TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjẹ́ fífi tipátipá fa òjò ló fa omiyale ní Dubai?
Share
Latest News
Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́
Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true
Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà
Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne
FACT CHECK: Kemi Badenoch’s claim that her children can’t get Nigerian citizenship is false
Naijiria ọ̀ kàgbùrù ńkwékọ́rị́tá àzụ́máhị́á àkụ̀ ọ̀nàtàràchí yá nà US nwèrè n’íhì ḿmáchí visa?
Ǹjẹ́ Nàìjíríà dá àjọṣe lórí àwọn àlùmọ́ọ́nì láàárín òhun àti Amẹ́ríkà dúró nítorí visa?
Nigeria stop ‘mineral deal’ with US afta visa restriction?
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjẹ́ fífi tipátipá fa òjò ló fa omiyale ní Dubai?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published May 4, 2024 7 Min Read
Share

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ atẹjade lórí àwọn ohun ibaraẹnise ìgbàlódé ti sọ pé òjò arọfẹku tàbí òjò omiyale, èyí tó rọ̀ tó kówàhálà bá àwọn ará orílẹ̀-èdè United Arab Emirates (UAE) ṣẹlẹ̀ nítorí pé wọ́n fi kẹ́míkà wá òjò tipátipá.

Ọ̀rọ̀ yìí, tí ó wà lórí X, ohun ìgbàlódé ibaraẹnise tí a mọ̀ síTwitter tẹ́lẹ̀, Facebook, ohun ìgbàlódé ibaraẹnise lórí ayélujáraàti Instagram, ohun ìgbàlódé ibaraẹnise tí àwọn ènìyàn ti máa ń pín àwòrán nǹkan tàbí ti ara wọn, fihàn pé UAE kó èrè òjò tíwọ́n fi tipátipa wá.

Massive floods hit Dubai when 2 Years' worth of rain fell in just 24 hours on Tuesday.

This is what is causing the floods in Dubai, UAE:

Dubai has been using cloud seeding, which can include salting clouds, to induce rain.

It's a method to tackle their water scarcity issues.… pic.twitter.com/OLLmvZyEP1

— WithAlvin 🇬🇭 (@withAlvin__) April 16, 2024

Unchecked cloud seeding led to costly consequences yesterday in 🇦🇪Dubai. Manipulating nature comes with risks, and yesterday's man-made rain proves it. Time to reassess the balance between innovation and environmental impact. #Dubai #dubairains pic.twitter.com/etcatxZlRd

— Mansoor Ahmed (@paindoo_jatt) April 17, 2024

The Dubai airport flooded due to cloud seeding, not climate change. Cloud seeding involves spraying chemicals into clouds to make it rain. It's banned in Tennessee. Modifying the weather can have unintended consequences.#Dubai #dubairain pic.twitter.com/ATM2F0qNf0

— صبر،شکر (@i_Syeda_) April 16, 2024

ÒJÒ ÀRỌ̀FẸ́Ẹ̀Ẹ́KÚ TÓ RỌ̀ NÍ DUBAI

Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún, ọdún 2024, àwọn ilé wọlẹ̀ nígbà tí òjò tí ó yẹ kí o rọ̀ ní ọdún kan rọ̀ ní ọjọ́ kan sí méjì ní Dubai, tí ó sì fa kí omi ya wọlé, tí ó sì tún fa kí àwọn ènìyàn fi ọkọ̀ wọn sílẹ̀, tíwọ́n sì sá àsálà fún ẹ̀mí wọn.

Òjò yìí ba iṣẹ́ jẹ́ ní ibi tí àwọn ènìyàn ti ń wọ ọkọ̀ Òfurufú.Àwọn ènìyàn sì sọ pé òhun ni ó fa ikú àwọn ènìyàn bíimọkandinlogun ní Oman, tí ó sì jẹ́ kí ènìyàn méjì sọnù.

Dubai jẹ́ ìkan nínú àwọn àgbègbè tí ó wà lára orílẹ̀-èdè tí a mọ̀ sí UAE. Aginjù ni Dubai. Ó sì jẹ́ ibi tí òjò kò kìí fi bẹ́ẹ̀ rọ̀. Òrùn ibẹ̀ ju òjò ibẹ̀ lọ.

