TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjẹ́ àwọn ọmọ isẹ ológun ‘tò lẹsẹẹsẹ yáányáán láti bọ̀wọ̀ fún’ Seyi Tinubu gẹ́gẹ́bí Mahdi Shehu se wí?
Share
Latest News
FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjẹ́ àwọn ọmọ isẹ ológun ‘tò lẹsẹẹsẹ yáányáán láti bọ̀wọ̀ fún’ Seyi Tinubu gẹ́gẹ́bí Mahdi Shehu se wí?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published December 31, 2024 7 Min Read
Share

Fídíò kan tí àwọn ènìyàn ti pín kiri tí se àfihàn Seyi Tinubu, ọmọ Bola Tinubu, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, níbi tí àwọn ọmọ isẹ ologun ti tò lẹsẹẹsẹ láti bọ̀wọ̀ fún ọmọ Ààrẹ yìí, ti fa àríyànjiyàn lórí àwọn ohun ibaraẹnise ìgbàlódé.

Ní ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù Kejìlá, ọdún 2024, Mahdi Shehu, ẹni tí ó máa ń sọ̀rọ̀ nípa àwọn ìṣẹ̀lẹ̀, fi fídíò tí ó tó ìṣẹ́jú mẹ́rin síta, inú èyí tí ó ti sọ pé itolẹsẹẹsẹ àwọn ọmọ isẹ ológun láti bọ̀wọ̀ fún Seyi kò yẹẹ.

“Orílẹ̀ èdè Nàìjíríà nìkan ni àwọn ọmọ isẹ ológun ti máa ń tò yáányáán lẹsẹẹsẹ láti bọ̀wọ̀ fún ọmọ Tinubu nítorí pé Bola Tinubu jẹ́ Ààrẹ”, báyìí ni Shehu se fi ọ̀rọ̀ yìí síta lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise alámì krọọsí (X) tí a mọ sí Twitter tẹ́lẹ̀.

Àwọn ènìyàn ọgọrùn-ún àti mẹ́fà ẹgbẹ̀rún ló ti rí/wo fídíò yìí, àwọn ènìyàn ẹẹdegbẹrun ó dín ogún ló fẹ́ràn ọ̀rọ̀ yìí, àwọn ènìyàn ẹgbẹ̀ta ó dín ní marunlelogun ló pín ọ̀rọ̀ yìí. Àwọn ènìyàn ọtalenigba àti méjì ló sọ̀rọ̀ nípa ọ̀rọ̀ yìí, àwọn ènìyàn aadọjọ ló fi fídíò yìí pamọ.

Ní ọjọ́ ìsinmi, Atiku Abubakar, Ólùdíje fún Ipò Ààrẹ nígbà kan rí sọ pé itolẹsẹẹsẹ yìí kò bófin tàbí ètò ìjọba mú. Àwọn oluranlọwọ Atiku tí wọ́n máa ń rí sí ọ̀rọ̀ ìròyìn sọ pé àyẹ̀wò yẹ kó wà fún itolẹsẹẹsẹ yìí. Àwọn oluranlọwọ yìí sọ pé itolẹsẹẹsẹ yìí kó àbùkù bá bí àwọn ọmọ isẹ ológun se máa ń se nǹkan wọn.

KÍNI ITOLẸSẸẸSẸ YÁÁNYÁÁN TÍ ÀWỌN ỌMỌ ISẸ  OLÓGUN MÁA Ń SE LÁTI BỌ̀WỌ̀ FÚN ÈNÌYÀN KAN?

Itolẹsẹẹsẹ tí àwọn ọmọ isẹ ológun máa ń se láti bọ̀wọ̀ fún tàbí yẹ ènìyàn sí jẹ́ ayẹyẹ tí àwọn sójà/ọmọ isẹ ológun (soldiers/military) máa ń se láti bọ̀wọ̀ fún àwọn ènìyàn pàtàkì tàbí láti bọ̀wọ̀ fún ènìyàn kan pàtàkì tó kú.

Itolẹsẹẹsẹ àwọn ọmọ isẹ ológun àti títòlẹsẹẹsẹ àwọn onisẹ ààbò tàbí àwọn ènìyàn jẹ́ ohun ibọwọfunni, biotilẹjẹpe wọn lè fara jọ bí àwọn ọmọ isẹ ológun se máa ń se.

Itolẹsẹẹsẹ àwọn ọmọ isẹ ológun, gẹ́gẹ́bí àjọ tí ó ń ṣètò ààbò fún ojú ọ̀nà tí àwọn awakọ̀ ń rìn (Federal Road Safety Commission-FRSC) se wí jẹ́ àkójọpọ̀ àwọn sójà tí wọ́n máa ń yan, tí wọ́n sì máa ń se àfihàn àwọn ohun tí wọ́n ti kọ láti gbaradì fún wàhálà, ibaraẹniwi àti ìgbáradì.

Itolẹsẹẹsẹ àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ bọ̀wọ̀ fún ènìyàn kan jẹ́ àwọn ènìyàn tí a yàn láti se ayẹyẹ ìbọ̀wọ̀fún láti kí àwọn ènìyàn pàtàkì kaabọ, dá ààbò bo àwọn ibi pàtàkì kan tàbí láti kópa nínú àwọn ayẹyẹ tí orílẹ̀ èdè tàbí àwọn ẹ̀ka orílẹ̀ èdè máa ń se.

