹ́ lóòótọ́ ni pé wọ́n ti mú Naira Marley àti Sam Larry?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published September 20, 2023 5 Min Read
Share

Atẹjade kan tí àwọn ènìyàn ń pín kiri lórí àwọn ohun ìgbàlódé ibaraẹnise ti sọ pé àwọn Ọlọpa ti mú Naira Marley, gbajúmọ̀ olórin àti Samson Balógun, agborinlarugẹ tí a fi bẹẹ mọ̀ sí Sam Larry lẹ́hìn ikú Mohbad, olórin gbajúgbajà.

“Ọwọ ti tẹ Naira Marley àti Sam Larry!! Wọn yóò sọ tẹnu wọn nípa ifiyajẹ tí wọ́n fi jẹ Mohbad,” báyìí ni atẹjade láti ọwọ @Mrklassiq_ ṣe wí.

Àwọn ènìyàn tí rí ọ̀rọ̀ yìí ní ọ̀nà mílíọ̀nù mẹ́ta àti ọọdunrun ẹgbẹ̀rún, wọ́n sì fẹ́ràn rẹ̀ ní ẹgbẹ̀rún ni ọna ọgbọn ó lé ní irinwo, wọ́n sì pín in ní ọna ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀ta ó lé ní méjìlélógún ní orí ibaraẹnise ẹlẹyẹ tí a mọ̀ sí X (tí a mọ̀ ṣí twitter tẹ́lẹ̀).

Lẹ́hìn X, a tún rí ọ̀rọ̀ tí ó jọ ọ̀rọ̀ yìí lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ níbi tí wọ́n ti sọ pé àwọn Ọlọpa ti mú Naira Marley àti Sam Larry.

Mohbad jẹ olórin tí Marlian Records ń gbé orin rẹ̀ jáde tẹ́lẹ̀rí. Naira Marley ni ó ni Marlian Records.

Mohbad kú ní ọjọ́ Kejìlá, ọdún 2023. Ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹtadinlọgbọn. Wọ́n sì sin ní ọjọ́ kejì.

Ikú rẹ̀ rú àwọn ènìyàn lójú. Ó sì ti fà àríyànjiyàn lórí àwọn ohun ìgbàlódé ibaraẹnise (social media) àti láàrin ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn tí kò sí ní orí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise.

Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹwàá, ọdún 2022, Mohbad pariwo lórí ibaraẹnise ẹlẹyẹ lórí nkan ti ó pè ní “ipalara” láti ọwọ Marlian Records.

“Nítorí pé mo fẹ́ paarọ ẹni tí ó ń ṣàkóso orin mi, wo ohun tí wọ́n ṣe fún mi ní ilé Marlian,” Ó tẹ ọrọ àwòrán tí ó ti fi ara pá jáde.

O sì tọrọ iranlọwọ nínú ọ̀rọ̀ yìí. Ó sì ní, “mò ń kú sára.”

Àwọn ènìyàn sọ pé awọn eniyan Marlian Record dẹrubaa léraléra, wọ́n sì ṣe ìpalára fún un ní àìmọye ìgbà títí di ìgbà tí ó fi kú.

Pẹtisọn (petition) kan tí ó dé ọwọ àwọn Ọlọpa ní ọjọ́ kẹtadinlọgbọn, oṣù kẹfà, ọdún 2023, ni a ti rí ní orí ayélujára. Nínú pẹtisọn yìí, Mohbad sọ ọ̀rọ̀ pé Sam Larry pa òhun lára, ó ba nkan òhun jẹ́, ó sì ń fi ajulọ han òhun. Ó fi pẹtisọn yìí ránṣẹ́ sí Force Criminal Investigation Department (FCID) Annex, tí ó wà ní Alagbọn ní ìlú Èkó (Lagos).

Sam Larry kò lo ohun ìgbàlódé ibi tí àwọn ènìyàn ti ń pín àwòrán ara wọn mọ́ nítorí ọ̀rọ̀ kobakungbe tí àwọn ènìyàn sọ síi nítorí pé wọ́n rò pé ohun ló ṣe ìpalára fún Mohbad, Naira Marley tí bẹ̀rẹ̀ sí ní pàdánù àwọn ènìyàn tí ó n tẹlee lórí àwọn ohun ìgbàlódé ibaraẹnise nítorí ọ̀rọ̀ yìí.

ÀWỌN AGBOFINRO KÒ TÍÌ MÚ NAIRA MARLEY ÀTI SAM LARRY

Àyẹ̀wò tí TheCable Newspaper, ìwé ìròyìn orí ayélujára ṣe fi yé wa pé àwọn Ọlọpa kò tíì mú Naira Marley àti Sam Larry láti fi ọ̀rọ̀ wá wọn lẹnu wò nípa ikú Mohbad.

“Irọ́ ni ìròyìn yìí. Wọn kò tíì mú ẹni kankan,” Oluniyi Ogundeji, agbẹnusọ fún FCID ní ìlú Èkó ló sọ bayii.

TheCable ti ṣe atẹjade pé àwọn Ọlọpa ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí ikú akọrin náà.

Ní ọjọ́ Ajé, ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kẹsàn-án, ọdún 2023, àwọn ènìyàn mẹ́tàlá tí a kó jọ láti lè ṣe ìwádìí ọ̀rọ̀ náà sọ pé wọn máa wú òkú rẹ̀ láti lè mọ irú ikú tí ó paa.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Ọ̀rọ̀ tí ènìyàn kan sọ pé àwọn Ọlọpa ti mú Naira Marley àti Sam Larry kìí se òótọ́.

Ìwádìí sì ń lọ lọ́wọ́. Wọn kò tíì mú ẹni kankan.

TAGGED: Imole, Marlian Records, Mohbad, Naira Marley, Sam Larry

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael September 20, 2023 September 20, 2023
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative…

July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?