TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ju miliọnu kan àti ọọdunrun bí Ohanaeze se wí?
Share
Latest News
Did Tinubu attend same school as Alexander Zingman? Here is what we know
FACT CHECK: No, Nigeria didn’t deploy peace support mission to Israel
FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?
FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?
FACT CHECK: Ndume erred. 22 governors didn’t endorse Jonathan in 2015
Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé
Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá
No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ju miliọnu kan àti ọọdunrun bí Ohanaeze se wí?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published November 24, 2024 5 Min Read
Share

Ohanaeze Ndigbo, ẹgbẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n jẹ́ ígbò, sọ pé àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ẹgbẹ̀rún ni wọ́n wà nínú àwọn ẹ̀wọ̀n ní orílẹ̀ èdè India.

Okechukwu Isiguzoro, akọ̀wé ẹgbẹ́ yìí ló sọ báyìí nínú ọ̀rọ̀ tí ó sọ nígbà tí Nàìjíríà se ikinikaabọ fún Narendra Mordi, Ààrẹ India sí Nàìjíríà.

Isiguzoro sọ pé ẹ̀rí tó dájú wà fún ọ̀rọ̀ tí òhun sọ yìí. Ó ní iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ló pọ̀jù ní gbogbo àgbáyé.

“Ohun kan tí ó kọmilominu ni ipò àti ìyè àwọn ọmọ Nàìjíríà, tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ẹgbẹ̀rún tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n káàkiri Ìpínlẹ̀ mejidinlọgbọn tó wà ní India, èyí tí iye rẹ̀ pọ̀ jù ní orílẹ̀ èdè kọ̀ọ̀kan ní àgbáyé,” Isiguzoro ló sọ báyìí.

 Ó ní pé orílẹ̀ èdè Nàìjíríà àti India gbọ́dọ̀ wá nnkan se nípa ọ̀rọ̀ yìí. Ó fi ẹ̀sùn kan àwọn olórí ìjọba India pé wọ́n kàn máa ń ti àwọn ọmọ Nàìjíríà tí kò hu ìwà búburú mọ ẹ̀wọ̀n àti pé ọ̀rọ̀ yìí gbọ́dọ̀ jẹ́ ara àwọn ohun pàtàkì tí Ààrẹ Bọla Tinubu ti Nàìjíríà gbọ́dọ̀ bá Mordi sọ.

“A rọ Tinubu láti se ètò fún bí India yóò ṣe dárí ji àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India, kí wọ́n sì tú wọn sílẹ̀ kí àjọṣe gidi tó wà láàárín àwa àti India lè máa lọ síwájú síi,” báyìí ni akọ̀wé yìí se wí.

Akọ̀wé yìí sọ pé òhun sọ ọ̀rọ̀ yìí kí ẹ̀tọ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà máa baà di ohun tí àwọn ènìyàn ń tẹ̀ mọ́lẹ̀.

ǸJẸ́ ÀWỌN ỌMỌ NÀÌJÍRÍÀ TÍ WỌ́N JU MILIỌNU KÀN ÀTI ỌỌDUNRUN ẸGBẸ̀RÚN NI WỌ́N Ń SE Ẹ̀WỌ̀N NÍ INDIA?

Láti lè se àyẹ̀wò, TheCable Newspaper, ìwé ìròyìn orí ayélujára wo àwọn ọ̀rọ̀ tí wọ́n wà lórí National Prisons Information Portal (NPIP) tí India fi kọmputa (computer) ṣe agbekalẹ rẹ̀, eléyìí tí ó ní í se pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àwọn ẹ̀wọ̀n ní gbogbo India.

Gẹ́gẹ́bí ọ̀rọ̀ tí a rí lórí ohun ẹ̀rọ ìgbàlódé yìí se wí, wákàtí mẹ́rin-mẹ́rin ni wọ́n máa ń se àtúnse ọ̀rọ̀ orí kọmputa yìí. Ọ̀rọ̀ tí a rí lórí nǹkan yìí fi iye àwọn ènìyàn tí wọ́n wà ní ẹ̀wọ̀n ní gbogbo ẹ̀wọ̀n India ye wa. 

