TheCable Fact Check
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Reading: Ṣé Nàìjíríà ni orílẹ̀ èdè kejì tí àwọn tó ní kòkòrò tó ń fa éèdì pọ̀ sí jù lagbaye?
Share
Latest News
FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?
FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria
FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?
Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027
A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba
No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election
Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027
FACT CHECK: Picture of Kwankwaso wearing cap with ‘Tinubu’s insignia’ photoshopped
Advertisement
Aa
TheCable Fact CheckTheCable Fact Check
Search
  • Home
  • Fact Check
  • Fake News
  • Check Am For Wazobia
Follow US

Ṣé Nàìjíríà ni orílẹ̀ èdè kejì tí àwọn tó ní kòkòrò tó ń fa éèdì pọ̀ sí jù lagbaye?

Yemi Michael
By Yemi Michael Published February 10, 2025 6 Min Read
Share

Ní ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù Kínní, ọdún 2025, Chinonso Egemba, dókítà tí ó mọ̀ nípa àìlera, tí ó jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ẹni tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn mọ̀ sí Aproko Doctor, sọ pé Nàìjíríà ni orílẹ̀ èdè kejì tí ó ní àwọn ènìyàn tí wọ́n pọ̀ jù tí wọ́n ní kòkòrò apasojaara tàbí kòkòrò tó ń fa àrùn eedi, èyí tí ó ń fa aarunisọdọlẹajẹsára ní àgbáyé.

Dókítà yìí fi ọ̀rọ̀ yìí síta lórí ohun ìgbàlódé ibaraẹnise alámì krọọsi (X), tí a mọ̀ sí Twitter tẹ́lẹ̀. Ẹni yìí ní àwọn ènìyàn mílíọ̀nù méjì àti ọọdunrun tí wọ́n ń tẹ̀lée. Ó sọ ọ̀rọ̀ yìí láti fèsì sí ìpinnu tí Ààrẹ Donald Trump ti orílẹ̀ èdè Amẹ́ríkà se pé òhun yóò dá owó ìrànlọ́wọ́ kan tí wọ́n ń pè ní president’s emergency plan for AIDS relief (PEPFAR) dúró.

Gẹ́gẹ́bí àjọ tó ń rí sí ètò ìlera ní àgbáyé (World Health Organisation-WHO) se wí, PEPFAR ń pèsè owó ìrànlọ́wọ́ fún ìtọ́jú kòkòrò tó ń fa àrùn eedi fún àwọn ènìyàn tí wọ́n ju ogún mílíọ̀nù tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú aarunisọdọlẹajẹsára, lára àwọn tó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà ẹẹdẹgbẹtá àti mẹrindinlaaadọrin àwọn ọmọdé tí ọjọ́ orí wọn kò tó ọdún mẹẹdogun.

Nínú ọ̀rọ̀ yìí, dókítà yìí se àlàyé àwọn ọ̀nà tí ìpinnu Trump yìí yóò se se àkóbá fún ògùn kan tí a mọ̀ sí antiretroviral drugs, tí àwọn ènìyàn ti àrùn yìí ń se máa ń lò.

Nígbà tí àwọn ènìyàn sọ pé kí dókítà yìí sọ ibi tí ó ti rí ọ̀rọ̀ yìí, ó se àfihàn ọ̀rọ̀ kan tí wọ́n tẹ̀ síta tí ó wà lórí ààyè ayélujára/wẹbusaiti (website) ti United Nations Children’s Fund (UNICEF).

“Orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ni orílẹ̀ èdè kejì ní àgbáyé, tí ó ní àwọn ènìyàn tí wọ́n pọ̀jù, tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò tó ń fa àrùn eedi,” báyìí ni dókítà yìí se wí.

Nínú àtẹ̀síta tó jáde ní ọdún 2018, UNICEF sọ pé àwọn ènìyàn ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà igba ó dín mẹwa àti ẹgbẹ̀rún kan dín ní àádọ́ta ní Nàìjíríà ni wọ́n kó àrùn yìí ní ọdọọdún, èyí tí ó jẹ́ kó jẹ́ pé Nàìjíríà ni orílẹ̀ kejì tí wọ́n pọ̀ sí jù ní àgbáyé. UNICEF fi kún ọ̀rọ̀ wọn pé àwọn ènìyàn bíi mílíọ̀nù mẹta ni wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò tó ń fa àrùn eedi yìí. Àtẹ̀síta yìí fi hàn pé ọdún 2015 ni UNICEF tí wá ọ̀rọ̀ yìí.

Ó se pàtàki kí a mọ̀ pé ìyàtọ̀ wà láàárín àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú àrùn apasojaara àti àwọn tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò tó ń fa àrùn eedi. Gbogbo wàhálà nǹkan yìí ń sọ nípa àwọn tó ń gbé pẹ̀lú kòkòrò tó ń fa àrùn eedi, bí àwọn ènìyàn se ń kó àrùn náà sí, àti àwọn ikú tí àrùn yìí fà.

AYẸWO Ọ̀RỌ̀ YÌÍ TÍ THECABLE NEWSPAPER SE RÈÉ

Láti lè jẹ́ kí àwọn ènìyàn mọ ohun tí ó jẹ́ òótọ́ àti irọ, CableCheck se àyẹ̀wò  WHO’s HIV country intelligence dashboard. Ní ọdún 2023, wọ́n fi ọ̀rọ̀ nípa àwọn tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò tó ń fa àrùn eedi ní bíi àwọn orílẹ̀ èdè mẹrinlelaaadoje síta.