Ooru máa ń pọ̀ ní oṣù kẹfà sí oṣù kẹsàn-án. Oṣù kìíní ọdún niòtútù máa ń pọ̀ jù níbẹ̀.

Láti ọdún 1949, ìgbà tí orílẹ̀-èdè náà bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe àkọsílẹ̀ bíìgbà ṣe rí, àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ sọ pé òjò yìí àti omi tó jẹ́ kó yawọlé ni ó pọ̀ jù.

Àjọ tí a mọ̀ sí National Centre of Meteorology sọ pé òjò náà jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà ní omi. Lára omi yìí sì wọlẹ̀ ṣinṣin.

KÍ NI JÍJẸ KÍ ÒJÒ RỌ̀ NÍ TIPÁTIPÁ?

Eléyìí jẹ́ fífà kí òjò rọ̀ ní tipátipá nípa lílo kẹ́míkà. Àwọn orílẹ̀-èdè tí òjò kò fi bẹ́ẹ̀ máa ń rọ̀ bíi UAE ló máa ń ṣe nǹkan báyìí.

Wọ́n máa ń fa òjò ní àkókò tí wọ́n bá nílò rẹ̀.

Àwọn kẹ́míkà tí wọ́n máa ń lò ni silver iodide, potassium iodide, sodium chloride tàbí dry ice (solid carbon dioxide).

Àmọ́sá, òjò tí a kò fọwọ́ fà ní tipátipá máa ń rọ̀ nígbà tí ohun bíomi bá di nǹkan bíi gaasi tí ó sì padà di omi. Eléyìí ni a mọ̀ síòjò.

ǸJẸ́ FÍFI KẸ́MÍKÀ FA ÒJÒ LÈ FA KÍ IRÚ ÒJÒ YÌÍ RỌ̀?

Àwọn onímọ̀ sayẹnsi sọ pé eléyìí kò lè ṣẹlẹ̀.

Òjò tí ó pọ̀ jù kí ti ọdún 2024 tó rọ̀ ní UAE, rọ̀ ní ọdún 1976.

Ní ìgbà ìfiọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò pẹ̀lú GB News, ìwé ìròyìn kan níorílẹ̀-èdè United Kingdom (UK), Maarten Ambaum, onímọ̀ nípa ojú ọjọ́ (meteorology) ní University of Reading, sọ pé UAE kò ní ohun èlò tí ó lè fa adúrú òjò tó rọ̀ ní Dubai ní ọjọ́ kẹtàdínlógún, oṣù kẹrin, ọdún 2024.

Ó tún sọ pé Dubai kò fà òjò tipátipá láìpẹ́, nítorí pé àwọnonímọ̀ tí sọ pé òjò gidi yóò rọ̀.

“UAE ní ohun tí wọ́n lè fi fa òjò. Àmọ́sá, kò sì ohun tí àwọnènìyàn lè lò láti fa irú òjò yìí,” Ambaum ló sọ báyìí.

Ó yẹ kí a tún mọ̀ pé, àwọn tí wọ́n máa ń sọ bí ojú ọjọ́ yóò ṣe rí, lára wọn tí a mọ̀ sí the Global Flood Awareness System (Glofas), èyí tí European Commission ṣàkóso rẹ̀ sọ pé ìkún omiyóò ṣẹlẹ̀ ní agbègbè náà kì òjò yìí tó rọ̀.

Àwon tí wọ́n máa ń sọ bí ojú ọjọ́ yóò ṣe rí yìí máa ń sọ déédéébí ojú ọjọ́ yóò ṣe rí, wọ́n sì máa ń sọ ibi tí ikùn omi yóò gbéṣẹlẹ̀. Tí wọ́n bá sọ pé irú nǹkan báyìí yóò ṣẹlẹ̀, kò sí nǹkan tíàwọn ènìyàn lè ṣe nípa rẹ̀. Ohun tí wọ́n lè ṣe ni pé kí wọ́n kúròní agbègbè náà.

ÀYẸ̀WÒ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ

TheCable, ìwé ìròyìn orí ayélujára bá Taiwo Ogunwumi, onímọ̀ nípa ikùn omi tó lè ya ilé ní Geohazard Risk Mapping Initiativesọ̀rọ̀ láti lè mọ bí ọ̀rọ̀ yìí ṣe rí. Ó ní pé bí àwọn ènìyàn ṣe ń lo àyíká wọn ló fà á.