Ayẹwo fínnífínní tí a se fi ye wa pé àwọn Ìpínlẹ̀ marunlelogun nínú Ìpínlẹ̀ méjìdínlógún tó wà ní India ni àwọn ọmọ Nàìjíríà ti ń se ẹ̀wọ̀n.

Ní ogunjọ, oṣù kọkànlá, ọdún 2024, àyẹ̀wò tí a se fi hàn wá pé ẹẹdẹgbẹta àti mẹrindinlọgbọn àti ẹẹdẹgbẹta ó lé ní ọgọ́ta àti mẹsan ènìyàn ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India. Iye àwọn ènìyàn yìí tí wọ́n jẹ́ ọmọ Nàìjíríà jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ní mẹtalelọgbọn.

Ìpínlẹ̀ Manipur ní ó ní iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n se ẹ̀wọ̀n tó pọ̀ jù ní India. Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní Manipur jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan àti mẹsan. Ọmọ Nàìjíríà kan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Ìpínlẹ̀ kan tí wọ́n ń pè ní Meghalaya, ọmọ Nàìjíríà kan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Andhra Pradesh, ìkan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Assam, ìkan ló ń se ẹ̀wọ̀n ní Puducherry. Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ní ọdún 2015 jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan àti ọgọ́rùn-ún, eleyii tí ó túmọ̀ sí pé iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India ti lé síi gẹ́gẹ́bí Ajjampur Ghanashyam, asojú India ní Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ se wí.

Iye àwọn ọmọ Nàìjíríà tí Isiguzoro sọ pé wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India kéré gan-an sí iye tí a rí lórí komputa àwọn tó ń ṣètò ẹ̀wọ̀n ní India.

BÍ A SE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ ṢÍ

Ọ̀rọ̀ tí Isiguzoro sọ pé àwọn ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n ju miliọnu kan àti ọọdunrun ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India kìí se òótọ́. Ahesọ lásán-làsàn ni.

Ọ̀rọ̀ tí ìjọba India fi ye wa nípa ọ̀rọ̀ yìí sọ pé ọmọ Nàìjíríà ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ní mẹtalelọgbọn ni wọ́n ń se ẹ̀wọ̀n ní India.

TAGGED: Fact Check, Fact check in Yoruba, India Prisons, News in Yorùbá, Nigerians, Ohanaeze

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael December 7, 2024 November 24, 2024
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

Did Tinubu attend same school as Alexander Zingman? Here is what we know

During the launch of the renewed hope mechanisation programme in Abuja on Monday, President Bola…

June 24, 2025

FACT CHECK: No, Nigeria didn’t deploy peace support mission to Israel

A Facebook video purports that Nigeria deployed troops for a joint peace support mission in…

June 24, 2025

FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?

A viral X post claims that Nigeria’s new national anthem was not recited during the…

June 13, 2025

FACT CHECK: Did a military coup oust Paul Biya as Cameroon’s president?

Reports of a military coup in Cameroon ousting President Paul Biya have gone viral on…

June 13, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

FACT CHECK: Did lawmakers skip the national anthem during Tinubu’s Democracy Day speech?

A viral X post claims that Nigeria’s new national anthem was not recited during the Democracy Day event at the…

Fact CheckTop Stories
June 13, 2025

Rárá, Pope Leo kò bẹ Tinubu kó tú Nnamdi Kanu sílẹ̀ ní àtìmọ́lé

Ẹni kan tí ó ń lo Facebook, ohun ìgbàlódé ibaraẹnisọrẹ orí ayélujára sọ pé Robert Francis Prevost, Pope Leo XIV…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

Ḿbà, Pope Leo áyọghị Tinubu kà ọ́ tọ́pụ̀ Nnamdi Kanu nà ǹgá

Ótù onye na Facebook ekwuola na Pope Leo na ụfọdụ ndị Bishop yọrọ onye isiala Bola Tinubu ka ọ tọpụ…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

No, Pope Leo no beg Tinubu to release Nnamdi Kanu

One Facebook user claim sey Pope Leo XVI and oda bishops join mouth beg President Bola Tinubu to release Nnamdi…

CHECK AM FOR WAZOBIA
June 10, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?