Ọ̀rọ̀ yìí fi hàn pé pé orílẹ̀ èdè South Africa ni ó ní àwọn ènìyàn tí wọ́n pọ̀ jù tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò tó ń fa àrùn eedi, àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò yìí níbẹ̀ jẹ́ mílíọ̀nù méje àti ẹẹdẹgbẹrin, orílẹ̀ èdè India ló tẹ̀ lée, àwọn ènìyàn mílíọ̀nù méjì àti ẹẹdẹgbẹta ni wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò náà, orílẹ̀ èdè Mozambique ló tẹ̀lée pẹ̀lú àwọn ènìyàn mílíọ̀nù méjì àti irínwó. Orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ni ó wà ní ipò kẹrin. Iye àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò yìí ní Nàìjíríà jẹ́ mílíọ̀nù méjì.

Country Number of Persons Living With HIV
South African 7,700,000
India 2,500,000
Mozambique 2,400,000
Nigeria 2,000,000
United Republic of Tanzania 1,700,000
Uganda 1,500,000
Kenya 1,400,000
Zambia 1,300,000
Zimbabwe 1,300,000
Brazil 1,000,000

Ohun tí àyẹ̀wò yìí túmọ̀ sí ni pé Nàìjíríà ni orílẹ̀ èdè kẹrin tí ó ní àwọn ènìyàn tí wọ́n pọ̀ jù tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò yìí ní àgbáyé. Ayẹwo yìí tún fi hàn pé Nàìjíríà ni orílẹ̀ èdè kẹta tí àwọn ènìyàn ti wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò yìí pọ̀ sí jù ní Afíríkà.

Nínú àtẹ̀síta kan tí àjọ tó ń rí sí ètò/ọ̀rọ̀ ìlera fún àgbáyé fi síta nínú oṣù keje, ọdún 2024, àwọn ènìyàn bíi ogójì mílíọ̀nù ó lé ẹgbẹ̀rún mẹsan-an ni wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò yìí ní ìparí ọdún 2023. Ọ̀rọ̀ yìí kò sọ iye tí àwọn ènìyàn yìí jẹ́ ní orílẹ̀ èdè kọ̀ọ̀kan.

Àmọ́sá, àwọn ènìyàn bíi mílíọ̀nù mẹrindinlọgbọn ni wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò yìí ní Afíríkà.

BÍ A SE RÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ ṢÍ 

Ọ̀rọ̀ tí dókítà yìí sọ pé Nàìjíríà ni orílẹ̀ èdè kejì tí ó ní àwọn ènìyàn tó pọ̀ jù tí wọ́n ń gbé pẹ̀lú kòkòrò yìí ní àgbáyé kìí se òótọ́,

Ọ̀rọ̀ tí WHO fi síta jẹ́ kí a mọ̀ pé kì í se òótọ́.

TAGGED: Àrọko Doctor, Chinonso Egemba, Fact Check, Fact check in Yoruba, HIV/AIDS, News in Yorùbá

Please send your feedback, claims to fact check and corrections requests to [email protected]

Yemi Michael February 10, 2025 February 10, 2025
Share this Article
Facebook Twitter Email Copy Link Print
Leave a comment Leave a comment

Leave a Reply Cancel reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

POPULAR POSTS

Advertisement

FACT CHECK: How true are Obi’s claims about poverty rate in Nigeria, China and Indonesia?

Peter Obi, Labour Party (LP) presidential candidate in the 2023 elections, sparked a debate with…

May 5, 2025

FACT CHECK: No, Finnish court didn’t approve Simon Ekpa’s extradition to Nigeria

On Tuesday, some social media users and blog sites made a post claiming that a…

April 24, 2025

FACT CHECK: Is Cardinal Arinze eligible to be elected as the next Pope?

A social media user has claimed that Francis Arinze, a Roman Catholic cardinal, is the…

April 21, 2025

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀…

April 20, 2025
Advertisement
Advertisement

YOU MAY ALSO LIKE

Rárá, Jonathan kò sọ pé Tinubu yóò se àṣeyọrí nínú ètò ìdìbò fún Ipò Ààrẹ ní ọdún 2027

Ní ọjọ́ ajé, ọ̀rọ̀ kan to sọ pé Goodluck Jonathan, Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ sọ pé Ààrẹ Bọla Tinubu…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

A’a, Jonathan bai yi hasashen nasarar Tinubu a zaben shugaban kasa na 2027 ba

A ranar Talata ne wani rahoto da ke ikirarin cewa tsohon shugaban kasa Goodluck Jonathan ya yi hasashen nasarar Shugaba…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

No, Jonathan no predict Tinubu victory for 2027 presidential election

On Tuesday, one report wey claim sey former President Goodluck Jonathan predict President Bola Tinubu victory for di 2027 presidential…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 20, 2025

Ḿbà, Jonathan ágbaghị àmà na Tinubu gà-èmérí ńtùlíáka ónyé ísíàlà ǹkè áfọ̀ 2027

N’ubọchị Tuesde, ozi na-ekwu na onye bụburu onye isiala Naijiria, bụ Goodluck Jonathan, gbara àmà na onyeisiala Bola Tinubu ga-emeri…

CHECK AM FOR WAZOBIA
April 19, 2025

CableCheck seeks to provide reliable tools and resources for readers to tackle the menace of fake and misleading materials constantly pushed into the public space from various sources. We monitor the accuracy of claims made in traditional and social media. We also provide a tracker to hold politicians and policymakers accountable for the plans and promises they make to the public. CableCheck is a project of the Cable Newspaper Journalism Foundation (CNJF), supported by the MacArthur Foundation and implemented by TheCable newspaper.

Follow US: 

LINKS

  • Contact
  • About Us
  • Non-Partisanship Policy
  • Funding
  • Correction Policy
© Copyright TheCable. All Rights reserved.
Welcome Back!

Sign in to your account

Lost your password?