TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ǹjé àwọn agbébọn sọ laipẹ yìí pé wọn yóò kọlù sọọsi? Rárá o, fídíò àtijọ ní
Share
Latest News
No, Emefiele no return N4trn to FG
Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà
Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn
A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba
FACT CHECK: No, Emefiele didn’t return N4trn to FG
FAKE NEWS ALERT: Akume hasn’t been replaced as SGF, says presidency
Rárá, Nàìjíríà kò fi àwọn ọmọ iṣẹ́ ológun rán sẹ sí Ísírẹ́lì láti dá rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀ dúró
Slurs, smears, slander… how gendered disinformation targets high-profile Nigerian women
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ǹjé àwọn agbébọn sọ laipẹ yìí pé wọn yóò kọlù sọọsi? Rárá o, fídíò àtijọ ní

Elizabeth Ogunbamowo
By Elizabeth Ogunbamowo Published June 17, 2022 3 Min Read
Share

Fídíò kan nínú èyí tí Ayuba Elkana, ọ̀gá Ọlọpaa ipinle Zamfara, fi ìdí rẹ múlẹ̀ pe àwọn agbébọn tí kọ lẹ́tà si àwọn ẹlẹsin Kristẹni ni Zamfara wípé kí wọn ti sọọsi pa fún oṣù mẹ́ta ti farahàn l’órí ẹ̀rọ ayélujára.

Contents
Iṣamudaju Àbọ̀ Ìwádìí 

Fídíò yìí ti wà káàkiri ojú òpó ìtàkurọ̀sọ WhatsApp, ati ìtàkùn ìbánidọ́rẹ̀ẹ́ Facebook pẹ̀lú Twitter.

“Ọlọpaa ti fi idi rẹ múlẹ̀ pe àwọn agbébọn kọ lẹta si àwọn sọọsi ni orílè-èdè Nàìjíríà ki wọn wa ni títìpa fún oṣù mẹ́ta,” ènìyàn kan kọ èyí sí Facebook ni ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹfà.

Ojú òpó yìí ní àwọn òntẹ̀lẹ́ bíi 112,000. Àwọn ènìyàn si ti wo fídíò náà ni ọ̀kẹ́ àìmọye ìgbà, èyí tíí ṣe 165,000, pẹlu ọ̀rọ̀ ìwòye 750. Awon ènìyàn lori ayélujára ti pín fídíò yìí ni ọ̀nà 8,200.

Ni ìgbà tí TheCable Check ṣe àyẹ̀wò awọn ọ̀rọ̀ ìwòye yìí, a ríi wipe, ọ̀pọ̀lọpọ̀ eniyan ni fídíò yìí ati ọrọ ifori rẹ ti tàn jẹ.

Iṣamudaju

Ayẹwo TheCable fi hàn pé fídíò ti o ń tàn ràn-ìn lórí ẹ̀rọ ayélujára yìí ti wa lori Youtube láti ọdún 2021.

Fídíò yii tí a gbàsílẹ̀ ní ìgbà tí Elkana n bá àwọn oníròyìn sọrọ ni ọjọ́ ọgbọ̀n oṣù kọkànlá ọdún 2021. Ninu ọ̀rọ̀ rẹ, Elkana fi ìdí rẹ̀ múlẹ pé àwọn agbébọn kọ lẹ́tà sí àwọn sọọsi ni Zamfara láti ti ilẹkùn wọn fún oṣù mẹta tabi ki wọn bọ sí ewu ìjàmbá.

“Àwọn ènìyàn aìmọ̀ kan fí lẹta yìí sì enu ònà àbáwọlé ilé iṣẹ ọlọpaa ni ìpínlẹ̀ yìí,” ọga ọlọpaa náà wii.

Ní ìgbà tí ó ń sọ ọ̀rọ̀ nípa ìgbésẹ̀ ti awọn eleṣọ ààbò yóò gbé láti kí ọwọ irufin náà bọ lẹ̀, ọ̀gá ọlọpaa náà sàlàyé wípé lẹ́tà ìhàlẹ̀ yìí dárúkọ àwọn sọọsi kan ní olú-ìlú ìpínlè náà ti ìjàmbá yóò dé bá ki ọdún 2021 to parí.

TheCable bá Iliya Tsiga, tíí ṣe alága ẹgbẹ́ Christian Association of Nigeria (CAN) ní ilu Zamfara, sọ̀rọ̀, ósì fìdí rẹ̀ mulẹ pe fídíò náà tí pẹ.

“Mo tí rí fídíò náà ti e nsọ̀rọ̀ nípa rẹ. Fídíò náà ti pẹ, lati ọdún 2021 níí. Ọrọ yìí ti ní ìyanjú; ẹnikẹni tí o ba n tán fídíò náà ka, olubi ni onítọ̀ún, o si fẹ dá rògbòdìyàn silẹ ninu ilu ni,” Tsiga wí.

“Awon agbébọn yìí kọ lẹta yìí nígbà náà síi gbogbo Kristẹni ni Zamfara ni. A rọ àwọn èèyàn wá ki wọn ma ṣe kobiarasi fídíò yìí, ki wọn ṣe iṣẹ ojumọ won ni àlàáfíà.”

 Àbọ̀ Ìwádìí 

Fídíò náà ti pẹ, àwòrán náà ti wa lórí ayélujára lati ọdún 2021.

Irọ́ pọnbele ni ahesọ ọ̀rọ̀ pe àwọn agbébọn sọ laipẹ yìí pé ki sọọsi ni orile-ede Nàìjíríà wa ni títìpa fún oṣù mẹ́ta.

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Elizabeth Ogunbamowo June 17, 2022 June 17, 2022
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

No, Emefiele no return N4trn to FG

One video wey dey waka for social media show as Facebook user claim sey Godwin…

July 4, 2025

Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà

Fídíò kan tí àwọn ènìyàn ti ń pín lórí àwọn ohun ìgbàlódé íbaraẹnise orí ayélujára,…

July 4, 2025

Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn

Ótù ihe ngosị nà soshal midia egosila ebe ótù onye ji Facebook ekesa ozi kwuru…

July 4, 2025

A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba

Wani faifan bidiyo da ke yawo a kafafen sada zumunta ya nuna wani ma’abocin Facebook…

July 4, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

No, Emefiele no return N4trn to FG

One video wey dey waka for social media show as Facebook user claim sey Godwin Emefiele, di forma govnor of…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

Rárá, Emefiele kò dá triliọnu mẹrin náírà padà fún ijọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà

Fídíò kan tí àwọn ènìyàn ti ń pín lórí àwọn ohun ìgbàlódé íbaraẹnise orí ayélujára, tí ó ṣe àfihàn ẹni…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

Ḿbà, Emefiele ènyéghàchìghị̀ FG ọ́nụ́ égó N4trn

Ótù ihe ngosị nà soshal midia egosila ebe ótù onye ji Facebook ekesa ozi kwuru na Godwin Emefiele, onye bụbu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

A’a, Emefiele bai mayarwa FG N4trn ba

Wani faifan bidiyo da ke yawo a kafafen sada zumunta ya nuna wani ma’abocin Facebook yana ikirarin Godwin Emefiele, tsohon…

CHECK AM FOR WAZOBIA
July 4, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?