Itolẹsẹẹsẹ láti bọ̀wọ̀ fún nnkan tàbí ènìyàn ní àwọn ènìyàn tí wọ́n kọ láti yan tàbí rìn bákan, èyí tí wọ́n máa ń se lọ́nà tí wọ́n máa ń se irú nnkan bẹ́ẹ̀ láti yẹ nnkan sí tàbí bọ̀wọ̀ fún nǹkan kan tí wọ́n máa ń se ní gbogbo ìgbà.

AYẸWO Ọ̀RỌ̀ YÌÍ TÍ THECABLE NEWSPAPER SE 

Nígbà tí TheCable Newspaper, ìwé ìròyìn orí ayélujára se àyẹ̀wò ọ̀rọ̀ yìí, a ríi pé àwọn ènìyàn tí wọ́n gba Seyi ní àlejò nínú fídíò yìí ni wọ́n ń pè ní CADETN (Community Auxiliary Development for Effective Transformation Network), àwọn ọdọ kan tí wọ́n yọnda ara wọn fún ètò kan.

Láàárín àríyànjiyàn orí ayélujára, J.G. Fatoye, adarí àwọn ọdọ yìí, fi ọ̀rọ̀ kan síta ní ọjọ́ ajé, ó sọ pé Itolẹsẹẹsẹ ìbọ̀wọ̀fún ni, kìí se Itolẹsẹẹsẹ ìbọ̀wọ̀fún tàbí ayẹyẹ tí àwọn ọmọ isẹ ológun máa ń se.

“Gẹ́gẹ́bí àwọn ọdọ tó yọnda ara wọn fún ètò kan, a fẹ́ fi òye yé àwọn ènìyàn nípa Itolẹsẹẹsẹ ìbọ̀wọ̀fún. Ó wà nínú àkọsílẹ̀ pé wọ́n máa ń fi Itolẹsẹẹsẹ tí kì í se ti àwọn ọmọ isẹ ológun kí àwọn ènìyàn pàtàkì kaabọ síbi ayẹyẹ nítorí pé ayẹyẹ itunleaye àwọn ènìyàn se ni àti wí pé ẹgbẹ́ àwọn ọdọ ni,” báyìí ni ọ̀rọ̀ tí ẹgbẹ́ àwọn ọdọ yìí fi síta se wí.

Fatoye fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé Seyi nìkan kọ ní wọ́n máa ń se irú ìyẹnisi yìí fún.

“Àwọn tí wọ́n tò lẹsẹẹsẹ yìí ti yẹ àwọn ènìyàn pàtàkì bíi oluranlọwọ fún olórí kan fún àwọn ohun kan sí, wọn tún ti yẹ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn pàtàkì bíi minisita fún idagbasoke àwọn ọdọ sí, minisita fún tẹkinọlọji, oluranlọwọ pàtàkì fún Ààrẹ lórí ọ̀rọ̀ àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè àti ìdarí, adarí àwọn òṣìṣẹ́ ní Ìpínlẹ̀ Ogun àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn pàtàkì mìíràn tí wọ́n wá sí ibi ayẹyẹ náà sí,” báyìí ni Fatoye se wí.

“CADETN jẹ́ ẹgbẹ́ àwọn ọdọ, kò ní ohunkóhun ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ isẹ ológun. Ẹgbẹ́ yìí kò sì ní ohunkóhun se pẹ̀lú àwọn ọmọ òṣìṣẹ́ ológun gẹ́gẹ́bí àwọn ènìyàn kan se sọ.”

“Ẹgbẹ́ yìí jẹ́ ẹgbẹ́ bíi Man O War, Peace Corps, Royal Ambassador, Man of Order, WAI Brigade àti àwọn mìíràn tí wọ́n máa ń yọnda ara wọn fún isẹ tó wù wọ́n (voluntary organisation), tí wọ́n máa ń wọ unifọọmu (uniform).”

Fatoye sọ pé kò sí ohunkóhun kan tí àwọn òṣìṣẹ́ ológun máa ń lò tí àwọn lò nígbà Itolẹsẹẹsẹ náà, ó ní àwọn ìbọn tí wọ́n fi máa ń ṣeré ni àwọn lò.

Ó ní kí àwọn ènìyàn yé máa sọ ọ̀rọ̀ tí kìí se òótọ́.

BÍ A SE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ ṢÍ 

Kìí se Itolẹsẹẹsẹ tí àwọn ọmọ isẹ ológun máa ń se láti bọ̀wọ̀ fún tàbí yẹ ènìyàn tàbí nǹkan sí ni wọ́n se fún Seyi Tinubu.

TAGGED: Fact Check, Fact check in Yoruba, Mahdi Shehu, military honour, News in Yorùbá, Seyi Tinubu

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael December 31, 2024 December 31, 2024
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: Is Nigeria 4th fastest-growing economy in the world in 2025?

A viral post claims, based on International Monetary Fund (IMF) projections, that Nigeria ranks fourth…

May 9, 2025

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025

FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?

A social media user has claimed that Francis Arinze, a Roman Catholic cardinal, is the…

April 21, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?