Ó sọ pé Biotilẹjẹpe ohun tí wọ́n ní Dubai ṣe yìí lè fa ikùn omi, èyí tí ó túmọ̀ sí pé iye òjò tó rọ̀ ju iye omi tí ilẹ̀ lè fà mu, òjò yìíkò rọ̀ nítorí ohun tí wọ́n ní Dubai ṣe nítorí pé àwọn tí wọ́n máań wo bí ojú ọjọ́ yóò ṣe rí ti sọ pé òjò yóò rọ̀ ní ọjọ́ tí òjòarọfẹku rọ̀ yìí.

“Ohun tí wọ́n ní Dubai ṣe yìí lè fa ikun omi, gẹ́gẹ́bí a ṣe mọ̀ péìdí tí àwọn ènìyàn ṣe máa ń fà òjò tipátipá ni pé kí òjò lè rọ̀ níàwọn agbègbè tí òjò kò sí tàbí tí òjò kò fi bẹ́ẹ̀ ń rọ̀,” Ogunwumiló sọ bayii.

“A kò lè sọ pé ohun tí wọ́n ní Dubai ṣe yìí ló fà ikùn omi nítorípé àwọn tí wọ́n máa ń sọ bí ojú ọjọ́ yóò ṣe rí ti sọ pé òjò yóò rọ̀kí òjò yìí tó rọ̀.”

“Àfọwọ́fa lè fà á. A kò gbọ́dọ̀ fi ohun tí wọ́n ní Dubai ṣe yìí sọpé bí òjò yóò ṣe rí ni eléyìí nítorí pé àwọn ènìyàn kò lo agbegbewọn dáadáa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ibi.”

Gloria Okafor, olùkọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga ní Nigerian Maritime University, ní ìpínlẹ̀ Delta, sọ pé kii se nǹkan tí wọ́n ní Dubai ṣeni ó fa òjò yìí.

“A kò lè sọ bí ojú ọjọ́ ṣe máa rí. Biotilẹjẹpe ohun tí wọ́n níDubai ṣe yìí lè mú òjò rọ̀, ṣùgbọ́n, òjò eléyìí pọ̀ gan-an,” Okafor ló sọ báyìí.

“Bí àwọn ènìyàn kan ṣe ń lo àyíká wọ́n kò dára. Èyí ló ń fààyípadà ojú ọjọ́ (climate change) tó ń pa àwa ènìyàn lára. Eléyìílè fa irú òjò yìí,” olùkọ́ yìí ló sọ bayi.

BÍ A ṢE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ SÍ

Kò sí ẹ̀rí tó dájú tí ó fi yé wa pé ohun tí wọ́n ní Dubai ṣe yìí ló fa òjò arọfẹku tàbí ìkún omi, tí àwọn Yorùbá máa ń pè ní omiyale.

TAGGED: cloud seeding, Dubai, Flood

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael May 4, 2024 May 4, 2024
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị…

July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass…

July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative…

July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za…

July 22, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Ókwú Badenoch nà ụ́mụ̀ yá ápụ̀ghị̀ ínwétá íkíké ị́bụ ńdị́ Naijiria bụ̀ àsị́

Kemi Badenoch, onye ndú òtù Conservative Party nke obodo United Kingdom, ekwuola na ọ gaghị enyenwu ụmụ ya ikike ịbụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Kemi Badenoch claim sey her children no fit get Nigerian citizenship but she no tok true

Kemi Badenoch, leader of di United Kingdom Conservative Party, claim sey she no fit pass her right of Nigerian citizenship…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Irọ́ ni Kemi Badenoch pa pé òfin kò fààyè gba àwọn ọmọ òhun láti di ọmọ Nàìjíríà

Kemi Badenoch, arábìnrin tó jẹ́ olórí ẹgbẹ́ òsèlú alátakò tí wọ́n ń pè ní Conservative Party ní orílẹ̀ èdè United…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

Maganar Kemi Badenoch na cewa ‘ya’yanta ba za su iya samun shaidar zama dan Najeriya ba karya ne

Kemi Badenoch, shugabar jam'iyyar masu ra'ayin rikau ta Burtaniya, ta yi ikirarin cewa ba za ta iya mika hakkinta na…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 22, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?